Jump to content

Olusegun Adeniyi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Olusegun Adeniyi Olusegun_Adeniyi.wav Listen (born 6 November 1965) jẹ́ akọ̀ròyìn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, alága àgbà igbìmọ̀ àtúnṣe (Editorial Board) ti ìwé ìròyìn ThisDay lọ́wọ́lọ́wọ́, àti agbẹnusọ Ààrẹ fún Ààrẹ tẹ́lẹ̀ rí. Umaru Musa Yar'Adua.[1]

Ìgbésí-ayé Àkọ́kọ́ àti Ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Adéníyì ní Ile-Ife, Nàìjíríà . Ó sì gba ìwé ẹ̀rì BSc ní ọdún 1989 nínú Ìbáṣepọ̀ Àgbáyé (International Relations) ní ilé ẹ̀kọ́ gíga Fáṣítì Obafemi Awolowo, Ile-Ife. Ó tún gba ìwé ẹri Masters nínú Òfin Àgbáyé àti Ìbánisọ̀rọ̀ Ìṣèlú (MILD) ní ọdún 1997 ni ile eko giga Fáṣítì tí ìlú Èkó. Pẹ̀lú èyí, ó jẹ́ Akẹ́gbẹ́ (Fellow) ní Weatherhead Centre for International Affairs ní Harvard University láàárín àkókò ẹ̀kọ́ ọdún 2010/2012. .[2] Ó ṣe ìwádìí rẹ̀ lórí àwọn nǹkan tí ń dá ìdìbò Ààrẹ tó wà lórí àga sílẹ̀ ní ilẹ̀ Áfíríkà.


Iṣẹ́ Ìṣe rẹ

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ akọ̀ròyìn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi òṣìṣẹ́ olùjábọ̀ ìròyìn (Staff Reporter) pẹ̀lú ìwé ìròyìn ''The Guardian'' ní oṣù Kejìlá ọdún 1990. Ní oṣù Kẹrin ọdún 1992, ó fi iṣẹ́ náà sílẹ̀ láti darapọ̀ mọ́ ìwé ìròyìn ''African Concord'' (tí kò sí mọ́ báyìí) gẹ́gẹ́ bí Olùkọ̀wé Òṣìṣẹ́ Agba (Senior Staff Writer). Ní oṣù Kẹsán ọdún kan náà, wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí Olórí Ẹ̀ka Abuja (Abuja Bureau Chief) fún ìwé ìròyìn náà, pẹ̀lú ìfọwọ́sí láti máa darí ìròyìn ní Ilé Ìjọba Ìpínlẹ̀ (State House).


Adéníyì ẹni tí ó darapọ̀ mọ́ ìwé ìròyìn ThisDay ní oṣù Kínní ọdún un 1999 gẹ́gẹ́ bí Igbakeji Olóòtú ìwé ìròyìn Satide, gbéga di Olóòtú ìtẹ̀jáde Sunday ThisDay , àti ní oṣù Kẹjọ ọdún 2005, wọ́n yàn án sí ipò Olóòtú ìwé ìròyìn tí wọn pé àkọlé rẹ ni ThisDay. Ní ọjọ́ ìkẹyìn, oṣù Karùn-ún ọdún un 2007, Ààrẹ tẹ́lẹ̀ rí tí ó ti kú, Umaru Musa Yar'Adua, yàn án gẹ́gẹ́ bí Olùdámọ̀ràn Pátáki fún Ààrẹ lórí Ìròyìn àti Ìpolówó tí ayélujára (Special Adviser on Media and Publicity)ipò yìí sí ní ó di mú títí di ìgbà tí Yar’Adua kú ní ọjọ́ karùn-ún oṣù Karùn-ún ọdún 2010. Látìgbà náà ni ó ti ń kọ̀wé nípa ìrírí rẹ̀ nígbà tó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú Ààrẹ tó ti lọ.[3]

Ní oṣù Kéje ọdún un 2007, Adeniyi kópa nínú International Visitor Leadership Programme tí United States Department of State ṣètò. Ó tún jẹ́ Akẹ́gbẹ́ (Fellow) ní Weatherhead Centre for International Affairs ní Harvard University ní àkókò ọdún ẹ̀kọ́ 2010/2011.

