Olúbàdàn
| Oba Rasheed Ladoja | |
|---|---|
44th Olubadan of Ibadan | |
| Reign | 26 Sept 2025 – |
| Coronation | 26 Sept 2025 |
| Predecessor | Oba Owolabi Olakulehin |
Olúbàdàn (Yoruba: Oní Ìbàdàn; " Olórí ilẹ̀ Ìbàdàn") ni ni ó jẹ́ orúkọ fún Ọba ti ilẹ̀ Ìbàdàn ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Nípa Ìbàdàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wọ́n tẹ ilẹ̀ Ìbàdàn dó ní nkan bí ọ̀rùndún kẹrìndínlógún (16th century), nígbà tí yóò sì fi di ọdún 1820 sí 1850, wọ́n ti gbé ìlànà ìṣàkóso àti ìjẹ Ọba àti oyè ní ilẹ̀ Ìbàdàn tí ó yàtọ̀ pátá pátá sí bí àwọn ilẹ̀ Yorùbá tókù ń gbà yan adarí (Olúbàdàn). Wọ́n gbé ìjà Olúbàdàn wọn kalẹ̀ láti orí agboolé kọ̀ọ̀kan tí wọ́n lẹ́tọ̀ọ́ sí oyè náà.
Ìtàn ránpẹ́ nípa Ìbàdàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ilẹ̀ Ìbàdàn tí Ọba Isaac Akínyẹlé sọ, wọ́n tà Ìbàdàn do ní àárín ọ̀rùndún kejìdínlógún (18th century) lẹ́yìn tí àwọn jagujagun ilẹ̀ Ẹ̀gbá, Ìjẹ̀bú, Ọ̀yọ́, Ifẹ̀ lẹ́yìn tí ilẹ̀ Ọba Owu ṣubú lọ́jọ́ sí. Lẹ́yìn tí ogun náà parí, ilẹ̀ Ìbàdàn ìlú alágbára ní ọdún 1829, wọ́n sì bẹ̀tlrẹ̀ sí ń gbé ìṣàkóso kalẹ̀ nípa ṣíṣètò oyè jíjẹ láti orí àwọn Báálé baálé, títí, ìpínsísọ̀rí agbára àwọn jagujagun wọ̀nyí ní ọdún 1851 tí ó sì di ohun tí Won fi ń yan Ọba títí di òní.
Ààfin
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Wọ́n kọ́ Àfin Olúbàdàn di orí ilẹ̀ tí ó tó sare ilẹ̀ mẹ́fà sí agbègbè Òkè Arẹmọ ní ìlú Ìbàdàn, wọ́n sì ṣì ní inú oṣù keje ọdún 2024 [1]

