Olúṣẹ́gun Bọ́lánlé Gbélẹ̀yí
Ọ̀túnba Olúṣẹ́gun Gbélẹ̀yí jẹ́ olóṣèlú ní ilẹ̀ Nàìjíríà [1] ati ayànnànán ọ̀rọ̀ tí a bí ní ọjọ́ kọkànlá Oṣù Kẹwa, Ọdún 1962.
Ìpilẹ̀sẹ̀ rẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó jẹ́ ọmọ fún olóògbé (Olóyè) E. A. O. Gbélẹ̀yí, Ọ̀tún Ọba ti ìlú Ìgbẹ̀sà àti ẹnì kejì tí ó jẹ́ olóṣèlú láti ìlú Ìgbẹ̀sà tí wọ́n dìbò yàn láti ìpínlẹ̀ èkó lọ sí ilé ìgbìmọ̀ aṣojúṣòfin ti ìjọba àpapọ̀ ní ọ̀dún 1964 sí ọdún 1966 láti lọ ṣojú Ẹkùn Gúsù ti Ẹ̀gbádò. Bàbá rẹ tún jẹ́ Minisita Àpapọ̀ fún ọ̀rọ̀ Iṣẹ́ àti Àkọwé Àpapọ́ fún ọ̀rọ̀ iṣẹ̀ lábẹ́ ìjọba Sir Tafawa Balewa ṣáájú kí ìdìtẹ̀ gbàjọba àwọn ọmọ ológun àkọ́kọ́ tó wáyé ní oṣù kínní ọdún 1966. [2]

Gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ení. Igbákejà ààrẹ ilé ìgbìmọ̀ aṣófin ti ìpílẹ̀ Ògùn láti ọdún 1999 si ọdún 2003 lábẹ́ àsìà ẹgbẹ́ Alliance for Democracy (AD) ó jẹ́ aṣojú fún agbégbè (Ado-Odo/Ota kejì) ní ìpínlẹ̀ Ògùn orílẹ̀ èdè Nàìjíríaà. [3] Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bíi igbákejí alága fún àwọn ìgbìmọ̀ wọ̀nyí: Àwọn òfin àti Ìṣòwò; Ìṣuúná àti ohun èlò gbogboogbò ; àti ìgbìmọ́ tó ń yanni sípò.
Ó tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ àwọn ìgbìmọ̀ wọ̀nyí: Ọ̀rọ̀ iṣẹẹ́ àti Ilégbèé; Àṣùwọ̀n ará ìlú; Ìṣúná àti pínre làáare; ìjọba ìbílẹ̀ àti ìfinijoyè. Ní oṣù kẹsàn-án ọdún 2000, ní ìpàdé àjọ ìṣòfin àwọn orílẹ̀ èdè (CPA) tó wáyé ní ìlú london gẹ́gẹ́ bí aṣojú ìjọba tó ń ṣojú fún orílẹ̀ èdè nàìjíríà (ó gbé ìgbésẹ̀ tó lágbára fún àdínkù tàbí ìfinjì ẹgbẹlẹmùkú gbèsè tí orílẹ̀ èdè nàìjíà jẹ láti lè fìdí ìjọba àwarawa lè rẹ́sẹ̀ walẹ̀, gbogbo àwọn akópa sì fọwọ́ ìgbésẹ̀ yìí.)
Èjì. Ní Oṣù Karùn ọdún 2011, Olúṣẹ́gun Bọ́lánlé Gbélẹ̀yí, (OBG) di ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ tó ń rísí ètò ìlànà fún àwọn ìjọba ìbílẹ̀ àti Oyè jíjẹ lábẹ́ ìjọba Gomìnà Ìbíkúnlé Amósùn.
Ẹ̀ta. Ní Oṣù Kejì sí ÌKẹrìn ọdún 2015, Olúṣẹ́gun Bọ́lánlé Gbélẹ̀yí, (OBG) sìn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ kékeré ti ètò àti ọgbọ́n àtinúdá fùn ìpolongo ìbò fún SIA, ó sì kó ipa ti olùdánilẹ́kọ̀ọ́, ó ńkọ́ àwọn aṣojú ẹgbẹ́ àti àwọn alábǒjútó ní gbogbo ìpínlẹ̀ lórí bí wọ́n ṣe ń ṣe nínú ètò ìdìbò àti bí ati ń dáàbò bo ìbò. Ó tún ṣiṣẹ́ bí aṣojú ẹgbẹ́ òṣèlú APC fún Agbègbè Ìwọ̀-oòrùn Ògùn lǎkókò ìdìbò àpapọ̀ ti ọdún 2015.
