Lagos Book and Art Festival
Lagos Book and Art Festival (LABAF) jẹ́ ayẹyẹ ọlọ́dọọdún tí ó dá lórí Ayẹyẹ Iṣẹ́-ọnà tí àwọn ìgbìmọ̀ tó ń rí sí iṣẹ́-ọnà tó péye ń ṣe ṣagbátẹrú dá sílẹ̀ ní ọdún 1999 Committee for Relevant Art (CORA), tí wọ́n fi ìdí ẹgbẹ́ múlẹ̀ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà .
Ìtàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àgbéjáde àkọ́kọ́ fún ayẹyẹ náà wáyé ní oṣù Kọkànlá ọdún 1999 ní Jazz 38’s permanent site ní Lekki, ní Ìpínlẹ̀ Èkó. Èrò tó wà lẹ́yìn ayẹyẹ náà ni láti ṣe ìrántí ìpadà Nàìjíríà [1] sí ìjọba aládàáni lẹ́yìn bíi ọgbọ̀n ọdún tí ìjọba ológun ti ń ṣàkóso, àti láti ní ayẹyẹ kan tí yóò jẹ́ kóríyá tí yóò sì tún kó àwọn ọdọ àti àgbàlagbà níjàánu, pàápàá jùlọ lórí àṣà ìwé kíkà ìwé tí ó ti ń dìmẹ́rí díẹ̀díẹ̀.Wọ́n pè é ní "Píkníkì Àṣà tó tóbi jù lọ ní Áfíríkà.”. "Africa’s biggest culture picnic",[2] Lagos Book and Art Festival máa ń wáyé fún ọjọ́ méje[3] ní oríṣìíríṣìí ibi bíi Goethe-Institute ,British Council , .[4] àti Freedom Park,gbogbo àwọn ibùdó yìí wà ní Ìpínlẹ̀ Èkó
Ìgbéléwọ̀n Ayẹyẹ Náà
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]LABAFLagos Book and Art Festival (LABAF) máa ń ṣàfihàn ọ̀pọ̀ iṣẹ́ àti ìṣẹ̀lẹ̀ oríṣìíríṣìí, pẹ̀lú àwọn ìṣe ṣáájú ayẹyẹ bíi ìrìn-àjò ìwé (book treks)[5] àti àwọn àjọ̀dún pàtàkì míì bíi orin ìdárayá, ìwé kíkà ní gbangba,[6] ìfihàn fíìmù, Àpéjọ àwọn ìwé, Ìtà] ìfihàn fíìmù, àpéjọ àwọn akéde ìwé (publishers’ forum), àfihàn ìwé àti iṣẹ́ ọnà, ìjíròrò pánẹ́lì, àpéjọ ìmọ̀ (colloquiums),àpéjọ ìwádìí (symposiums), àfihàn ìtẹ̀jáde ìwé, àfihàn àṣà, àyẹ̀wò ìwé, ayẹyẹ aláwọ̀ ewé (green festival)àti ọ̀pọ̀ iṣẹ́ míì. Ayẹyẹ náà tún ń jẹ́ kí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé-ẹ̀kọ́ alákọ́ọ́bẹrẹ, ilé-ẹ̀kọ́ girama àti àwọn yunifásítì ní Nàìjíríà kópa, nípa fífi àwọn ìdíje àti àǹfààní ìtọ́sọ́nà (mentoring) .[7] Wọ́n fi àkòrí yìí sọrí Òṣèré kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ David Dale ní ìrántí rẹ̀,[8] who diìwé ìíràn tí ó ń jẹyọ gẹ́gẹ́ bíi Ìwé ayẹyẹdifftí ó sì kó ipe nínú àjọyọ̀ ọdún náà. ding Pius Adesanmi, Eddie Ugbomah, Bisi Silva,. Àkòrí ayẹyẹ náà ní ọdún un 2017 ni Eruptions: Global fractures and the out common humanity, nígbà tó di 2018 wọ́n sọ ọ́ ní Renewal: Towards a world that works for all.[9] Àsìkò ọdún yìí ni wọ́n tún máa ń ṣe àtúngbéyẹ̀wò àwọn ìwé, fíìmù, àwọn ohun àjogúnbá, iṣẹ́ àkànṣe,eré onítà àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìjábọ̀ iṣẹ́ àkànṣe kí ó ba lè jẹ́ kóríyá fún tonílé tàlejò.
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Lagos Book & Art Festival, (LABAF) set for November 4-10, 2019". The Lagos Review (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2019-10-27. Retrieved 2020-08-06.
- ↑ "LABAF: Nigeria on hot seat at Culture Picnic". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2012-11-21. Retrieved 2020-08-06.
- ↑ "A Week of 52 Engaging Events With Loads of Lessons for the Youths". guardian.ng. Retrieved 2020-08-06.
- ↑ Murua, James (2015-11-16). "British Council's publishing Creative Hustle at the Lagos Theatre #LABAF2015". Writing Africa (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2024-05-11.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
- ↑ Roqeebah (2016-11-11). "Catch up with the 18th Lagos book and art festival (LABAF) » YNaija". YNaija (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-08-06.
- ↑ Olorunsola, Moyosoluwa (2019-09-14). "LABAF to hold in November" (in en-GB). Daily Trust. https://www.dailytrust.com.ng/labaf-to-hold-in-november.html.
- ↑ "Book and Art Festivals in Nigeria worth Traveling for in 2019". Jumia Food Nigeria Blog (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2019-03-21. Retrieved 2021-08-11.
- ↑ "David Dale, Renowned British-Nigerian Artist, Dies at 71 – THISDAYLIVE". This Day. https://www.thisdaylive.com/index.php/2019/08/07/david-dale-renowned-british-nigerian-artist-dies-at-71/.
- ↑ read 1, News 1 min (2019-10-27). "Lagos Book & Art Festival, (LABAF) set for November 4-10, 2019". The Lagos Review (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2021-08-11.