Jump to content

Lọlá Áṣírù

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Lola Ashiru
Arc. Lola Ashiru
Senator of the Federal Republic of Nigeria from Kwara South Senatorial District
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
11 June 2019
AsíwájúRafiu Adebayo Ibrahim
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí
Oyelola Yisa Ashiru

14 Oṣù Kẹfà 1955 (1955-06-14) (ọmọ ọdún 70)
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Ẹgbẹ́ olóṣèlúAll Progressives Congress
Other political
affiliations
People's Democratic Party (until 2018)
OccupationArchitect, politician

Oyèlọlá Yísá Áshírù a bí ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹfà ọdún 1955 jẹ́ ayàwòrán ilé àti olóṣèlú ọmọ orílẹ̀- èdè Nàìjíríà, ẹni tí wọ́n yàn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin lábẹ́ àsìà ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress láti ṣojú fún agbègbè Gùùsù Kwara ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin kẹsàn-án[1][2] . Ó jẹ́ Olórí àti ọ̀gá Àgbà fún ilé iṣẹ (Capital Projects Limited), ilé-iṣẹ́ tó ń rísí dúkìá àti ọ̀rọ̀ ìkọ́lé, tí ó ní ẹ̀ka ní ìlú Èkó, Àbújá àti àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní Ìwọ̀-Oòrùn Áfíríkà .

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé rẹ̀ àti àwọn ilé ẹ̀kọ́ tí ó lọ

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Áṣírù ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹfà ọdún 1955, ní ìlú Offa, ìpínlẹ̀ Kwara, orílẹ̀ èdè Nàìjíríà . Ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Ìyẹ̀rú ọ̀kín, ní ìlú Offa, kí ó tó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ girama ti ìjọ Àgùdà (Anglican) ní ọdún 1968. Ó parí ẹ̀kọ́ girama rẹ̀ ní Federal Government College, ní ìlú Sokoto ní ọdún 1974, lẹ́yìn náà ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwòrán àyíká àti àwòrán ilé ní Yunifásítì ìlú Èkó níbi tí ó ti parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ọdún 1980.

Gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Lẹ́yìn tí ó ti díje fún ipò ní ọ̀pọ̀ ìgbà ní ọdún 2018, Ashiru kéde èrò rẹ̀ láti díje gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin fún ẹkùn ìdìbò Gúsù ti ìpínlẹ̀ Kwara ní ìdìbò gbogbogbòò ti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó wáyé ní ọdún 2019, lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú ti People's Democratic Party (PDP) [3].

Ní oṣù kẹjọ ọdún 2018, àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní Ìpínlẹ̀ Kwara, títí kan Lọlá Áshírù, fi ipò wọn sílẹ̀ lọ sí inú ẹgbẹ́ òṣèlú ti All Progressives Congress (APC) láti lè ṣe ìpolongo lòdì sí ìjẹgàba ìdile Bukola Saraki, ẹni tí ó fi ẹ̀sùn kan pé ó ń ṣàkóso ìpínlẹ̀ Kwara lọ́nà tí kò dára, fún ọdún mẹ́rìndínlógún[4].

Nínú ìdìbò abẹ́le APC, Ashiru ló borí láti ṣojú ẹgbẹ́ náà nínú ìdìbò gbogbogbò , lẹ́yìn tó ti fẹ̀yìn alátakò rẹ̀ Suleiman Ajadi janlẹ̀ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn mìíràn. Ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kejì ọdún 2019, Ashiru ló borí nínú ìdìbò gbogbogbò láti lọ sílé ìgbìmọ̀ aṣòfin pẹ̀lú ìbò tó jẹ̀ ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ̀rún-dín lẹ́gbẹ̀rún kan ati ẹ̀ẹ́ẹ́dẹ̀rin ó lé mẹ́rin, ó sì borí Adebayo Rafiu Ibrahim tó ń ṣojú ẹkùn ìdìbò náà lọ́wọ́lọ́wọ́ láti inú ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, tó ní ìbò ẹgbẹ̀rún márùndínláàádọ́ta lè lọ́gọ́jọ ó dín márùn-ún[5].

Lẹ́yìn tí a búrafun sí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Kẹsàn-án ní ọjọ́ kọkànlá oṣù kẹfà ọdún 2019, wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Ààrẹ Ìgbìmọ̀ Ilé Aṣòfin lórí Ilé [6][7] àti Igbákejì Ààrẹ Ìgbìmọ̀ Ilé lórí Àwọn Ohun Èlò Gbogbogbò ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù keje ọdún 2019. [8]

Àwọn Aṣáájú Àgbà ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Kẹwàá

Aṣòfin Áshírù Oyèlọlá Yísá ti fi agbára ìdarí tó tayọ hàn ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin kẹwàá ti Nàìjíríà. Gíga rẹ̀ kíákíá sí àwọn ipò pàtàkì fi hàn pé ó jẹ́ olùfọkànsìn, ògbóǹtarìgì, àti ìfarajìn sí iṣẹ́ ìjọba.

Àwọn ipò adarí Pàtàkì

Ní oṣù Keje ọdún 2024, wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Olórí ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Kẹwàá, èyí tó fi agbára rẹ̀ hàn láti mú kí ìfọwọ́sowọ́pọ̀ àti láti mú kí ìlọsíwájú ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin rọrùn. Ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kẹwàá ọdún 2024, wọ́n gbé e ga sí ipò Igbákejì Olórí ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin, èyí sì tún mú kí agbára àti ipò aṣáájú rẹ̀ lágbára sí i nínú Ìgbìmọ̀ Aṣòfin.

Alága Ìgbìmọ̀ àkànṣe iṣé

A fi ojúse pàtàkì kan lé Aṣòfin Áṣírù Oyèlọlá Yísá lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí Alága ìgbìmọ̀ aṣòfin tó ń ṣe ìwádìí lórí àwọn iṣẹ́ ìjọba àpapọ̀ tí wọ́n ti kọ̀ sílẹ̀. Iṣẹ́ yìí fi hàn pé ó jẹ́ olùfẹ́ láti ṣe àfihàn, láti fi hàn pé òun jẹ́ olóòtọ́, àti láti máa ṣe ìjọba rere.

Ìgbìyànjú ìpànìyàn

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Nígbà ètò ìpolongo ìbò lọ sí Ojoku ní agbègbè Oyun nì ìpínlẹ̀ Kwara nì ogùnjọ oṣù kejì ọdún 2019, Áṣírù àti àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ni àwọn jàǹgùkú dojúkọ àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú APC fẹ̀sùn kan ẹgbẹ́ òṣèlú PDP wípé àwọn alátìlẹyìn wọn ni wọ́n ṣe iṣẹ́ láabi náà níbití wọ́n ti pa méjì lára àwọn olólùfẹ́ óhun[9].

Ojoku ni ìlú Adébàyọ̀ Rafiu Ibrahim, ẹni tó ń díje fún ipò Aṣòfin ní gúúsù ìpínlẹ̀ Kwara ní ìdìbò gbogbogbòò Nàìjíríà ní ọdún 2019. Ní ọjọ́ kejìlélógún oṣù kejì ọdún 2019, wọ́n mú Adébáyọ̀ Rafiu Ibrahim, Aṣòfin tó wà ní gúúsù ìpínlẹ̀ Kwara nítorí ìkọlù tí wọ́n ṣe sí Áṣírù àti àwọn alátìlẹ́yìn rẹ̀[10].

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]