Jump to content

Oba C. D. Akran

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Oba Claudius Dosa Akran jẹ olóṣèlú ọmọ Nàìjíríà ati oloyè ibilẹ to sójú Badagry ni ile ìgbìmọ̀ aṣòfin ni ọdún 1951 to si di oyè Aholu Jiwa II ti Jegba mu. O jẹ ọmọ ẹgbẹ ti Action Group lakoko àkọkọ òmìnira ati pe wọn yan ní Minisita agbègbè ti Ijọba Agbègbè ati Ètò Eto-ọrọ ni ọdún 1952. O jẹ ọmọ ẹgbẹ ti o ni ipa ninu ẹgbẹ náà ati pe o jẹ Minisita fun Ìṣúná agbègbè láti ọdún 1962 si 1966. [1]

Akran ni a bi ni ọdún 1899 nínú ìdílé Kopon, ti o ṣe bi olori ti Jegba quarters ti Badagry. [1] Ni aṣẹ alufa Catholic kan, baba rẹ gba láàyè lati lọ si ile-iwe, Akran si lọ si St Gregory's College, Obalende o si pari eto-ẹkọ gírámà ni King's College. O sise fún ìdàgbàsókè Post àti Telegraph fun ọpọlọpọ ọdun, o darapọ mọ ẹka náà ni ọdún 1926 o si kúrò ni ọdún 1947. Nígbàtí bàbá rẹ ku ni ọdún 1946, wọn yan gẹgẹ bi olórí egbé Jegba ni ọdún 1948 wọn si yan ni ọdún 1950. Bi Oba Akran ìlú Badagry, o je ọmọ ẹgbẹ wọn sí padà fi jẹ Ààrẹ ti Badagry Town Council and Egun Àwórì Native Authority . [1]

Akran ni ipa lori idasilẹ ti Badagry Grammar School ni ọdun 1955, ile-iwe giga akọkọ ni Badagry ati ìdàgbàsókè àwọn amayedẹrùn míìràn ni Badagry gẹgẹbi ifiweranṣẹ ati telegraph, ìtanná ati awọn ohun elo opopona. [2]

  1. 1 2 3 Ogunremi, Gabriel Ogundeji; Opeloye, M. O.; Oyeweso, Siyan (1994) (in en). Badagry: A Study in History, Culture and Traditions of an Ancient City. Rex Charles Publications. pp. 344–350. ISBN 9789782137241.
  2. Podo, Sunday (March 10, 2018). "Oba Akran: The legend who combined politics, tradition" (in en-US). New Telegraph. https://newtelegraphonline.com/2018/03/oba-akran-legend-combined-politics-tradition/.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]