Jump to content

Nimbe

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

 

Nimbe tí a tún mọ̀ sí Nimbe: Eré náà jẹ́ eré orí-ìtàgé ọdún 2019 Nàìjíríà tí Tope Alake darí rẹ̀. Gbajúgbajà òṣèré fíìmù náà ni Chimezie Imo, Toyin Abraham, Rachael Okonkwo àti Doyin Abiola . [1] asájú oṣere Chimezie Imo ní o kópa olú-èdá ìtàn nínú eré náà àti pé ìtàn náà dá lórí ìlòkulò òògùn. Fíìmù náà ni a gbé jáde sí orí ìtàgé ní Nàìjíríà ní ọjọ́ kọkàndinlọ́gbọ̀n Oṣù Kẹta ọdún 2019 àti pé o gba àwọn àtúnyẹwò rere láti ọ̀dọ̀ àwọn aláriwisi. [2] Fíìmù náà di wà niwájú láàrín àwọn fíímù tí ó jáde nínú pop box nla àti pé o jẹ ọ̀kan nínú awọn fíìmù àṣeyọrí Nàìjíríà fún ọdún 2019 . Fíìmù náà wà ní ipò kokàndínlọ́gọ́ta 59th ní atokọ gbogbogbò ti àwọn fíìmù ti o n wọlé ga jùlọ ní Naijiria . Wọn tún yan fíìmù náà fún Aamì Ẹ̀yẹ Fíìmù Nólíwùdù UK ti ọdún 2019. [3]

Àkòrí fíìmù náà dá lórí ọmọdékùnrin ọ̀dọ́ kan Nimbe (Chimezie Imo) tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ máa n dálára yá nígbàgbogbo ṣùgbọ́n láànú ri ìtùnú, ìfẹ àti ìbáramu nínú ẹgbẹ́ oníjàgídíjàgan ti òpópónà ti o ṣàfihàn nípasẹ aládúgbò alàgbà kan ti o ba pàdé. Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ǹkan yípadà bi o ti ṣàfihàn sí ọna ti o léwu ti gbígbé oògùn olóró káàkiri ti o di aayé ìyípadà nínú ìgbésí ayé rẹ̀. O ni ìrírí àti jẹrìí àwọn ìtaláyà ti o tẹle e, àwọn idiwọ àti àwọn àbájáde ti o ní nkan ṣe pẹ̀lú ìlòkulò oògùn. [4]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. https://thenationonlineng.net/odunlade-adekola-other-actors-expose-problems-of-drug-abuse-in-nimbe/
  2. https://medium.com/@pelumiwrites/nimbe-a-visual-decode-of-vulnerable-teenage-boys-movie-review-b75365b50429
  3. https://www.premiumtimesng.com/entertainment/nollywood/355899-six-nollywood-movies-nominated-for-2019-uk-film-festival-award.html
  4. https://www.nollywoodreinvented.com/2019/03/coming-soon-nimbe.html