Odun oro
Àjọyọ̀ ayẹyẹ Odún Orò ( Yoruba : Orò) jẹ́ ayẹyẹ tí àwọn ìlú àti agbègbè ìbílẹ̀ Yorùbá má ń ṣe. Ó jẹ́ ayẹyẹ àṣà ọdọọdún tí ó jẹ́ ti baba ńlá, nítorí pé àwọn ọmọkùnrin tí wọ́n jẹ́ ọmọ ìlu nìkan ni wọ́n ń ṣe ayẹyẹ rẹ̀ ní àwọn ibi pàtó tí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ti ń wáyé. [1] Ó ń bọ̀wọ̀ fún Orisha Orò, òrìṣà àwọn onk Ajá Orò àti ìdájọ́ òdodo ti àwọn ará ìlú Yorùbá. Nígbà àjọyọ̀ náà, àwọn obìnrin àti àwọn tí kì í ṣe ọmọ agbègbè ibè yio dúró sílé nítorí ìtàn ẹnu sọ pé àwọn obìnrin àti àwọn tí kì í ṣe ọmọ ìlú kò gbọdọ̀ rí Orò. Àwọn ayẹyẹ tí ó yí ayẹyẹ Orò ká yàtọ̀ síra láti ìlú dé ìlú, àmọ́ won sì sábà máa ń pè é lẹ́yìnbi ọba kan bá wàjà. [2] Nígbà tí Oba tàbí aláṣẹ pàtàkì mìíràn bá kú, a máa ń ṣe ètùtù pàtàkì àti àkókò ìdárò ọ̀fọ̀.
A sábà máa ń fi Orò pamọ́ àyàfi nígbà ayẹyẹ. Bí Orò bá má jáde, òun máa ń fi ohùn ìró gíga fohùn. Ìró ohùn gíga yí ìtàn so pe oun ni ìyàwó òrò tí wọ́n ń pè ní Majowu. [3]
Àwọn kan jiyàn pé ayẹyẹ Orò lòdì sí obìnrin nítorí pé ó ṣe pàtàkì kí àwọn obìnrin dúró sílé nígbà ayẹyẹ náà. Àwọn obìnrin kò gbọdọ̀ jáde síta fún gbogbo ọjọ́ náà. Wọ́n gbàgbọ́ pé obìnrin èyíkéyìí tí ó bá jáde wá pàdé Ọ̀rọ̀, òrọ̀ yóò gbé, lèyí tí ó lè jásí ikú fún irú obìnrin bẹ.
Èyí fi idi múlè nínú gbólóhùn èdè Yorùbá kan ti o sọ bayi pé:
Awo Egúngún l’obìnrin le ṣe, awo Gẹ̀lẹ̀dẹ́ l’obìnrin le mọ̀. Bí obìnrin bá fi ojú kan Orò, Orò á gbé e lọ.
Ìtumọ̀:
Àwọn obìnrin lè ní ìrírí Egungun, obìnrin lè kópa nínú Gelede . Tí obìnrin bá fojú dí Oro, dájúdájú Oro yóò gbe lọ.
Ni iyàtọ̀ sí Oro tí ó jẹ́ awo fún àwọn ọkùnrin nikan. Gelede jẹ́ ayẹyẹ eleyi ti oun se afihan agbára àti ipa àwọn obìnrin àti ìyá ní àwùjọ Yorùbá.
Ní àkókò àjọyọ̀ náà, ohùn tàbí ohùn Orò máa ń gba ibi gbogbo kan, tí ìgbàgbọ́ àtọwọ́dọ́wọ́, sì ṣe àlàyé lórí pé irẹ ni ó jẹ́ fún gbọgbọ ẹni ba fi etí gbó ìró ohun na. [4]
A mẹ́nu ba ayẹyẹ Orò nínú ìwé ìtàn DO Fágúnwà ti ọdún 1954, Ìrìnkèrindó nínú Igbó Elégbèje (Ìrìnàjò sí Òkè Ìrònú), níbi tí ìyá Olojumajele sá lọ sínú igbó nítorí ó gbọ́ ìró àwọn Ajá Orò ní ẹ̀yìn àti níwájú rẹ̀, ó sì bẹ̀rù pé óun le se alabapade ẹ̀mí Orò. Láìmọ̀ pé kò sí ègún òrò nítòsí, àyàfi àwọn ẹ̀mí búburú inú igbó ni wọ́n ń dùn bí ajá òrò. [5]
Ayẹyẹ Oro ni Ikorodu
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ayẹyẹ náà jẹ́ ayẹyẹ àṣà ìbílẹ̀ tí òun ṣe afihan òun alumoni ìlú náà, a sì sábà máa ń wáyé nínu oṣù Kẹjọ. Nígbà ayẹyẹ náà, àwọn olùkópa mon wo aṣọ ìbílẹ̀ aláwọ̀ pupa, wọ́n sì máa ń jó onírúurú ijó àti àṣà ìbílẹ̀, títí kan ijó Oro Magbo, èyí tí í ṣe ijó abíyí tí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Oro ń jó. Ayẹyẹ náà tún ní orin ìbílẹ̀, oúnjẹ, àti iṣẹ́ ọ̀nà tí tie, ó sì jẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì fún àwọn ènìyàn Ikorodu láti péjọ pọ̀ láti ṣe ayẹyẹ orírun won. Ayẹyẹ náà sábà máa ń wáyé ní Gbọ̀ngàn Ìlú Ikorodu, àwọn ọlọ́lá láti gbogbo ìpínlẹ̀ náà sì máa ń wá síbẹ̀.
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "Ooni: Ife Declares Oro Festival". 31 July 2015. http://www.premiumtimesng.com/regional/ssouth-west/187605-ooni-ife-declares-oro-festival.html.
- ↑ "Traditionalists Hold Oro Festival In Ile-Ife". 1 August 2015. http://www.ngrguardiannews.com/2015/08/traditionalists-hold-oro-festival-in-ile-ife/.
- ↑ "Yoruba festival that are anti women". The Guardian. https://guardian.ng/life/oro-a-yoruba-festival-that-is-anti-women/.
- ↑ sounding the voice of tolerance: the orò secret society at the yorùbá borderlands. 2021. https://www.tandfonline.com/doi/full/10.1080/17432200.2021.1951089. Retrieved 21 May 2022.
- ↑ Expedition to the Mountain of Thought (The Third Saga) being a free translation of the full text of D.O. Fágúnwà's Yorùbá novel Ìrìnkèrindó nínú Igbó Elégbèje. Ile-Ife, Nigeria: Obafemi Awolowo University Press Ltd..