Mo Abudu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Mo Abudu
Ọjọ́ìbí11 Oṣù Kẹ̀sán 1964 (1964-09-11) (ọmọ ọdún 59)
London, United Kingdom
Ẹ̀kọ́Ridgeway School
MidKent College
West Kent College
University of Westminster
Iṣẹ́Media proprietor
Websiteebonylifetv.com

Mosunmola Abudu, tí orúkọ ìnagijẹ rẹ̀ ń jẹ́ Mo Abudu, tí ó sì jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà jẹ́ ògbóǹtarìgì agbóhùnsáfẹ́fẹ́, ẹlẹ́yinjú àánú, onímọ̀ràn ìṣàkóso àwọn òṣìṣẹ́ àti ẹni tí a mọ̀ mọ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́.[1][2] Forbes fi Mo Abdul hàn gẹ́gẹ́ bíi obìnrin ilẹ̀ Adúláwọ̀ tó lọ́lá jù lọ ni.[3][4]

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé àti ètò-ẹ̀kọ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Abudu sí Hammersmith ní apá Ìwọ̀-oòrùn ní London.[1] UK ni ó ti ṣe èwe. Ó sì lọ sí Ridgeway School, MidKent College àti West Kent College. Ó gboyè Master's degree nínú Human Resource ManagementLondon.

Iṣẹ́ tí ó yàn láàyò[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Iṣẹ́ rẹ̀ ní EbonyLife TV[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọdún 2006,Abudu bẹ̀rẹ̀ EbonyLife TV,[5][6][7] ètò ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ó tàn ká orílẹ̀-èdè tó ju ọkàndínláàádọ́ta lọ ní ilẹ̀ Adúláwọ̀ àti ní UK àti Caribbean.[8] Ó jẹ́ ètò kan lábẹ́ Media and Entertainment City Africa (MEC Africa). EbonyLife TV wà ní Tinapa Resort ní Calabar, Ìpínlẹ̀ Cross Rivers, orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Ní ọdún 2018, Sony Pictures Television (SPT) kéde àṣẹ̀ṣẹ̀yanjú ìfọwọ́sowọ́pọ̀ ọlọ́dún mẹ́ta pẹ̀lú EbonyLife TV tí ó máa ní ṣe pẹ̀lú gbígbé fíìmù The Dahomey Warriors jáde.[9]

Iṣẹ́ rẹ̀ mìíràn; EbonyLife Films[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Abudu dá EbonyLife Films sílẹ̀. Àkọ́lé fíìmù tí ó kọ́kọ́ gbé jáde ni Fifty. Ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ELFIKE ní ọdún 2016 láti gbé fíìmù The Wedding Party jáde.[10]

Moments with Mo[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Abudu jẹ́ olóòtú àti ẹni tó gbé ètò "Moments with Mo" kalẹ̀ tí ó jẹ́ ètò ojoojúmọ́ àkọ́kọ́ tí ó hàn káàkiri ilẹ̀ Adúláwọ̀ lórí afẹ́fẹ́.[11][12]

Abudu with US Secretary of State Hillary Clinton

Ní ọdún kẹwàá ọdún 2009, a ti rí tó igba ìgbà tí ètò tí ó gbé sórí afẹ́fẹ́ hàn lórí afẹ́fẹ́. Àwọn ètò orí afẹ́fẹ́ náà máa ń dá lé lórí ìgbésí ayé ẹ̀dá, ètò-ìlera, àṣà, ètò-òṣèlú, eré-ìdárayá, ìṣe, orin àti ọ̀rọ̀ lórí ìgbéyàwó láàárín ẹ̀yà méjì. Wọ́n ti gbé àwọn olókìkí èèyàn lóríṣiríṣi, Ààrẹ orílẹ̀-èdè àti àwọn èèyàn tó lórúko sórí ètò náà.[1][13]

The Debaters[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Abudu jẹ́ olùdásílẹ̀ àti ẹni tó gbé ètò The Debaters jáde. Ó jẹ́ ètò tí Guaranty Trust Bank ń ṣàkóso nípa ètò ìṣúná. Ọjọ́ kẹta oṣù kẹwàá ọdún 2009 ni wọ́n dá a sílẹ̀. Ètò náà dá lé lórí "fífún ilẹ̀ Adúláwọ̀ ni ohùn kan" nípa gbígbé ọ̀rọ̀ sísọ lárugẹ.[14]

