Jump to content

Oba (ruler)

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Ọba[1][2] jẹ́ orúkọ oyè ẹ̀yẹ tí a fi ń pe àwọn alákòóso tàbí aládé ní ilẹ̀ Yorùbá, àti nípasẹ̀ ìgbòòrò, ní Ìjọba Benin.

Gẹ́gẹ́ bí ìtàn àtẹnudẹ́nu Yorùbá, ọba àkọ́kọ́ ni Oduduwa, akọni ìwáṣẹ̀ tí ó jẹ́ orírun àwọn ọmọ Yorùbá. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdílé ọba ni wọ́n sọ pé wọ́n ṣẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, nínú èyí tí a ti rí Ọọ̀ni ti Ìfẹ̀, Aláàfin ti Ọ̀yọ́, Awùjálẹ̀ ti Ìjẹ̀bú, Ọba ti Benin, Olú ti Warri àti àwọn mìíràn.[3][4] Àwọn Ọba máa ń ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí aṣáájú nípa tẹ̀mí, àṣà, àti nígbà míràn nípa ìṣèlú fún ìlú tàbí ìjọba wọn. Ní àsìkò ti òde-òní, àwọn Ọba jẹ́ ẹni àpọ́n-lé tí wọ́n ń tọpasẹ̀ ìran wọn padà sí àwọn ìjọba Yorùbá ti ìṣẹ̀báyé, pápá jùlọ Ilé-Ìfẹ̀, èyí tí a gbà gẹ́gẹ́ bí orírun tẹ̀mí àti ìtàn fún gbogbo Yorùbá.[5] Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yà Ẹdó ni Ìjọba Benin tí kò sì sí ní abẹ́ ilẹ̀ Yorùbá, ìran ọba wọn náà tọpasẹ̀ orírun wọn lọ sí Ilé-Ìfẹ̀.[6]

Oyè yìí yàtọ̀ sí oyè Olóyè ní ilẹ̀ Yorùbá, èyí tí àwọn ìjòyè abẹ́ ọba máa ń lò nínú ètò ìṣèjọba ìbílẹ̀.[7]

Ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìtàn oyè Ọba

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ilé-Ìfẹ̀, tí a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọkàn ẹ̀mí àti àṣà àwọn Yorùbá, ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ tẹ́wọ́gbà gẹ́gẹ́ bí ìpilẹ̀ṣẹ̀ oyè Ọba àti ètò ìjọba aládé. Gẹ́gẹ́ bí ìtàn Yorùbá, Ilé-Ìfẹ̀ ni Odùduwà ti sọ̀kalẹ̀ láti Òkè Ọrà tí ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í darí àwọn ènìyàn, nípa dídá ètò ìjọba aládé sílẹ̀. Ìgbà ìjọba Odùduwà ni ètò ọba bẹ̀rẹ̀, tí orúkọ náà "Ọba" sì di kòṣeémáàní fún oyè aṣáájú kárí ilẹ̀ Yorùbá.[8]

Àwọn oyè ọlá láàárín àwọn Yorùbá

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A lè pín ètò oyè Yorùbá sí ìpele mẹ́rin: àwọn ọba (royal chiefs), àwọn ìjòyè ńlá (noble chiefs), àwọn aṣáájú ẹ̀sìn (religious chiefs) àti àwọn olórí ìlú/àdúgbò (common chiefs). Àwọn ọba ni wọ́n wà ní orí pátápátá, àwọn sì ni orísun ọlá (fons honorum) fún gbogbo ètò náà. Wọ́n tún wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ọba tó jẹ oyè nínú ìdílé ọba. Àwọn ìpele mẹ́ta tókù, tí wọ́n ń pèsè aṣojú fún àwọn ìgbìmọ̀, ẹgbẹ́ àti ọ̀gbà, ni wọ́n ń rí sí ìṣàkóso ojoojúmọ́ láàárín ìlú. Àwọn tó ń darí wọ́n ni àwọn ìwàrẹ̀fà (nínú ẹgbẹ́ Ògbóni), àwọn àràbà (nínú ẹgbẹ́ Babaláwo), àti àwọn àgbààgbà ìlú.[9]

