Jump to content

Magaji Muhammed

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Magaji Muhammed
Federal Minister of Industry, Nigeria
In office
May 2003 – 13 July 2005
AsíwájúStephen Akiga
Arọ́pòFidelis Tapgun
Federal Minister of Internal Affairs
In office
13 July 2005 – June 2006
AsíwájúIyorchia Ayu
Arọ́pòOluyemi Adeniji
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí(1940-12-31)31 Oṣù Kejìlá 1940
Dutsin-Ma, Katsina State, Nigeria
AláìsíApril 2017 (age 76)
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeople's Democratic Party (PDP)

Magaji Muhammed (tí a bí ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kejìlá ọdún 1940 – oṣù kẹrin ọdún 2017 [1] [2] ) ló jẹ olórí ilé iṣẹ́ ìjọba àpapọ̀ ti orílẹ-èdè Naijiria títí di oṣù kẹfà ọdún 2006, nígbà ti o fipò silẹ̀ láti lépa èròngbà Gómìnà, Oluyemi Adeniji lo si tẹ̀lé e. O tun jẹ Mínísítà tẹ́lẹ̀ rí fún Àwọn ile-iṣẹ. [3]

A bi Magaji Muhammed ni ọjọ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kejìlá ọdún 1940 ni Dutsin-Ma, ni ìpínlẹ̀ Katsina . Ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ Fásítì Ahmadu Bello, ní Zaria gẹ́gẹ́ bí aṣáájú-ọ̀nà àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ti fásitì náà, níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí BA ní ìṣàkóso. Láti ọdún 1965 si 1975, o jẹ Alakoso agbègbè ni alábojútó ẹka Idoma, Wukari ati Tiv ti àríwá Nàìjíríà, ati Alákoso Ìrànlọ́wọ́ Akọ̀wé, Ọfiisi Gómìnà ológun, Kaduna . O tun ṣiṣẹ bi Alakoso, orísun ìṣèjọba àpapọ Kaduna. Ni ọdún 1975, o di Akọ̀wé láíláí. O darapọ̀ mọ Iṣẹ Abẹle ti ijọba àpapọ ni ọdún 1980 ati pe o jẹ Oludari, Imuse iṣẹ, mínísítírì ìjọba àpapọ̀ fún àwọn ilé iṣẹ́ àti Olùdarí, ètò àlọ-àbọ̀ àti àwọn ilé iṣẹ́, mínísítírì ìjọba àpapọ̀ fún ètò ọrọ̀ ajé àti àwọn ilé iṣẹ́. [4]

Ìṣèjọba Obasanjo

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Muhammed jẹ Aṣojú Nàìjíríà, tó kájùẹ̀ sí ìṣèjọba orilẹ èdè Saudi Arabia láti ọdún 2000 sí 2003. [5] Aarẹ Olusegun Obasanjo yán an ni Mínísítà fún Ile-iṣẹ ni Oṣù Kàrún ọdún 2003 ati ni ọdún 2005 o jẹ mínísítà fún ọrọ abẹnu ti ìjọba àpapọ̀. Magaji jẹ alárinrin ènìyàn àti ènìyàn tí ó dára jùlọ gẹgẹbi mínísítà ti ọrọ inú ìlú, ni àkókò rẹ ni ètò kaadi ìdánimọ̀ orílẹ-èdè àti pínpín ti pọ̀ si láti de gbogbo igun orílẹ-èdè náà. Bakan náà ni àkókò rẹ gẹgẹ bi mínísítà ètò ọrọ abẹ́lé ti ṣe atunto ajọ ààbò ati ààbò ará ìlú Naijiria ti wọn si fún ni iṣẹ àfikún ni ijọba apapọ.

Ni oṣù karùn-ún ọdún 2006, Mohammed ati akegbe rẹ Idris Waziri mínísítà fún ọ̀rọ̀ oko-òwò kọwe fipò silẹ láti díje du àwọn Gómìnà ìpínlẹ̀ wọn nítorí òfin ni pé àwọn ti wọn yán fún ipò kàn nínú òṣèlú ni láti kọwe fi ipò wọn sílẹ ti wọn ba ní láti díje fún ọfiisi ìdìbò èyíkéyìí nígbà náà.