Oluwayomi Oluwapelumi
Oluwayomi Oluwapelumi jẹ́ agbóhùnsáfẹ́fẹ́, akọ̀ròyìn, ajàfẹ́tọ̀ọ́ àwọn ọ̀dọ́ àti olùdarí agbègbè ìbílẹ̀, ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Òun ni olóòtú kejì fún ètò Sunday Show lórí NTA.[1]
Ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè B.Sc. nínú ìmọ̀ Mass Communication, láti National Open University of Nigeria, bẹ́ẹ̀ sì ni ó gboyè Diploma nínú ìmọ̀ Mass Communication bákan náà, láti Nigerian Institute of Journalism. Yàtọ̀ sí èyí, ó gba ìwé-ẹ̀rí gẹ́gẹ́ bí akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ nínú ìmọ̀ kíkọ ìròyìn láti Nigerian Broadcast Academy.[2]
Iṣẹ́ rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Oluwapelumi ni olùdásílẹ̀ Sconcerns Media Network and Magazines Ltd & Recordbreaker Global Ventures. Ní ọdún 2024, ó darí ìfẹ̀hónúhàn kan láti dẹ́kun ìtàjẹsílè àwọn òṣìṣẹ́ tó ń rí sí ìdáàbòbò.[3] Ní ọdún 2022, ó gba àmì-ẹ̀yẹ lọ́wọ́ Lions Club fún iṣẹ́ ribiribi rẹ̀.[4]
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Oluwayemi, Oluwapelumi (2024-04-25). "Breaking News, Nigerian News, Paris2024, EndBadGovernanceInNigeria, Protest & Top Stories". PMNews Nigeria. Retrieved 2025-05-21.
- ↑ Online, ClipTv (2025-01-25). "International Day of Education: Amb. Oluwapelumi Urges Reforms and Community Development". ClipTv Online. Archived from the original on 2025-02-14. Retrieved 2025-05-21.
- ↑ https://thenationonlineng.net/group-seeks-end-to-attacks-on-security-personnel/
- ↑ https://theeagle.com.ng/topic/lion-oluwayomi-oluwapelumi-jegede-and-other-recognised-dignitaries-during-the-charter-presentation-and-installation-of-other-club-officers-on-june-11th/