Ọba Abessan Karùn-ún, Oníkòyí ti Porto-Novo, Benin

Oríṣi ọba méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ló wà ní ilẹ̀ Yorùbá: Àwọn ọba tí wọ́n ń darí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìlú tó wà ní ìṣọ̀kan (Bí àpẹẹrẹ, ọba àwọn ẹ̀yà Ẹ̀gbá ń jẹ́ "Aláké" nítorí pé orírun rẹ̀ wà ní agbègbè Aké ní Àbẹ́òkúta; nítorí náà Aláké túmọ̀ sí Ẹni tó ni Aké. Bákannáà, ọba Ọ̀yọ́ ń jẹ́ "Aláàfin", tí ó túmọ̀ sí Ẹni tó ni ààfin) àti àwọn ọba tó ń darí ìlú kan ṣoṣo, gẹ́gẹ́ bí i ti Ìwó — ìlú kan ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun — tí ọba ibẹ̀ ń jẹ́ "Olúwòó" (Olú ti Ìwó).[10]

Àwọn ìlú tí wọ́n kọ́kọ́ dá sílẹ̀ ní ilẹ̀ Yorùbá (èyí tó gba apákan Benin, Nàìjíríà, àti Togo) ni àwọn tó ní ọba tó máa ń dé adé ìlẹ̀kẹ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú ìran-kejì náà ní Ọba. Ṣùgbọ́n àwọn ìlú kékeré tàbí ìran-kẹta máa ń ní alákòóso tí ń jẹ́ "Baálẹ̀" (Iba-Ilẹ̀ tàbí Baba-ilẹ̀), tí wọn kì í dé adé, tí wọ́n sì wà ní abẹ́ Ọba aládé kan.

Gbogbo àwọn tó wà ní abẹ́ ọba, yálà ìjòyè ìbílẹ̀ tàbí ìjòyè ẹ̀yẹ, ló máa ń lo "Olóyè" (tàbí "Ìjòyè") ṣáájú orúkọ wọn, bí ọba ṣe ń lo 'Ọba'. Àwọn ọmọ-ọba náà máa ń lò ó nínú ọ̀rọ̀ ojoojúmọ́, ṣùgbọ́n orúkọ tí wọ́n sábà máa ń pè wọ́n ní gbangba ni "Ọmọba" (Ọmọ-ọba). Àwọn ìyàwó ọba tàbí ọmọ-ọba máa ń jẹ́ "Olorì", bó tilẹ̀ jẹ́ pé díẹ̀ nínú àwọn ìyàwó ọba tún fẹ́ràn kí wọ́n pè wọ́n ní "Ayaba" (Aya Ọba). Àwọn ìyàwó ìjòyè tí wọ́n jẹ oyè fúnra wọn máa ń jẹ́ "Ìyálóyè" (Ìyá tó ni oyè).

Adé Ìlẹ̀kẹ̀ ti Ọba Onijagbo Obasoro Alowolodu, Ọ̀gọ́gà ti Ìkẹ́rẹ́ (1890-1928).

Adé ìlẹ̀kẹ̀ pẹ̀lú ìbòjú ìlẹ̀kẹ̀ ni ohun èlò tó ga jùlọ fún Ọba, tó sì ṣàpẹẹrẹ ipò àṣẹ tó ga jùlọ. Nínú àpilẹ̀kọ rẹ̀, Robert F. Thompson kọ pé:

Adé ṣàpẹẹrẹ agbára ogún àwọn baba-ńlá wa, ìṣípayá ọgbọ́n ìjìnlẹ̀ àti ìwà rere nínú àkópọ̀ ìwà ọba, àti dídán àwọn ohun ẹ̀ṣọ́ tó lẹ́wà.

Robert F. Thompson, African art & leadership[11]

Àwọn ohun èlò oyè

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn ohun èlò wọ̀nyí sábà máa ń wà fún ipò Ọba ní ilẹ̀ Yorùbá:

  • Adé - Ohun èlò àṣẹ tó ga jùlọ. Láti Ilé-Ìfẹ̀ ni wọ́n ti máa ń pín in fún àwọn Ọba tó tọ́ sí.[12][13]
  • Ìrùkẹ̀rẹ̀ - Ìrù ẹṣin tí ọba ń mú lọ́wọ́, èyí tó ṣàpẹẹrẹ iyì àti àlàáfíà.[14]
  • Ọ̀dìgbà / Ẹ̀jìgbà - Ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn tàbí ẹ̀gbà-ọrùn àwọn ọba.[15]
  • Ọ̀pá Àṣẹ - Ọ̀pá tí ó ṣàpẹẹrẹ àṣẹ, tí a tún mọ̀ sí ọ̀pá ìlẹ̀kẹ̀.[16]
  • Idà àti Àbẹ̀rẹ̀ - Idà ìdájọ́ òdodo, tí wọ́n ń mú wá láti Ilé-Ìfẹ̀ nígbà ìfọni-joyè.[17]
  • Ìlẹ̀kẹ̀ - Ìlẹ̀kẹ̀ ọwọ́ àti ọrùn (iyùn tàbí sẹ̀gí).
  • Àgbá / Gbẹ̀dú - Ìlù ńlá tí a ń lù fún Ọba. Òun ni ìlù tó tóbi jùlọ ní ilẹ̀ Yorùbá.[18]
  • Ẹ̀wù Ìlẹ̀kẹ̀ - Ẹ̀wù tí a fi ìlẹ̀kẹ̀ tò pọ̀, àti bàtà ìlẹ̀kẹ̀.[19][20]