Ìkẹrin. Láti ọdún 2016 sí 2019 Gómìnà Ìbíkúnlé Amósùn ṣe Olúṣẹ́gun Gbélẹ̀yí ni olùkànsí fún Ìjọba Ìpínlẹ̀ Ògùn lórí ọ̀rọ̀ Agbára.
Ìkarùn-ún. Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù keje ọdún 2021, Olúṣẹ́gun Bọ́lánlé Gbélẹ̀yí, (OBG) ni a yàn sí ipò ààrẹ, Ìgbìmọ̀ olùdarí ti Digital Bridge Institute, (DBI), Àjọ Àgbáyé tó ń rísí Ìwádìí nípa ètò ìmọ̀ ẹ̀rọ àti ìbáraẹnisọ̀rọ̀ lábẹ́ àjọ tó ń rísí ìbáraẹnisọ̀rọ̀ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, (NCC). Ìyànsípò náà bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ọdún 2021
Ìkẹfà. Olùdarí Ìgbìmọ̀ DBI, Olúṣẹ́gun Gbélẹ̀yí, gbóríyìn fún àwọn ọ̀gá tó ń rísí ọ̀rọ̀ òṣìṣẹ́ tó nítorí pé wọ́n gbàgbọ́ nínú DBI lè jẹ́ olùkọ́ fún àwọn ilé iṣẹ́ wọn.
Àwọn Àṣeyọrí rẹ̀ Nínú Òṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Olúṣẹ́gun Bọ́lánlé Gbélẹ̀yí, ni a yàn ní ọdún 1999 gẹ́gẹ́bí aṣojú fún Ado-Odo / Igbesa ti labẹ pẹpẹ ti Alliance for Democracy (AD) sí Ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ Ògùn. Àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yàn án gẹ́gẹ́ bí igbákejì Ààrẹ, ó sì sìn ní àṣeyọrí títí di òpin ọdún mẹ́rin rẹ̀ láti ọdún 1999 sí 2003.
Nígbà tó wà ní Ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin, ó jẹ́ aṣojú orílẹ̀ èdè nàìjíríà níbi ìpàdé àjọ ìṣòfin àwọn orílẹ̀ èdè (CPA) ti ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínláàádọ́ta irú ẹ̀ tó wáyé ní United Kingdom ní ọdún 2000 ati ẹlẹ́ẹ̀kejìdínláàádọ́ta tó wáyé ní orílẹ̀ Namibia ní ọdún 2002. Nígbà tí Gbeleyi kópa fún ìgbà àkọ́kọ́ ní Àpéjọ CPA kẹrìndínláàádọ́ta ní London ní ọdún 2000, ó gbé ìwé kan jáde lórí "ìfagilé gbèsè gẹ́gẹ́ bí irinṣẹ́ gbóògì láti fìdí ìjọba àwarawa múlẹ̀ láwọn orílẹ̀ èdè tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń dàgbàsókè", ó sì gbé ìgbésẹ̀ àwọn akópa fọwọ́ sí èyí tí ó ṣokùnfà bí wọ́n ṣe dárí gbèsè jin orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, èyí tí a fìdí rẹ̀ múlẹ̀ lábẹ́ ìjọba oní sáà méjì ti ààrẹ Olúṣegún Obasanjo ní orílẹ̀ èdè Nàìjiria.
