Lèkan Sàlámì
Olálékan Sànúsí Sàlámi Ọdún 1928 sí ọdún 1988 jẹ́ olóṣèlú, oníṣòwò, àti gbajúmọ̀ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí tẹ́lẹ̀ fún Western Nigeria Development Corporation tí a mọ̀ sí Odu'a Investment Company lọ́wọ́lọ́wọ́. Ó tún jẹ́ olùdarí ilé-iṣẹ́ ìkọ́lé ti ìlú Ísírẹ́lì nì Solel Boneh, ó sì dá ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Shooting Stars SC [1] sílẹ̀ ní àwọn ọdún 1970.
Ilé eré ìdárayá Adamasingba tí wọ́n dá sílẹ̀ ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n oṣù karùn-ún ọdún 1988, oṣù méjì lẹ́yìn ikú rẹ̀, ni wọ́n yí orúkọ rẹ̀ padà sí Pápá ìṣeré Lekan Salami ní ọdún 1998 láti ọwọ́ Gómìnà Ológun Ìpínlẹ̀ Oyo nígbà náà, Ahmed Usman .
Ìgbésí ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wọ́n bí Salami ní ìlú Ibadan sí ìdílé ọba Sàlámì, Oyèbimpé Oyètúndé, baba rẹ̀ sì jẹ́ àbúrò Olúbadan Ọba Shittu Akintọlá Oyètúndé tí ó ti kú. Àdúgbò ìdílé náà wà ní agbègbè Ẹléta ní ìlú Ibadan, nítorí náà wọ́n fún un ní orúkọ náà Salami Ẹlẹ́ta nígbà tí ó wà ní kékeré. [2] Ó bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ ẹ̀kọ́ nípa kíkọ́ ẹ̀kọ́ Al-Quran nígbà tí ó wà ní ọmọ ọdún mẹ́ta, nígbà tí ó sì wà ní ọmọ ọdún méje, ó bẹ̀rẹ̀ sí í lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn Islam. Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ gíga àwọn ọmọkùnrin Ibadan àti ilé-ẹ̀kọ́ gíga Lisabi ní Abeokuta. [3]
Gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní ọdún 1950, Sàlámì ni akọ̀wé fún Ìbàdàn Cooperative Produce Marketing Union, ipa kan tí ó ní í ṣe pẹ̀lú ìpínsípò àti sísan owó fún àwọn oun tí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ alájẹṣẹ́kù náà bá mú wá. Lẹ́yìn àkókò rẹ̀ pẹ̀lú ilé iṣẹ́ alájẹṣẹ́kù yìí, ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú UAC lẹ́yìn náà.
Kí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tó gba òmìnira, Salami dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ Mábọlájé ti Adégòkè Adélabú . Ní ọdún 1954, wọ́n dìbò yàn-án gẹ́gẹ́ bíì alága kékeré sí Agbègbè Ìbàdàn lábẹ́ àsíá ẹgbẹ́ òṣèlú ti NCNC [4] àti ní ọdún 1956, ó borí níbi ètò ìdìbò sí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìwọ̀ Oòrùn, ó sì borí Akinloye tó wà nípò yìy´ nígbà náà. Lẹ́yìn ikú Adelabu ní ọdún 1958, wàhálà kan tó ṣẹlẹ̀ nínú ẹgbẹ́ NCNC ẹka ti Ibadan yọrí sí bí Salami ṣe kúrò nínú ẹgbẹ́ NCNC.
Lẹ́yìn náà, ó dara pọ̀ mọ́ Action Group ó sì jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Akintola . [5] Wọ́n yàn án padà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìgbìmọ̀ Agbègbè Ìbàdàn ní ọdún 1961, wọ́n sì yàn án gẹ́gẹ́ bí olùdarí àgbà ti Western Nigeria Development Corporation tí a mọ̀ sí Odu'a Investment Company lọ́wọ́lọ́wọ́.
Lẹ́yìn ìdìtẹ̀gbàjọba àwọn ọmọ ológun ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kìíní, ọdún 1966, wọ́n fi Salami sí àhámọ́ fún oṣù márùn-ún [6] kí àwọn ọmọ ológun tó dá a sílẹ̀ nígbà ìdìtẹ̀gbàjọba ológun kejì ní oṣù keje ọdún 1966 .
Àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn ará Ísírẹ́lì
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Lékan Sàlámì ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú ilé-iṣẹ́ kan latí ìlẹ̀ Ísírẹ́lì Solel Boneh nípasẹ̀ ipa rẹ̀ nínú onírúurú iṣẹ́ ìdàgbàsókè ní ìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà . Salami jẹ́ ọ̀kan lára àwọn olùdarí pàtàkì nínú Western Nigerian Development Corporation (WNDC), tí ó ṣe àkóso àwọn iṣẹ́ àgbékalẹ̀ ní agbègbè náà.