Òun ni ó jẹ alága ìgbìmọ̀ àtúnṣe (Editorial Board) ìwé ìròyìn ThisDay lọ́wọ́lọ́wọ́. .[4] A fellow of the Nigeria Leadership Initiative (NLI), Adeniyi tún jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ olùdásílẹ̀ ti National Stakeholder Working Group ti Nigeria Extractive Industries Transparency Initiative (NEITI).

Ìgbésí-ayé Ara Rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adeniyi ti gbéyàwó, ó sì ní ọmọ mẹ́ta.

Àwọn ìwé tí ó ti kó

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adeniyi ni ó ṣe agbátẹrù àwọn ìwé wọ̀nyíi:

  • The Last 100 Days of Abacha[5]
  • Abiola’s Travails
  • Fortress on Quicksand
  • POLITRICKS: National Assembly under Military Dictatorship
  • Power, Politics and Death: A front-row account of Nigeria under the late President Yar’Adua
  • Against the Run of Play: How an incumbent president was defeated in Nigeria[6]
  • From Fry Pan To Fire[7]
  • Naked Abuse: Sex for Grades in African Universities[8]

Àwọn àmì ẹ̀yẹ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  • 1992 Jakande Prize or Political Reporter of the Year at Nigeria Media Merit Awards (NMMA)[9]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Olusegun Adeniyi. "Discussions on Pragmatic steps to moving Nigeria forward- How Understanding & Building the Right Institutions is Driving the Growth of Nations and Understanding the New Global Economy: How the internet, Social Media & Technology is Driving Business & Entrepreneurship". The Platform Nigeria 10.1 & 10.2. Retrieved 2015-04-28.
  2. "Olusegun Adeniyi, Chairman of the Editorial Board, ThisDay | The Future Project". Thefutureafrica.com. 2007-05-30. Archived from the original on 2015-06-01. Retrieved 2015-04-28.
  3. Category: ARTICLES (2014-08-24). "Power, Politics and Death: Confession of Yaradua's Segun Adeniyi". Elombah.com. Retrieved 2015-04-28.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  4. Powered by DMflex WebGen --- www.dmflex.com (2011-06-06). "Adeniyi Returns, Appointed THISDAY Editorial Board Chairman, Articles". This Day. Archived from the original on 2015-09-02. https://web.archive.org/web/20150902165012/http://www.thisdaylive.com/articles/adeniyi-returns-appointed-thisday-editorial-board-chairman/92733/. Retrieved 2015-04-28.
  5. Olusegun Adeniyi (2005). Last One Hundred Days of Abacha. Bookhouse Company. ISBN 9789780674601. https://books.google.com/books?id=j6cuAQAAIAAJ. Retrieved 2015-04-28.
  6. "Why I wrote 'Against The Run of Play' - TheCable" (in en-US). TheCable. 2017-04-28. https://www.thecable.ng/why-i-wrote-against-the-run-of-play.
  7. "'Afonja', 'Be(com)ing Nigerian' – The Top Nigerian Books Of 2019". December 31, 2019. Retrieved August 15, 2021 via Channels Television.
  8. Adeniyi, Olusegun (in English). Naked Abuse: Sex for Grades in African Universities. https://www.amazon.com/Naked-Abuse-Grades-African-Universities-ebook/dp/B08KJ4YFLG.
  9. Bivan, Nathaniel (2019-05-18). "Roving Heights hosts Olusegun Adeniyi today" (in en-GB). Daily Trust. https://www.dailytrust.com.ng/roving-heights-hosts-olusegun-adeniyi-today.html.