Olúrẹ̀mí Tińubú
Olúrẹ̀mí Tińubú | |
|---|---|
| Ààrẹ | Bola Tinubu |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ẹgbẹ́ olóṣèlú | All Progressives Congress (2013–present) |
Olúrẹ̀mí "Rẹ̀mí" Tińubú CON. A bi ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹsàn-án ọdún 1960 jẹ́ olóṣèlú ní Nàìjíríà àti Ìyàwó ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà lọ́wọ́lọ́wọ́ láti ọdún 2023, gẹ́gẹ́ bí ìyàwó Ààrẹ Bola Tinubu . Ó jẹ́ ìyáàfin àkọ́kọ́ ní Ìpínlẹ̀ Èkó láti ọdún 1999 sí 2007 nígbà tí ọkọ rẹ̀ jẹ́ gómìnà. Ó jẹ́ Aṣòfin tó ń ṣojú fún Àgbègbè Àárín Gbùngbùn Ìpínlẹ̀ Èkó ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Nàìjíríà láti ọdún 2011 sí 2023. Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC).
Ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí Olúrẹ̀mí Tińubú ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹsàn-án ọdún 1960. Òun ni ọmọ kejìlá nínú ọmọ mẹ́tàlá nínú ìdílé rẹ̀, ó sì wá láti ìdílé Ikúṣebíàlá ti ìpínlẹ̀ Ogun . [1]
Ẹ̀kọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Olúrẹ̀mí bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ilé-ẹ̀kọ́ girama Our Lady of Apostles to wà ní Ìjẹ̀bú-Òde, níbi tí ó ti gba ìwé-ẹ̀rí ti àpapọ̀ ti apá ìwọ̀ oòrùn Áfríkà (West African Senior Senior School Certificate Examination (WASSCE)) ní ọdún 1979 àti PGD láti ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti ìjọ ìràpadà (The Redeemed Christian BibleCollede) ní ọdún 2010 [2]
Tińubú gba oyè ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ àkọ́kọ́ nínú ẹ̀kọ́ ní Yunifásítì Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ ti ìlú ilé-Ife àti ìwé ẹ̀rí ti olùkọ́ni nínú ìmọ̀ nípa ìmọ̀ nípa ewéko àti ẹranko láti Adeyemi College of Education . [2]
Gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó di obìrin àkọ́kọ́ ní Ìpínlẹ̀ Èkó nígbà tí wọ́n yan ọkọ rẹ̀ Bọ́lá Tińubú gẹ́gẹ́ bí gómìnà. Gẹ́gẹ́ bí ìyáàfin, ó dá àjọ ìgbà ọ̀tun (New Era Foundation) sílẹ̀, èyí tí a yà sọ́tọ̀ fún ṣíṣẹ̀dá àwọn ilé-iṣẹ́ fún “ìdàgbàsókè àwọn ọ̀dọ́ àti gbígbé ìmọ̀ lárugẹ lórí ìlera àyíká àti iṣẹ́ àwùjọ.” [3]
Nígbà Tińubú wọlé nínú ètò ìdìbò, wọ́n pe èsì àbájáde ètò ìdìbò náà lẹ́jọ́ ní Ilé ẹjọ́ tó ń gbọ́ àwọn awuyewuye tó ń wáyé lẹ́yìn ètò ìdìbò si Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin - lẹ́yìn tí wọ́n gbọ́ ẹjọ́ náà, ó fọwọ́ sí àbájáde ètò ìdìbò náà ní ọdún 2012. [4]
Tinubu jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Aṣòfin tó lé ní ọgọ́rùn-ún (100) tí wọ́n dìbò yàn sí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin kẹjọ ní ọdún 2015. Mẹ́fà nínú wọn jẹ́ obìnrin. Àwọn tó kù ni Stella Oduah àti Uche Ekwunife, tí wọ́n ṣojú fún Anambra, Fatimat Raji Rasaki, Rose Okoji Oko àti Binta Garba . Ní ìdìbò gbogbogbòò ọdún 2019, ó padà wọlé sí ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí aṣòfin tó ń ṣojú fún ààrin gbùngbùn ìpínlẹ̀ Èkó, èyí tó fi jẹ́ ìgbà kẹta tí ó ṣojú fún agbègbè náà. [5]
Ní ọdún 2016, Aṣòfin Tińubú béèrè fún ààbò tó péye láti ọ̀dọ̀ Ọ̀gá Àgbà àwọn Ọlọ́pàá nítorí ìhalẹ̀ ìkọlù láti ọwọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú rẹ̀ Dino Melaye nínú ìpàdé ìkọ̀kọ̀ kan ti ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ṣe.
Wọ́n kọ orúkọ rẹ̀ pẹ̀lú Babajide Sanwo-Olu, Tony Elumelu àti àwọn ènìyàn pàtàkì mìíràn fún àmì ẹ̀yẹ àwọn tó peregedé jùlọ ní ìlú (Eko Excellence Awards) ní ọdún 2019.
