Pascal Atuma jẹ́ òṣèrékùnrin ti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, olùdarí erẹ́, àti oníṣòwò.[1] Òun ni olùdásílẹ̀ ilé-iṣẹ́ TABIC Record Label, èyí tó jẹ́ ilé-iṣẹ́ agbórinjáde.
Wọ́n bí Pascal sí ìlú Ikwuano, ní Umuahia, ìpínlẹ̀ Abia, ó sì lọ sí Government College, Umuahia, àti University of Port Harcourt, Rivers State. Ó tún lọ sí KD Conservatory-College of Film & Dramatic Arts ní Dallas, Texas, US, láti lọ kẹ́kọ̀ọ́ nípa iṣẹ́ tíátà. Bẹ́ẹ̀ sì ni ó gba àmì-ẹ̀yẹ Entrepreneurship Specialization láti University of Pennsylvania.
Ó ṣàfihàn nínú àwọn fíìmù bí i Sweet Revenge, Eat my Shorts láti ọwó Lions Gate, Bloodlines, LAPD African Cops, The Other Side of Love, My American Nurse, àti Secret Past. Ó fìgbà kan jẹ́ olóòtú ètò orí ẹ̀rọ-amóhùnmáwòrán kan, èyí tí ń ṣe One-World with Pascal Atuma, àti The House of Commons. Ó jẹ́ olùdarí fíìmù Professor Johnbull fún apá mẹ́tàlá àkọ́kọ́ àti Clash (2019).
Ó ní ìfọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú Kastina State Ministry of Youths and Sports Development.[2]
Atuma gba àmì-ẹ̀yẹ fún Òṣèrékùnrin tó dára jù lọ ní ọdún 2012 àti 2015, ní Golden Icons Academy Movie Awards (GIAMA). Wọ́n fún ní àmì-ẹ̀yẹ ní ọdún 2013, ní Los-Angeles Nollywood Film Award (LANFA) nítorí àwọn iṣẹ́ ribiribi tí ó ti ṣe àti fún ipa rẹ̀ nínú iṣẹ́-tíátà. Bẹ́ẹ̀ sì ní fíìmù rẹ̀, L.A.P.D. African Cops gba àmì-ẹ̀yẹ fuhn fíìmù tó dára jù lọ ní ọdún 2015.