Orin Sákárà
Orin Sákárà ni irúfẹ́ orin kan tí ó gbajúmọ̀ láàrín ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ orin ní ní àárín àwọn elédè Yorùbá ní a pa gúúsù ìwọ̀ Oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Wọ́n sábà ma ń fi orin Sákárà ki ènìyàn ni pẹ́lú lílo àwọn ohun èlò orin ìbílẹ̀ Yorùbá bí ìlù Sákárà, gòjé, ṣẹ̀kẹ̀rẹ̀ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ gbé ohùn dídùn jáde níkùn akọrin tí ó bá ń léwájú orin náà.[1] Ìwọ́hùn orin Sákárà fẹ́ fara jọ orin àwọn Lárúbáwá àti àwọn èdè míràn láti aríwá Áfíríkà, àmọ́ ohun tí ó fi yàtọ̀ sí wọn ni àwọn ohun èlò orin ti ẹ̀yà Yorùbá. [2] Orin náà ni ó sábà ma ń kún fún ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ tí ó sì ma ń tuni lára.[3] Púpọ̀ àwọn ònkọrin Sákárà ni wọ́n ti lo orin náà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ àselà tí wọ́n sì ti di olókìkí káàkiri àgbáyé. Lára wọn ni Abibu Olùwá tí ó bẹ̀rẹ̀ orin Sákárà ní ọdún láàrín ọdún 1930 ní ìlú Èkó. Lẹ́yìn tí Abibu Olùwá kú ní ọdún 1964, ẹni tí ó rópò rẹ̀ nínú ẹgbẹ́ akọrin wọn ni Salami Alabi Balogun tí wọ́n ń pe ní Salami Lefty tàbí Lefty Salami) tí ó jẹ́ onílù nínú ẹgbẹ́ náà ni ó ṣe àwo orin tí ó tó márùndínlógójì jáde lẹ́yìn ikú ọ̀gá rẹ̀. Àwọn tó kú nínú ọmọ ẹgbẹ́ akọrin wọn tí àwọn tún lààmì-laaka pẹ̀lú orin Sákárà ni: Baba Mukaila, àti Yusuf Olatunji.[4] Yusuf Ọlátúnjí tí wọ́n ń pe ní Bàbá lẸ́gbá gbìyànjú gidi láti ri wípé iná orin Sákárà jo láálá, òun náà gbé àwọn àwo orin Sákárà oríṣiríṣi jáde lábẹ́ ilé-iṣẹ́ agbórinjáde Phillip Nigeria. Òun náà kú ní ọdún 1978. Wọ́n fi òpópónà kan kan sórí orúkọ rẹ̀ ní ìlú Abẹ́òkúta.[5]
Púpọ̀ nínú àwọn ẹ̀ka orin Yorùbá tó kù bíi orin jùjú,fújì àti orin hip hop ni orin Sákárà kò ipa tó lọ́ọ̀rìn nínú kíkọ wọn .[4] orin fújì is a mixture of Muslim traditional orin wéré with elements drawn from Sakara and Apala music.[3]
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ John Collins (1985). Musicmakers of West Africa. Lynne Rienner Publishers. p. 49. ISBN 0-89410-075-0. https://archive.org/details/musicmakersofwes00coll/page/49.
- ↑ Michael E. Veal (2000). Fela: the life & times of an African musical icon. Temple University Press. p. 28. ISBN 1-56639-765-0. https://archive.org/details/felalifetimesofa00veal.
- 1 2 "History of Nigerian Music". OnlineNigeria. Retrieved 2010-01-31.
- 1 2 "Azeez Ojutiku - Bio". MyRhythm.com. Archived from the original on January 21, 2009. Retrieved 2010-01-31. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ Maurice Archibong (July 29, 2004). "Abeokuta’s many minstrels and a museum". Daily Sun. Archived from the original on October 14, 2007. Retrieved 2010-01-31. Unknown parameter
|url-status=ignored (help)