Olu Aboderin
| Olu Aboderin | |
|---|---|
| Ọjọ́ìbí | James Olubunmi Aboderin 3 September 1934 Ibadan, Oyo State, Nigeria |
| Orílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Ọmọ orílẹ̀-èdè | |
| Iṣẹ́ | Journalist |
| Ìgbà iṣẹ́ | 1961 - 1984 |
| Gbajúmọ̀ fún | The Punch |
Olu Aboderin ( ọjọ́ kẹta oṣù kẹsàn án ọdún 1934 - ọjọ́ kejìdínlọ́gbòn oṣù kejì odún 1984) jẹ́ olùtẹ̀jáde ìwé ìròyìn Nàìjíríà tí ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Olùdásílẹ̀ The Punch ti Nàìjíríà ó sì jẹ́ ààrẹ Ẹgbẹ́ Àwọn Oníṣẹ́ Ìròyìn ti Nàìjíría (Newspaper Proprietors’ Association of Nigeria) títí ó fi kú ní ọdún 1984. Ó tún jẹ́ akọ̀ṣirò tí ó mọ iṣẹ́ dujú tí ó sì Kúrò nínú ilè ìfowópamọ́ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà gẹ́gẹ́ bí akọ̀ṣirò àgbà. Iwé ìròyìn The Punch jẹ́ ìwé ìròyìn tí ó jẹ́ kárí ayé tí àwọn ènìyàn ń kà ní orílè èdè Nàìjíríà.[1] Ó dá ìwé ìròyìn The Punch sílẹ̀ pẹ̀lú Olùdásílẹ̀ ìwé ìròyìnVanguard, Sam Amuka-Pemu, ní ọjọ́ kìíní, oṣù kejìlá ọdún 1976.[2][3]
Ó jẹ́ olólùfẹ́ iṣẹ́ ọnà àti alábòójútó Ẹgbẹ́ Àwọn akọrin tí ń ṣe eré ní Nàìjíría (Performing Musicians Association of Nigeria).
Ayé e rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí Aboderin sínú ẹbí James Oyebode àti Janet Aboderin ní ìlú Ìbàdàn. Láti ọdún 1941 sí 1944, Ó lọ sí ilé-ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Native Authority ní Oranyan, Ìbàdàn ṣáájú kí ó tó lọ sí ilé-ìwé girama ní ìlú Ìbàdàn (Ibadan Grammar School). Ní ilé ẹ̀kọ́ girama fẹ́ràn bọ́ọ́lù àfẹsẹ̀gbá èyí sì tèsíwájú lẹyìn ilé ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ndárì. Ó parí ilé ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ndárì nípa ṣíṣe àṣeyege nínú ìdánwò A-level. Ní àárín1950s, ó rin ìrìn àjò lọ sí London ó sì ká ìwé nípa ìwádìí ìtàn ni Northwestern Polytechnic. Ó sẹ ìdánwò Institute of Chartered Accountants nígbà tí ó wà ní ìlú náà ó sì wọlé ní oṣù karùn ún ọdún 1964. Ní àsìko yìí ó ṣisẹ̀ bí akọ̀wé pẹ̀lú Brighton, Sussex, láti ọdún 1963 sí ọdún 1964, Ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ilé iṣẹ́ Bradley, Lytton & Co, tí ó jẹ́ ilé iṣẹ́ akọ̀ṣirò ní Moorgate, London. Ó padà sí Nàìjíríà ní 1964 ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ilé iṣẹ́ Pannell Fitzpatrick & Co, chartered accountants. Ó darapọ̀ mọ́ àwọn ilé iṣẹ́ ìfowópamọ́ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní 1967 ó sì jẹ́ akọ̀ṣirò pẹ̀lú ilé ìfowópamọ́ ní ìgbà ogun abẹ́lé Nàìjíríà (Nigerian civil war). Ní àsìko yìí ilé iṣẹ́ ìfowópamọ́ wà ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tí ó gba òmìnira tí wọ́n sì ṣètò ẹ̀ka ti ìta. Ó tún ṣiṣẹ́ lórí àwọn ìgbìmọ̀ ti ìjọba agbègbè díẹ̀ tí ó ní àwọn ẹ̀ka bíi West African Pictures, Nigeria Spinning Company, ati General Insurance. Ó fi iṣẹ́ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí akọ̀ṣirò àgbà ní 1971 sí ilé iṣẹ́ ẹlẹ́nìkan ṣoṣo.
Ó bẹ̀rẹ̀ àwọn ilé-iṣẹ́ ìṣòwò díẹ̀, pẹ̀lú ilé-iṣẹ́ ìrìn-àjò àti Feedwell Nigeria Ltd. Ní ọdún 1976, ó ṣètò ìwé ìròyìn The Punch. Ní àkókò tí ó bẹ̀rẹ̀ bí ìwé ìròyìn Sunday, ó mú àwọn ìmọ̀ràn tuntun tí àwọn iṣẹ́ ṣíṣẹ sí ilé-iṣẹ́ náà. Punch náà gbòòrò sí Daily Punch, Sunday Punch, Ìwé ìròyìn Happyhome, àti ìwé ìròyìn Top Life.
Ikú rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó kú ní Ilé-ìwòsàn Princess Grace, ní Ìlú London. Ṣáájú ikú rẹ̀, ó ti gbéjáde àtẹ̀jáde kan láti gbèjà Haroun Adamu, akọròyìn tí wọ́n fi sẹ̀wọ̀n gẹ́gẹ́ bí olórí ẹgbẹ́ àwọn oníṣòwò ìwé ìròyìn ní Nàìjíríà. Ní òpin ọdún 1983, ìwé ìròyìn rẹ̀ ṣe àtakò púpọ̀ sí ìṣàkóso ti Shehu Shagari.
Ó jẹ oyè aṣípa Parakoyi ti ìlú Ìbàdàn ní Ìbàdàn
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "The unforgettable Olu Aboderin, 1934-1984". The Sun News. Retrieved 14 June 2015.
- ↑ "Buhari pays tribute to mauka pemu at 80". The Nation News. 12 June 2015. Retrieved 14 June 2015.
- ↑ "Remembering James Olubunmi Aboderin (1934-1984)". The Punch News. Archived from the original on 15 June 2015. Retrieved 14 June 2015.