Jump to content

John Afolabi Fabiyi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
John Afolabi Fabiyi
Justice of the Supreme Court of Nigeria
In office
2009  25 November 2015
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí25 Oṣù Kọkànlá 1945 (1945-11-25) (ọmọ ọdún 80)
Kogi State, Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúNon partisian

John Afolabi Fabiyi, CON (tí a bí ni ọjọ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù kọkànlá ọdún 1945) jẹ agbẹjọ́rò olókìkí ọmọ orilẹ-ede Nàìjíríà ati Adájọ́ tẹ́lẹ̀ rí ti Ile-ẹjọ Giga julọ ti Nàìjíríà . Ó jẹ́ Adájọ́ ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn ní Nàìjíríà tẹ́lẹ̀. [1] [2] [3]

Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbésí ayé

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bi Adájọ́ Fabiyi ni ọjọ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù kọkànlá ọdún 1945, ní Ipinle Kogi, Ààrin Árèwá Nainiria . Ni ọdún 1969, o gba oye ìyẹ̀wù kínní ninu ìmọn ofin lati Ile-ẹkọ Fásítì Ahmadu Bello wọn sí pé sórí àleefà ni ọdún 1970 lẹhìn ti o pari ile-iwe òfin ti Naijiria . [4]

Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ ní Noel Gery & Co, ilè iṣẹ agbejọ́rọ̀ ní ipinle Kano kó tóo dí pé o darapọ̀ mọ adájọ ìpínlẹ̀ Kwara gẹgẹ bi Majisreeti tó si ri àgbéga sípò adájọ ilè ejọ́ gíga ni ìpínlẹ̀ náà. Ni ọdún 1994, wọn gbè e lọ si ipinlẹ Anambra níbití o ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́bí Alága ti ẹjọ́ ìtakò ìdìbò fún ọdún mẹrin. Ni ọdún 1998, wọn yan an si ààrin awọn ilè ẹjọ́ kò-tẹ́-mi-lọ́rùn ti Naijiria gẹ́gẹ́bí Agbẹjọ́rọ̀ ní ọdún 2006 o si ri ìgbéga si ipo Adájọ́ ti Ile-ẹjọ kò-tẹ́-mi-lọ́rùn ni Ilu Ibadan. Ó ṣíṣe ni ipò yẹn fún ọdún mẹ́ta kí wọ́n tó yàn án sí ààrin ilé ẹjọ́ Gíga Jù Lọ ní Nàìjíríà lọ́dún 2009 gẹ́gẹ́ bí agbẹjọ́rọ̀, ni ọdún yẹn bákannáà ló sì gba àmì ẹ̀yẹ ọlá ti orílẹ̀-èdè náà, Commander of Order of Niger, tí ìjọba àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà fi fún, Goodluck Ebele Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ló ṣe lọ́ṣọ̀ọ́. [5] Fabiyi lo se àkóso ìdájọ́ ile-ẹjo to gaju nínú èyí ti wọn yọnda Oloye Bode George ti wọn si da a láre fun ẹ̀sùn jegúdújerá ti Àjọ to n gbógun ti eto oro aje ati ẹ̀sùn-owo fi kan an . [6] O tun ṣe olórí lori ile-ẹjọ gíga jùlọ ti o fi idi rẹ mulẹ wípé Ayodele Fayose ni gómìnà ti wọn dibò yan ni Ìpínlẹ̀ Èkìtì níbi ìdìbò gomina tó wáyé ní ọjọ kọkànlelógún Oṣu Kàrún, ọdún 2014. [7]

O fẹyìntì kúrò ni ile-ẹjọ ni ọjọ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Kọkànlá ọdún 2015 lẹhin ti o ti pe ọjọ-ori ifẹyìntì dandan tin ṣe Aadọrin ọdún. [8]

  • Akojọ ti àwọn adajọ ti awọn ile ejo kò-tẹ́-mi-lọ́rùn Naijiria