Àwọn iṣẹ́ ọba

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Ní oṣù kẹfà ọdún 2006, Ọ̀gá ọkọ̀ ojú-omi USS Barry, Cmdr. Jeffrey Wolstenholme, ń gbé ẹ̀bùn fún Ọba Rilwan Akiolu, Ọba ti Èkó, nígbà tí ọkọ̀ rẹ̀ ṣèbẹ̀wò sí ìlú náà.

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé agbára Ọba ti dínkù pẹ̀lú dídé ìjọba àmúnisìn (colonialism) àti ìjọba tiwa-n-tiwa (democracy), pípín oyè ìjòyè fún àwọn ènìyàn ṣì jẹ́ ohun ńlá tó bọwọ̀ fún Ọba. Ètò yìí bẹ̀rẹ̀ láti àkókò ìjọba Ọ̀yọ́ ìgbàanì, nígbà tí àwọn jagunjagun àti òṣìṣẹ́ ààfin máa ń gba oyè. Ní ilẹ̀ Yorùbá, a sábà máa ń fi oyè dá àwọn ọkùnrin àti obìnrin tó kẹṣọrí lọ́lá nínú ìlú, bó tilẹ̀ jẹ́ pé a tún lè fi jẹ àwọn àjèjì tó tọ́ sí i. Àwọn oyè yìí jẹ́ àmì iyì tó ń fúnni ní ipò pàtàkì láwùjọ.

Nígbà ayẹyẹ ìfọni-joyè, gbogbo àwùjọ ló máa ń fojú sùn Ọba ju àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba kankan lọ. Ọba yóò darí àwọn olóyè tuntun wá sí iwájú àwọn ará ìlú pẹ̀lú ìlù àti ijó. Àṣírí ìfọni-joyè tó ga jùlọ nìkan ni wọ́n máa ń bò mọ́lẹ̀ fún àwọn tí kì í ṣe ọmọ ẹgbẹ́ kọ̀kọ̀.[21]

Àwọn iṣẹ́ ẹ̀sìn

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Ọba Adefunmi Kìíní ti ìlú Ọ̀yọ́túnjí, ní Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà (U.S.A.).

