Jump to content

Olajumoke Akinjide

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Olajumoke Akinjide
Minister of State for Federal Capital Territory (FCT)
Arọ́pòRamatu Tijani Aliyu
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí4 Oṣù Kẹjọ 1959 (1959-08-04) (ọmọ ọdún 65)
Oyo State, Nigeria
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeoples Democratic Party (Nigeria)
BàbáRichard Akinjide
Alma materKing's College London, Harvard Law School
OccupationBusiness, Politician

Ọlajumọ̀ké̩ Akinjide tí a bí ní ojó kerin osù kejò odún 1959, ó jé Olóṣèlú Nàìjíríà láti ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ Nàìjíríà.Ó jẹ́ mínísítà ipinle fún(FCT)[1] ti àrẹ Naijírià tó jẹ sé̩yìn fàkalẹ̀ (Goodluck Jonathan)ní osù kéje,Ọdún 2011láti ṣiṣẹ́ ní ìgbìmọ̀ oriléèdè Nàìjíríà.[2]

Ìbẹ̀rẹ̀ayé àti ẹbí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọlájùmọ̀kẹ́ Akínjídé,tí a tún mò̩ sí jùmọ̀kẹ́ Akinjide,a bi ní ọjọ́ kẹrin oṣù kẹjọ ọdún 1959 ní ìlú Ìbàdàn,ní ìjọba ìbílẹ̀ Ọ̀nà-Àrà ní àgbègbè kan ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ sínú ẹbí ìlú mọ̀-ọ́n ká Adájọ́ tí ó ti di olóògbé pa,Osuolale Abimbola Richard Akinjide, Adájọ́ Àgbà (SAN).[3][4]

láàrín oṣù karù-ún sí oṣù kẹsàn-án ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bíi amúgbá lẹ́gbẹ̀ẹ́ pàtàkì fún àrẹ lórí ọ̀rọ̀ orí ìlú Àbújá[5][6] lẹ́yìnáà ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí i amúgbá lẹ́gbẹ̀é̩ pàtàkì àrẹ lórí àwọn ọ̀rọ G7 àti àwọn ọmọ Nàìjíríà tó wà lókè òkun lábẹ́ àrẹ ìgbànáà Olusegun Obasanjo.

Ó sì tún jẹ́ Òṣèlú Ẹsè̩ kùkú,àti wípé ó jẹ́ olùdíje sí ilé ìgbòmọ̀ asòfin àgbà,Àrin gbùngbùn ìjọba ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ lábẹ́ Àbùradà ẹgbẹ́ ìṣèlu PDP[7][8] ní o̩dún 2011, ní ọdún kanánnà tí wọ́n yàn-án sí ipò mínísítà.[9][10]

Akinjide lọ sí Maryhill Convent School, Idi-Ape, Iwo,Agodi,ní ìlú ìbàdàn, lati ọdún1963 sí ọdún 1968, níbi tí ó ti gba ìlé ẹ̀rí ilé ìwé aláàkọ́ bẹ̀rẹ̀ tí ó sì tẹ̀síwájú sí ilé ìwé girama, ní Ibadan lati 1969 sí1974 níbi tí ó ti gba West African School Certificate(WASSCE).[11]

Akinjide gba ìwé è̩ri LLB (Hons) láti King's College London, àti ìwé ẹ̀rí master's degree nínu ìmọ̀ òfin (LLM) láti ilé ẹ̀kó̩ òfin Harvard ní òkè òkun (United States.)[12]

Ó wà lára àwọn tó gba ọ̀wọ́ ipò kinni nínú ìdánwò English Solicitors.

Akinjide ní ìwé ẹ̀rí mẹ́jì gẹ́gé̩ bí i Agbe̩jó̩rò àti Olùfisùn ní ilé e̩jọ́ aṣòfin tó gajù lo̩ ti Nàìjíríà àti gẹ́gẹ́ bí i Solicitor of England àti Wales.[13]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "The Amazon – Profile of Oloye Olajumoke Akinjide". Vanguard Newspapers (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2022-08-22. Retrieved 2022-08-28. 
  2. "Olajumoke Akinjide". Citizen Science Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-08-28. 
  3. "Akinjide's daughter vies for Senate seat". The Guardian. 21 December 2009. 
  4. "Olubadan, CCII, honour Akinjide, Makinde, six Others". Daily Post. 20 November 2013. 
  5. "Nigeria: Obasanjo's Aide Commended For Enlightenment Effort". All Africa. 
  6. "Meet The 3 Leading Oyo Female Politicians". Inside Oyo. 19 August 2017. 
  7. "I remain a staunch PDP member – Ex-Minister, Jumoke Akinjide reacts to defection rumour". Daily Post. 7 August 2018. 
  8. admin (2022-05-15). "Jumoke Akinjide: The Governor Backpedaling, Feature Of A Listening Leader — Isiaka Kehinde". OyoInsight (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-12. 
  9. "NEW CABINET: A CASE FOR JUMOKE AKINJIDE". The Nigerian Voice. 
  10. Aka, Jubril Olabode (February 2012) (in en). Nigerian Women of Distinction, Honour and Exemplary Presidential Qualities: Equal Opportunities for All Genders (White, Black Or Coloured People). Trafford Publishing. ISBN 978-1-4669-1554-1. https://books.google.com/books?id=A0I5gsKiDasC&dq=jumoke+akinjide+special+assistant+to+the+president&pg=PA226. 
  11. Admin (2016-09-27). "Akinjide-Balogun, Mrs Jumoke". Biographical Legacy and Research Foundation (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-12. 
  12. "LinkedIn Profile of Olajumoke Akinjide". LinkedIn. 
  13. "Biography Questionnaire - Women Who's Who" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-12. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]