Ní ọdún 2020, ó ké sí ìdásílẹ̀ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà láti dẹ́kun ìdojúkọ ètò ààbò tó ń pọ̀ sí i ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Ó gbàgbọ́ gidigidi nínú ìrónilágbára fún àwọn èèyàn àwùjọ àti àwọn ọ̀dọ́ àti wípé ètò ìrónilágbára tó ń ṣe pẹ̀lú ìfọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú àjọ ìrónilágbára fún àwọn ọkùnrin àti obìrin tí o dára (Good Boys and Girls Empowerment Scheme (GBGES)) ti pèsè àwọn ènìyàn bíi ẹgbẹ̀rún kan ó lé láàádọ̀sán lé méjì ni wọ́n ti jẹ àǹfàní yìí. Nǹkan bí àwọn ọ̀dọ́ tí ó tó ọgọ́jọ ó lé mẹ́rin 164 ni wọ́n kọ́ ní onírúurú iṣẹ́ ọwọ́, wọ́n sì gba àwọn ohun èlò láti ìbẹ̀rẹ̀ àti owó tó tó ẹgbẹ̀rún lọ́nà ogójì náìrà fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn.
Ní oṣù kẹta ọdún 2021, Aṣòfin Tińubú gbé ìwé òfin kan kalẹ̀ láti ṣe àtúnṣe sí Ilé-Iṣẹ́ Ìfìwéránṣẹ́ Nàìjíríà (NIPOST) láti jẹ́ kí ó jẹ́ àjọ tó lágbára jù. Ó tún gba ẹ̀bùn fún aṣòfin obìnrin tó ní ipa jùlọ ní ìpàdé ọjọ́ àwọn obìnrin ti orílẹ̀-èdè (The Guardian) tí wọ́n ṣètò fún ọdún 2021.
Àwọn àmì ẹ̀yẹ àti ìdálọ́lá
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó ti gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀bùn, ó sì ti gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọlá, àwọn ẹ̀bùn àti ọlá tí ó gbà ni: ẹ̀bùn orílẹ̀-èdè ti Officer of the Order of the Niger OON, Ọmọ ẹgbẹ́, Ìgbìmọ̀ Àwọn Olùtọ́jú ti Kings University, Ọdẹ-Òmu; Ghana Noble International Award for Leadership (2004), Gambian Diamond Award fún ipa pàtàkì tó ń kó nípa yíyọ àwọn Ènìyàn kúrò nínú Ìṣẹ́ (2005) [2]
Ìgbésí ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Bó tilẹ̀ jẹ́ pé òun jẹ́ ẹlẹ́sìn Kristẹni, ó fẹ́ Bola Tinubu, Mùsùlùmí kan tí ó di Ààrẹ kẹrìndínlógún ti Nàìjíríà lẹ́yìn náà; wọ́n bí ọmọ mẹ́ta: Zainab Abisola Tinubu, Habibat Tinubu àti Olayinka Tinubu. Ó jẹ́ ìyá fún àwọn ọmọ ọkọ rẹ̀ mẹ́ta láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyàwó tí ọkọ rẹ̀ ti fẹ́ tẹ́lẹ̀, Olajide Tinubu (tí ó ti kú), Folashade Tinubu àti Oluwaseyi Tinubu. Ó jẹ́ Kristẹni [6] ó sì jẹ́ pásítọ̀ tí a yàn nínú ìjọ ìràradà ti krístì (Redeemed Christian Church of God) . Ìfinijoyè rẹ̀ wáyé ní ọdún 2018 ní gbọ̀ngàn àtijọ́ ti ilé ìjọsìn náà, èyí tó wà ní òpópónà márosẹ̀ ìlú Èkó sí Ìlú Ìbàdan níbi tí ìjọ náà ti ṣe ìpàdé ọlọ́dọọdún ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínláàádọ́rin irù rẹ̀ tí àkọlé ìgbàjọba (Dominion). Ó tún jẹ́ ìyá ẹgbẹ́ fun ìgbìmọ̀ àwọn Ìyàwó àwọn ọ̀gá lẹ́nu iṣẹ́ ìjọba ti Ìpínlẹ̀ Èkó (COWLSO).
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]| Preceded by Munira Marwa |
First Lady of Lagos State 1999–2007 |
Succeeded by Abimbola Fashola |
| Preceded by Aisha Buhari |
First Lady of Nigeria 2023–present | |
| Preceded by Munirudeen Muse |
Senator for Lagos Central 2011–2023 |
Succeeded by Wasiu Sanni |
Ẹ̀ka ayélujára
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn Àkíyèsí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
- ↑ Empty citation (help)
- 1 2 3 Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ "Tribunal upholds Tinubu's election". odili. Archived from the original on 23 February 2016. https://web.archive.org/web/20160223180825/http://odili.net/news/source/2011/sep/6/6.html.
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)