Jump to content

Mohammed Umar Bago

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Mohammed Umaru Bago
Gómìnà ìpínlẹ̀ Niger
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
29 May 2023
DeputyYakubu Garba
AsíwájúAbubakar Sani Bello
Aṣojú fún
Aṣojú ilè ìgbìmò aṣòfin tí orilẹ ède Nàìjíría
láti Niger
In office
Ọjọ kẹfà oṣù kẹfà ọdún 2011  Ọjọ kọkàndínlọ́gbàn oṣù kàrún ọdún 2023
ConstituencyChanchaga
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí
Mohammed Umar Bago

Àdàkọ:Ọjọ ibi àti ọmọ ọdún
Minna, North-Western State (now in Niger State), Nigeria
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Ẹgbẹ́ olóṣèlúAll Progressives Congress
ResidenceMinna
Occupation
  • Olóṣèlú
  • òṣìṣẹ́ ilè ìfowópamọ́

Mohammed Umar (ti a bi ní ọjọ kéjìlélógún oṣù kejì ọdún 1974) jẹ oṣiṣẹ ilè ìfowópamọ́ ati olóṣèlú ọmọ Nàìjíríà ti o jẹ gomina lọwọlọwọ ni Ìpínlè Niger lati ọjọ kọkàndínlọ́gbàn oṣù kàrún ọdún 2023.

A bi sí Minna, Ìpinlẹ̀ Niger, si idile Tápà . [1] O jẹ ọmọ ẹgbẹ ti Ile-igbimọ Aṣoju ti o nsoju agbègbè chanchaga lọdọ Ìjọba àpapọ̀[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́][2][3]. Mohammed Bago lo jáwé olúborí nínú ìdìbò gómìnà tí ọdún 2023 ni Ìpínlè Niger lẹyìn ti o borí Isah Liman Kantigi ti ẹgbẹ́ òṣèlú PDP . [4]

Ìbẹrẹ ìgbésí ayé ati ẹkọ

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bi ni ọdún 1974, Hon. Umar Bago lọ si ilè ìwé alákọbẹ̀rẹ̀ Marafa Primary School, Minna àti Federal Government College, Jos. O gbá iwe-ẹri ile-iwe àpapọ tí iwọ òòrùn afrika lati ọ̀dọ̀ WAEC . O ti gbá oye ìyẹ̀wù àkọ́kọ́ nínú ìmọ òṣèlú ni fasiti Usman Danfodio, Sokoto . [5]

Hon. Umaru Bago ti gbá ọ̀pọ̀lọpọ̀ awọn ìwé-ẹ̀rí Ìdánilẹ́kọ́ lẹ́yìn Ìyẹ̀wù Àkọ́kọ́ ati awọn ìwé-ẹ̀rí Ìyẹ̀wù kejì si, pẹlu ìwé-ẹ̀rí giga nínú ìsàkóso lati Federal University of Technology Minna ni ọdún 2001, o tún gba ìwé ẹ̀rí ìyẹ̀wù kejì nínú ìṣàkóso ọrọ̀ ajé àti ìmọ̀ ìdàgbàsóke ni fásítì Ambrose Ali ni Ekpoma ni ọdún 2003, àti ìwé ẹ̀rí ìyẹ̀wù kejì nínú ìṣàkóso owó ni fásítì Calabar ni ọdún 2005. O tún jẹ akẹ́kọ́ pari láti ilè ìwé fásítì Cambridge ni òke okùn ni ọdún 2014[6].

Bago ṣiṣẹ pẹlú ilè ìfowópamọ́ United Bank for Africa (UBA), First City Monument Bank (FCMB) ati Afri-Bank PLC lẹsẹsẹ. O ṣiṣẹ bi oluṣakoso ni First city Monument Bank . [7] O darapọ mọ òṣèlú ni àfihàn ni ọdún 2007.

Àwọn ipó nínú oselu

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

O díje fún ipò Agbọrọsọ ti Ile-igbimọ Aṣofin Naijiria ti o ṣe ipo keji si Femi Gbajabiamila ni Ile-igbimọ Aṣofin kẹsán . [8] O sọ pe, "Emi kii yoo fẹyinti, Mo kan fẹ lati ṣe àtúnṣe àṣìṣe ti awọn oludari ẹgbẹ nipasẹ ero dídarí sí awọn agbegbe." [9]

O ṣe alága Ìgbimọ Ile lori Aabo Maritime, Ẹkọ ati Ìṣàkóso. Ni ọdún 2016 o gba awọn ìṣàkóso ti ìgbìmò àṣẹ ti Maritime niyanju pe awọn oṣiṣẹ mẹ́tàlélọgọrin ni oyẹ ki won yọnda kúrò lẹnu iṣẹ wọn. O sọ pe, “Iyẹn ni bi awọn jàndùku ṣe n gbaṣẹ.” [10] [11] O rọ NIMASA láti ló owó pẹlú ọgbọ́n ni ọ̀nà tó da pẹlú igbaradi. [12] O jawe olubori ninu idibo ìpìlẹ tí gomina nínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC ni Ìpínlẹ̀ Niger ṣáájú ìdìbò gbogboògbò tí ọdún 2023. O jáwé olúborí nínú ìdìbò gómìnà lẹyìn ti o ri ibo 469,896 jù ẹni to sunmọ lọ Alhaji Isah Liman Kantigi to ri ibò 387,476. [13]

Ìgbésí ayé ara ẹni àti alaanu

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Bago ti ni ìyàwó pẹlú àwọn ọmọ. Iya rẹ, Hajiya Aisha Mohammed, ku ni ọjọ kínní Oṣù Kàrún ọdún 2019 lẹhin àìsàn ránpẹ́. [14]

Láti mu ìlọsíwájú ètò ẹ̀kọ́ agbègbè rẹ dara, o ra awọn fọọmu ẹgbẹ̀rún kàn ti JAMB fun awọn eniyan rẹ. [15] Ati pe o tun pin awọn ẹru tirela mọkanla ti o kún irẹsi si agbègbè rẹ gẹgẹ bi ìtura lakoko ajakaye-arun COVID-19. [16]