Ní àwọn ọdún 1950 sí 1960, lábẹ́ ìdarí Olóyè Obafemi Awolowo àti ẹgbẹ́ Action Group, WNDC yan Solel Boneh láti ran lọ́wọ́ nínú àwọn iṣẹ́ àkànṣe pàtàkì. Gẹ́gẹ́ bí ara ìbáṣepọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú WNDC, Lékan Sàlámì kó ipa pàtàkì nínú ṣíṣàkóso àti ṣíṣe ìrànlọ́wọ́ fún àjọṣepọ̀ láàárín ilé-iṣẹ́ náà àti Solel Boneh. Iṣẹ́ rẹ̀ ran lọ́wọ́ láti rí i dájú pé a parí àwọn iṣẹ́ àkànṣe náà dáadáa àti pé yóò bá àwọn ète àti èròúngbà ìdàgbàsókè ti Ìwọ̀-Oòrùn Nàìjíríà mu.
Nítorí náà, àjọṣepọ̀ Sàlámì pẹ̀lú Solel Boneh ṣe pàtàkì nínú ìdàgbàsókè oun amáyédẹrùn àti ìdàgbàsókè ètò ọrọ̀ ajé ní agbègbè náà, nípa lílo ìmọ̀ àwọn ará ilẹ̀ òkèèrè láti fi ṣe àwọn iṣẹ́ àkànṣe ní agbègbè náà.
Sàlámì gbé àwọn ọlọ́lá àti àwọn akọ́sẹ́mọṣẹ́ Solel Boneh wá sí ilé rẹ̀, tí ó wà ní Bodìjà, Ìbàdàn. Ìbáṣepọ̀ yìí wáyé ní ọdún 1960 nígbà tí Solel Boneh ń kópa nínú onírúurú iṣẹ́ àgbékalẹ̀ ní Nàìjíríà.
Ilé yìí wà ní Bodija, Ìbàdàn, ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ilé tó gbajúmọ̀ ní Salami. Wọ́n ṣe é láti pèsè àwọn ilé gbígbé òde òní, ó sì di ibi pàtàkì fún àwọn oníṣòwò ńlá.
Olùdásílẹ̀ ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Shooting Stars
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Sàlámì jẹ́ olùfẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹgbẹ́ agbabọ́ọ̀lù ní ẹsẹ̀kùkú láti ọdún 1937 nígbà tí wọ́n dá ẹgbẹ́ agbabọ́ọ̀lù àkọ́kọ́ sílẹ̀ ní Ìbàdàn, Hercules club. Ní àwọn ọdún 1950, ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ àjọ́ tó ń rísí ìṣàkóso eré bọ́ọ̀lù aláfẹsẹ̀gbá ní ilẹ̀ Ìbàdàn (Ibadan District Football Association), àjọ kan tí ó ń ṣàkóso ẹgbẹ́ agbabọ́ọ̀lù Ibadan Lions. Nígbà tí ó wà pẹ̀lú ẹgbẹ́ náà, ó jẹ́ olùdarí ẹgbẹ́ àwọn lions àti ààrẹ ẹgbẹ́ náà lẹ́yìn náà. Yíyàn rẹ̀ sí Western Nigeria Sports Council yọrí sí fífi ẹgbẹ́ náà sílẹ̀ nítorí ìforígbárí ìfẹ́. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wà nínú ẹgbẹ́ náà, ó dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin bíi J. O Obi ó sì ṣètìlẹ́yìn owó oṣù fún àwọn agbábọ́ọ̀lù [7] ní àkókò tí eré bọ́ọ̀lù aláfẹsẹ̀gbá ní ìlú náà ṣẹ̀ṣẹ̀ ń dàgbàsokè níbití àwọn agbábọ́ọ̀lù ti ní iṣẹ́ míìrán tí wọ́n ṣe èyí sì mu kí wọn máa ra àwọn ohun èlò tiwọn.
Ní ọdún 1963, nígbà tí wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí olùdarí àgbà fún Western Nigeria Development Corporation, ó ṣètò ìnáwó fún ẹgbẹ́ WNDC Sports club tí ó wà ní Ibadan tí a mọ̀ sí WNDC Shooting Stars, IICC Shooting Stars àti 3SC. Ṣáájú ọdún 1963, wọ́n mọ ẹgbẹ́ náà sí Pepsi-Cola FC tí Pepsi-Cola ń ṣàkóso nígbà náà. [8] Ó kópa gidigidi nínú gbígba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn agbábọ́ọ̀lù sí ẹgbẹ́ náà, lára wọn ni Jide Johnson, Godwin Etemeke, Muda Lawal . Ní àwọn ọdún 1970, ẹgbẹ́ náà gba ife ẹ̀yẹ ẹlẹ́kùnjẹkùn. Ìbáṣepọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ẹgbẹ́ náà mú kí wón yàn-án alábǒjútó títí láé fún ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù náà.
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Sanni 2005, p. 6.
- ↑ Sanni 2005, p. 7.
- ↑ Sanni 2005, p. 13.
- ↑ Sanni 2005, p. 25.
- ↑ Sanni 2005, p. 27.
- ↑ Sanni 2005, p. 34.
- ↑ Sanni 2005, p. 51.
Àwọn Orísun
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Sanni, Ladi (2005). Larger than life. Ibadan: Spectrum Books.
- Ethical Issues in the Western Nigeria Development Corporation and its Israeli Partners, 1958-1966 Marklene Chinatu Ugbogu