Gẹ́gẹ́ bí aṣáájú mímọ́, àwọn Yorùbá kà Ọba sí olórí àlùfáà tàbí aṣáájú gbogbo àwọn oníṣẹ̀ṣe àti ẹlẹ́sìn Òrìṣà ní agbègbè rẹ̀. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn Àràbà àti Awóró ló máa ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ ojoojúmọ́ lórí ẹ̀sìn, àwọn àtùdà àti ètùtù kan wà tí Ọba nìkan ṣoṣo ló lè ṣe é. Ìdí nìyí tí a fi ń wo Ọba gẹ́gẹ́ bí aṣáájú ẹ̀sìn yàtọ̀ sí oyè ìṣèlú àti ìṣèjọba.[22]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Samuel Crowther (1843). Vocabulary of the Yoruba Language: Part I. English and Yoruba.. p. 206. https://books.google.com/books?id=NMINAAAAQAAJ&q=%22king%2C+monarch%2C+lord%22. "ỌBA, s. king, monarch, lord, prince, liege, master."
  2. Society, Church Missionary (March 2009). Dictionary Of The Yoruba Language: English-Yoruba, Yoruba-English (1913). Kessinger Publishing. p. 202. ISBN 978-1-104-17000-4. https://books.google.com/books?id=sZaiPwAACAAJ. "Ọba, n. king; monarch; lord; prince; liege; master; sovereign."
  3. J.F.A Ajayi and, M. Crowder (1967). The Yoruba and Edo-speaking Peoples and their Neighbors before 1600 AD. pp. 255–322.
  4. Toyin Falola and, Emmanuel Mbah (2018). Dissent, Protest and Dispute in Africa. Taylor & Francis. ISBN 9781315413082.
  5. Du Bois, W.E.B (1911). "The Crisis: A Record of the Darker Races". http://www.modjourn.org/issue/the-crisis-volume-2-number-5-september-1911/.
  6. Johnson, Samuel (1921). History of the Yorubas: From the Earliest Times to the Beginning of the British Protectorate. CMS Bookshop, Lagos. pp. 576.
  7. Blair, Major J.H., Intelligence Report on Abeokuta: 65 year anniversary reprint edition (2002), p. 3.
  8. Johnson, Samuel (1921). The History of the Yoruba People. Cambridge University Press. pp. 149. ISBN 9781108020992.
  9. Sotunde, F.I., Egba Chieftaincy Institution (2002), Appendix X.
  10. Jr, Everett Jenkins (2015-07-11) (in en). Pan-African Chronology II: A Comprehensive Reference to the Black Quest for Freedom in Africa, the Americas, Europe and Asia, 1865-1915. McFarland. pp. 220. ISBN 978-1-4766-0886-0. https://books.google.com/books?id=c4EwCgAAQBAJ&pg=PA220.
  11. Thompson, Robert F. (1972). Douglas Fraser and Herbert M. Cole. ed. African art & leadership. Madison: University of Wisconsin Press. pp. 227–260. ISBN 0299058204.
  12. Ogbontiba, Femi Ade (1997) (in en). The Glory of the Yoruba Race: Past, Present, and Future : Challenges of the 21st Century. Global Books & Publications. p. 60. ISBN 978-978-34355-0-6. https://books.google.com/books?id=-GQuAQAAIAAJ&q=It+is+well+known+that+only+the+Ooni+can+issue+crowns+,+Ife+is+the. Retrieved 11 October 2024.
  13. (in en) Odu. University of Ifẹ Press. 1989. p. 116. https://books.google.com/books?id=ACUlAQAAMAAJ&q=Bata+ileke. Retrieved 10 October 2024.
  14. (in en) The Dancing Palm Tree and Other Nigerian Folktales. Texas Tech University Press. 1990. p. 93. ISBN 978-0-89672-216-3. https://books.google.com/books?id=NlfN3yceM80C&dq=ejigba+ileke&pg=PA93. Retrieved 8 October 2024.
  15. Pokornowski, Ila Pelkey (1974) (in en). Social Significance of African Beads: Case Studies of the Yoruba and Bini Peoples. Michigan State University. Department of Human Environment and Design. p. 74. https://books.google.com/books?id=ZCOEKlzJ8TAC&q=ejigba+ileke. Retrieved 8 October 2024.
  16. Johnson, Samuel (1966) (in en). The History of the Yorubas: From the Earliest Times to the Beginning of the British Protectorate. Cambridge University Press. p. 156. ISBN 978-1-108-02099-2. https://books.google.com/books?id=7XSiGw4_qlAC&dq=ejigba+ileke&pg=PA156.
  17. Negri, Eve De (1976) (in en). Nigerian Body Adornment. Nigeria magazine. p. 52. https://books.google.com/books?id=Zp0KAQAAIAAJ&q=ejigba+ileke. Retrieved 8 October 2024.
  18. (in en) Odù. Western Region Literature Committee. 1976. p. 5. https://books.google.com/books?id=ZiwziumkbxcC&q=Agba+Yoruba+drum. Retrieved 9 October 2024.
  19. Campbell, Bolaji (2001) (in en). Yoruba Shrine Painting Traditions: Color, Cosmos, Process and Aesthetics. University of Wisconsin--Madison. p. 55. https://books.google.com/books?id=5pdpAAAAMAAJ&q=ewu+ileke. Retrieved 10 October 2024.
  20. Fraser, Douglas; Cole, Herbert M. (1972) (in en). African Art and Leadership. Univ of Wisconsin Press. p. 228. ISBN 978-0-299-05824-1. https://books.google.com/books?id=sSIxOcgE378C&dq=ewu+ileke&pg=PA228. Retrieved 10 October 2024.
  21. Lionel Caplan, Humphrey Fisher, David Parkin; The Politics of Cultural Performance. Berghahn Books, 1996, p 30-37.
  22. "Oba and Oriatè: Leadership and Spiritual Stewardship in Yoruba tradition and the diaspora". ileoro.org. Retrieved September 10, 2025.