Ó kó ipa pàtàkì nínú mímú kí àwọn àgbègbè ìjọba ìbílẹ̀ mìíràn wà, èyí tí wọ́n ṣe lábẹ́ àkóso Olóyè Olúṣẹ́gun Ọ̀sọbà CON. Gbeleyi tún jẹ́ alátìlẹyìn fún ìgbédìde àwọn ìjọba ibilẹ méjìdínláàádọ́ta àti wípé OBG ni inú rẹ̀ dùn nígbàtí wọ́n ṣe àtúnṣe sí òfin náà láti fi ààyè gba ìdásílẹ̀ ìjọba agbègbè métàdínlógójì mìíràn tí ètò ìdìbò sì wáyé lábẹ́ Gómìnà, Aṣòfin Ibikunle Amosun, CON, FCA fún àwọn ìjọba ìbílẹ̀ àti ìjọba agbègbè tí àpapọ̀ wọn jẹ́ mẹ́tàdínlọ́gọ́ta èyí tó mú ìjọba súnmọ́ àwọn ará ìlú si. Ní ọdún 2007, ó díje fún ipò aṣòfin àgbà láti lọ́ ṣojú ẹkùn ìwọ̀ oòrùn ìpínlẹ̀ ògùn lórí pẹpẹ ti ẹgbẹ́ òṣèlú Action Congress (AC) ó sì pàdánú. Ní ọdún 2019, ó díje fún ipò aṣòfin àgbà láti lọ́ ṣojú ẹkùn ìwọ̀ oòrùn ìpínlẹ̀ ògùn lórí pẹpẹ ti ẹgbẹ́ Allied Peoples' Movement (APM) ó sì pàdánù. Láti ọdún 2016 sí ọdún 2018, ó ṣiṣẹ́ bí olùkànsí lórí ọ̀rọ̀ Agbára fùn Aṣòfin Ìbíkúnlé Amósùn, CON, FCA. Òun àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ mìíràn lórí ọ̀rọ̀ agbára ṣe àbójútó àṣeyọrí ìṣẹ lórí àkànṣe iṣẹ́ lórí ọ̀rọ̀ Agbára (IPP), Àkànṣe iṣẹ́ agbára ti Lisabi tó ń pèsè agbára fún gbogbo ilé ìjọba ní Abeokuta, títí kan àwọn iná ojú òpópónà àti àwọn òǹtajà. Wọ́n tún fi méjìlá irú àwọn àkànṣe iṣẹ́ agbára yi sí ayika ipinlẹ ògùn, lára wọn ni Ìpókíá, Ọ̀tà àti Àgbárá. Ó tún ṣe àbójútó àwọn iṣẹ́ lórí ọ̀nà tí a fi ń pín iná mọ̀nàmọ́ná tí ó tó kìlómítà lọ́nà igba ó lé méta látipaṣẹ̀ àjọ tó ń rísí pínpín iná mọ̀nàmọ́ná káàkiri orílẹ̀ èdè Nàìjírí (TCN). Ó kọ̀wé fipò sílẹ̀ láti dije fún ipò aṣòfin tí yó ṣojú ẹkùn ìwọ̀ oòrùn ìpínlẹ̀ Ògùn níbi ìdìbò àpapọ̀ tó wáyé ní ọdún 2019. O jẹ ara àwọ́n ọmọ ẹgbẹ tó kọ́kọ́ darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress, (APC). Lẹ́hìn àwọn ìjà àti awuyewuye tó wáyé nínú ìdìbò abẹ́lé ti ẹgbẹ́ òṣèlú APC, ó yan pẹpẹ mìíràn láti díje nínú ìdìbò àpapọ̀ 2019 àti láti ìgbà náà ó ti padà sínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC.
Àwọn Àkànṣe iṣẹ Àgbàṣe tí ó ṣe
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ení. Àkànṣe iṣẹ́ Agbára (IPP) tí ilé iṣẹ́ Sholep Energy Ltd láti pèsè agbára látipasẹ̀ agbára oòrùn tí ó tó Mẹ́gáwàtì márùn-ún fún lílò bá ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìṣé ìpínlẹ̀ Ogun, Ìpókíá àti àwọn agbègbè rẹ̀, lórí ètó "sán bí o ṣe ń lòó". [4]
Ìkejì. Ó jẹ́ olùdarí ìgbìmọ̀ ẹlẹ́nu márùn-ún tó ń bójú tó títún ojú ọ̀nà Atan - Àgbárá ṣe pẹ̀lú afárá abẹ́yẹfò.
Ìkẹta. Gómìnà Ibikunle Amosun tún yàn án sípò láti darí àkànṣe iṣẹ ti ilé ìfowópamọ́sí Àgbáyé ń ṣe lórí àwọn ọ̀nà tí a ń gbé iná mọ̀nàmọ́ná gbà tí ó jẹ́ tuntun àti àwọn ibùdó alágbèéká tuntun márùn-ún.