Mojisola Adekunle-Obasanjo
| Mojisola Adekunle-Obasanjo | |
|---|---|
| Birth name | Mojisola Adekunle |
| Born | 10 Oṣù Kẹjọ 1944 British Nigeria |
| Died | 4 June 2009 (ọmọ ọdún 64) Lagos, Nigeria |
| Allegiance | |
| Service/branch | |
| Rank | |
Mojisola Adekunle-Obasanjo (Ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹjọ ọdún 1944 – ọjọ́ kẹrin oṣù kẹfà ọdún 2009) jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ ilẹ̀ iṣẹ́ ológun àti olóṣèlú ní orílè-èdè Nàìjíríà. Ó dá ẹgbẹ́ òṣèlú Masses Movement of Nigeria (MMN) sílẹ̀ ní ọdún 1998, èyí tí ó díje lábẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùdíje fún ipò ààrẹ ní ìdìbò ọdún 2003, èyí tí ó jẹ́ obìnrin kàn ṣoṣo tí ó dije nínú ètò ìdìbò fún ìdìbò ààrẹ ní ọdún 2007.[1] Ó tún jẹ́ ìyàwó Ààrẹ orílè-èdè Nàìjíríà nígbà kàn rí ààrẹ Olusegun Obasanjo.[2] Adekunle-Obasanjo kú ní ọjọ́ kẹrin oṣù kẹfà ọdún 2009, ní ilé ọmọbìnrin rẹ̀ ní Ikoyi, Èkó lẹ́yìn àìsàn díẹ̀.[3] Ó ní ọmọ mẹ́rin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ọmọ.
Ìrìnàjò òṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Mojisola ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí onímọ̀ nípa rédíò pẹ̀lú ẹgbẹ́ ọmọ ogun Nàìjíríà fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ rẹ̀ kí ó tó fẹ̀yìntì láti dije fún ipò ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.[4] Ní ọdún 2003, Mojisola díje gẹ́gẹ́ bí olùdíje ààrẹ nínú ètò ìdìbò orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó gba àpapọ̀ ìbò 157,560 èyí tí ó dọ́gba pẹ̀lú 0.40% àwọn ìbò tí a fọwọ́ sí.[5] Ó tún díje nínú ètò ìdìbò orílè-èdè Nàìjíríà ti ọdún 2007, nibiti o tún tí fi ìdí remi.[6]
- ↑ Celestine Okafor (April 3, 2004). "We’ll mobilise the masses, says Moji Obasanjo!". Vanguard media. http://news.biafranigeriaworld.com/archive/2004/apr/03/0041.html. Retrieved April 22, 2014.
- ↑ James Ezema. "Women in Politics: Challenges, and the Rwandan Example". Newswatch Times. http://www.mynewswatchtimesng.com/women-politics-challenges-rwandan-example/. Retrieved April 22, 2015.
- ↑ Godwin Mbachu (March 5, 2015). "Female Presidential Candidates: How Far can They Go?". Leadership News. Archived from the original on June 11, 2016. https://web.archive.org/web/20160611102458/http://leadership.ng/news/415316/female-presidential-candidates-how-far-can-they-go!. Retrieved April 22, 2015.
- ↑ All Africa. "Nigeria: Moji Obasanjo Dies at 65". AllAfrica.
- ↑ Gupta, K.R (2005). Studies in World Affairs, Vol. 1 (1 ed.). India: Atlantic Publishers & Distributors (P) Ltd.. p. 116. ISBN 9788126904952.
- ↑ Sahara Reporters. "Major Moji Obasanjo is Dead!-PM News, Lagos". Sahara Reporters. Retrieved 11 March 2019.