Jump to content

Olowo Imade

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Olowo Imade
(Ologho)
Reign 1070–1106AD
Predecessor Ojugbelu Arere
Successor Olowo Korodo
House Olowo of Owo
Father Ojugbelu Arere
Born Ondo State South-Western Nigeria
Died 1106AD
Ọ̀wọ̀
Religion Traditional Religion

Ọláọ́wọ̀ Imadẹ̀ ni ẹni tí ó gba ipò bàbá rẹ̀ Ojugbelu ní agbègbè Òkìtì Upafa (Òkè Upafa). Òun ni ó kò àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ sí Òkè-Madẹ̀ (Òkè Madẹ̀) níbi tí wọ́n gbé fún ìgbà diẹ̀ látàrí ogun àti àrá sísán ní gbogbo ìgbà tí ó sì ń ṣekú pa púpọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀. Lèyìn èyí ni wọ́n gbéra lọ sí ibi tí wọ́n pe ní Òkítì-Asegbo tí ó di ìlú Ọ̀wọ̀ lónìí. [1]) Lẹ́yìn èyí ni 9lọ́wọ̀ Madẹ̀ àti àwọn ọmọ ogun Ighare bẹ̀rẹ̀ sí ń fẹ ìlú náà lọ sí apá gúúsù nípa jíjagun gbalẹ̀ tí wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀. Lára àwọn ibi tí wọ́n gblẹ̀ tí wọ́n sì tẹ̀dó sí ni wọ́n fi àwọn Olóyè Ighare do sí ni wọ́n ń pè ní Iloro tàbí Uloro . Lónìí, àwọn Iloro méjèèjìlá ni wọ́n ma ń ṣe ètò ìfọba Ọlọ́wọ̀ àti sísin òkú Ọlọ́wọ̀ bí wọ́n bá wàjà.[citation needed][2] Ọlọ́wọ̀ àkọ́kọ́ ni ó sọ ìlú náà ní orúkọ tí ó sì ń lo orúkọ àpèjẹ́ rẹ̀ Ọlọ́wọ̀ (Ẹni tí ó ni Ìlú Ọ̀wọ̀) tí orúkọ yìí sì túmọ̀ sí Ẹni tí àá b'ọ̀wọ̀ fún

Ọlọ́wọ̀ àkọ́kọ́ gbésẹ̀ ní 1106 AD ní ìlú Ọ̀wọ̀ tí Ọlọ́wọ̀ Krodo sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Admin, Admin (January 2017). "Owo town". www.researchgate.net/. Retrieved 1 December 2024.
  2. "Expedition Magazine | New Treasures From Nigeria". Expedition Magazine (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2024-12-31.


Àdàkọ:Africa-royal-stub