Àwọn Àṣeyọrí rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Forbes Africa fi Abudu hàn bíi obìnrin Adúláwọ̀ àkọ́kọ́ láti ni Pan-Africa TV channel ní ọdún 2013.[15][16] Wọ́n kà á mọ́ ọkàn lára àwọn obìnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n tó lọ́lá jù lọ lórí Global TV láti owó oníròyìn Hollywood ní ọdún 2013.[17] and received the Entrepreneur of the Year award by Women Werk in New York (2014).[18] Ní ọdún 2014, Babcock University dá a lọ́lá pẹ̀lú Honorary Doctor nínú Humane Letters.[19] Ní ọdún 2019, wọ́n dá a lọ́lá pẹ̀lú Médailles d'Honneur ti MIPTV 2019 ní Cannes, ìlú France. Èyí sì jẹ́ kó jẹ́ obìnrin ilẹ̀ Adúláwọ̀ àkọ́kọ́ tó gba àmì ẹ̀yẹ náà.[20] Bákan náà, wọ́n kà á mọ́ ọkàn lára ọgọ́rùn-ún obìnrin tí ó lọ́lá jù lọ lórí 2020 Powerlist ní UK láti ilẹ̀ Adúláwọ̀.[21]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. 1.0 1.1 1.2 Smallman, Etan (16 November 2013). "Meet Africa's Oprah: Why Mosunmola 'Mo' Abudu wants to change the world's view of her continent". Independent. Retrieved 17 August 2016. 
  2. Florence Amagiya (2 August 2014). "Mo Abudu, the pie that made her rich". The Vanguard. http://www.vanguardngr.com/2014/08/mo-abudu-pies-made-rich/. Retrieved 1 April 2015. 
  3. Funsho Arogundade (9 January 2015). "Mo Abudu Is Forbes Africa's Most Successful Woman". Prime News. http://www.pmnewsnigeria.com/2015/01/09/mo-abudu-is-forbes-africas-most-successful-woman/. Retrieved 31 March 2015. 
  4. "Africa's Most Successful Women: Mo Abudu". Forbes. 1 January 2015. Retrieved 28 March 2015. 
  5. "MIPCOM: The 25 Most Powerful Women in Global TV". The Hollywood Reporter. 4 October 2013. http://www.hollywoodreporter.com/lists/mosunmola-abudu-642527. Retrieved 1 March 2014. 
  6. "Meet the hosts of Moments". DStv. 26 June 2015. Retrieved 17 August 2016. 
  7. "Nigerian woman launches tv network". 
  8. Michelle Cohan and Nosmot Gbadamosi. "The Nigerian Media mogul with a global empire". CNN. Retrieved 2017-09-04. 
  9. Giles, Chris. "Nollywood, Sony Pictures join forces for TV series on all-female African army". CNN. https://edition.cnn.com/2018/03/29/africa/nollywood-hollywood-female-african-tv-show/index.html. 
  10. "'The Wedding Party' rakes in over N400m in ticket sales" (in en-US). https://guardian.ng/life/film/the-wedding-party-rakes-in-over-n400m-in-ticket-sales/. 
  11. Faul, Michelle (2 July 2013). "'Africa's Oprah' Mo Abudu launches TV network in Nigeria". Thestar.com. Retrieved 17 August 2016. 
  12. Enengedi Victor (10 June 2013). "ET Exclusive: Mo' Abudu launches N2bn TV channel". Nigerian Entertainment. Net newspapers. p. 1. Archived from the original on 19 April 2014. Retrieved 27 March 2014.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  13. "Grand launch for Mo-ments with Mo". 31 October 2007. Retrieved 31 October 2007. 
  14. "The Debaters... new on screen". 23 July 2009. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  15. "Mo Abudu Africa's queen of talk - Forbes Africa" (in en-US). Forbes Africa. 2013-10-01. https://www.forbesafrica.com/entreprenuers/2013/10/01/mo-abudu-africas-queen-talk/. 
  16. "[1] Archived 23 August 2013 at Archive.is. The Guardian (Nigeria)
  17. "Mosunmola Abudu - MIPCOM: The 25 Most Powerful Women in Global TV" (in en). The Hollywood Reporter. http://www.hollywoodreporter.com/lists/mipcom-25-powerful-women-global-642526/item/mosunmola-abudu-25-powerful-women-642527. 
  18. "International Women's Day: Mo Abudu wins Entrepreneur of the Year - The Nation Nigeria" (in en-US). The Nation Nigeria. 2014-03-11. http://thenationonlineng.net/international-womens-day-mo-abudu-wins-entrepreneur-of-the-year/. 
  19. "Mo Abudu Receives Honorary Doctorate from Babcock University - BellaNaija". www.bellanaija.com (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2017-09-04. 
  20. "Nigerian media mogul Mo Abudu receives 2019 Médailles d'Honneur at MIPTV - Screen Africa" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-12-13. 
  21. Mills, Kelly-Ann (25 October 2019). "Raheem Sterling joins Meghan and Stormzy in top 100 most influential black Brits". mirror. Retrieved 20 April 2020.