Kolawole Olawuyi
Kolawole Olawuyi
Kóláwole Oláwuyi''' (1963 – oṣù kẹta 3, 2007) jẹ́ akọ̀ròyìn aṣòfintótó, oníròyìn aṣòfintótó was an, akàròyìn àti òǹpìtàn.
== Ìgbésí ayé ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ==
A tọ́ Olawuyi dàgbà ní [[Ibadan]], gúsùìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà, ọmọkùnrin Williams Inaolaji Olawuyi àti Alhaja Olawuyi. Ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìse ti Ìbàdàn [[The Polytechnic, Ibadan|The Polytechnic Ibadan]] láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa mass communication. Ó ti fẹ́rẹ̀ẹ́ parí ẹ̀kọ́ onípò kejì nínú Communication Arts ní ilé ẹ̀kọ́ gíga ti [[University of Ibadan]] síwájú kí ó tó kú.
== Iṣẹ́ ==
Olawuyi bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ rẹ̀ ní ilé iṣẹ́ rédíò Federal Radio Corporation of Nigeria, níbi tí ó ti sẹ̀dá ètò orí rédíò, Ìrírí Ayé , Irinkerindo Akolawole ní ọdún 1992, ètò náà ṣe àfihàn ìwòye tuntun lórí ìtàn ọmọnìyàn àti àwọn ìpèníjà, tí ó ń sí aṣọ lójú eégún 'ohun tó ṣe àjòjì ṣùgbọ́n tí ó jẹ́ òótọ́' àwọn ìtàn àdììtú .
Ètò náà ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òǹwòran pẹ̀lú ìtàn Okorocha, àti Malaika Agba, síbẹ̀, ètò náà rí ìfàsẹ́yìn bí ó ti jẹ́ pé ètò náà kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní FRCN. Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ní o mú un kí ó ṣe ìdásílẹ̀ Kolbim Communications, àjọ ìtàkurọ̀sọ olómìnira ní èyí tí ó ti ṣe ìdásílẹ̀ 'Nnkan Nbe', ẹ̀yà ti ohùn-àwòrán ti ètò lórí Ogun State Broadcasting Corporation, OGBC, [[Abeokuta]], àti láìpẹ́ lórí later [[Galaxy Television (Nigeria)|Galaxy Television]], Èkó. Ó ń ṣe ètò náà títí ó fi kú.
== Àdììtú àti awuyewuye ==
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olawuyi kì í ṣe akàròyìn olójoojúmọ́, ètò rẹ̀ dá yàtọ̀ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀nà. Àfojúsùn rẹ̀ ni láti fi àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ àdììtú àwọn ẹni ibi lọ́kùnrin àti lóbìnrin hàn ní àwùjọ, pàápàá jùlọ ní Gúsù Ìwọ oòrùn, níbi tí ó ti máa ń ṣe wọ́n lórí afẹ́fẹ́ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ amóhùnmáwòrán àti rédíò. Gẹ́gẹ́ bí ''Premium Times'' ti sọ, ní àkókò 1990s ó ń ṣe àfihàn ọlọ́sọ́ọ̀sẹ̀ kan lóríran 'Nkan Mbe' níbi tí ó ti bá ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn òṣìṣẹ́ tẹ́lẹ̀ àti àwọn ọmọ ẹgbẹ́ TB Joshua's SCOAN sọ̀rọ̀, "ẹni tí ó tú orísìírísìí ọ̀nà ìwà ìbàjẹ́, tí ó fi mọ́ ẹgbẹ́ òkùnkùn ní ilé ìjọsìn.
Orísìírísìí ìwòye ló ti di ṣíṣe àfihàn lórí ohun tí ó fa ikú Olawuyi ní pàtó. Àwọn kan sọ pé ó ṣàìsàn fún oṣù mẹ́ta, síwájú ikú rẹ̀ Some nígbà tí àwọn mìíràn sọ pé ikú rẹ̀ jẹ́ látàrí àṣírí tó tú nípa ìlú òkú kan ní Benin Republic. Àwọn ènìyàn gbàgbọ́ pé ó wà nínú ẹgbẹ́ alágbára ńlá kan ní èyí tí ó tako wíwà níbẹ̀ nígbà gbogbo.