Patrick Ekeji
Patrick Chima Ekeji tí wọ́n bí ní ọjọ́ kọkànlá oṣù ẹrẹ́nà, ọdún 1951, jẹ́ alábòójútó eré ìdárayá tẹ́lẹ̀ rí ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà [1] [2] àti agbábọ́ọ̀lù . Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ní Yunifásítì Nàìjíríà, Nsukka, níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí àkọ́kọ́ nínú Ẹ̀kọ́ ìdáraya Ara (Physical Education) ní ọdún 1978, àti ilé ẹ̀kó gìga Yunifásítì ti Frankfurt,tí ó wà ní orílẹ̀ èdèe Germany, tí ó kẹ́kọ̀ọ́ jáde ní ọdún 1982. Gẹ́gẹ́ bí ọmọ ilé ẹ̀kọ́ girama, Ekeji ṣe iṣẹ́ agbófinró fún East Central State Academicals, ósì jáwé olúborí ní Manuwa Adebajo Cup ní ọdún 1971.
Ekeji lọ sí St Jude's Catholic Primary School, Amuzi, Ìpínlẹ̀ Imo ní ọdún (1955); St Mathias Catholic School, Lafiaji tí ó wà ní ìlú Èkó ní ọdún (1956); St George's Primary School, Falomo, tí ó wà ní ìlú Èkó ní ọduń (1958–1962); St Gregory's College, tí ó wà ní ìlú Èkó ní ọdún (1963–1967); Community Secondary School, Amuzi (1970); Ilé-ìwé Atẹle Mbaise (WASC, 1971); Ilé-ẹ̀kọ́ Ẹ̀mí Mímọ́, ti ìlú Owerri (1971–1972).
Àwọn kókó iṣẹ tí Ekeji ṣe nínú bọ́ọ̀lù aláfẹsègbá pẹ̀lú àwọn àmì-iṣẹ́ pẹ̀lú ẹgbẹ́ orílẹ̀-èdè, Green Eagles (1975–1980); Rangers of Enugu (1977/1978); àti Vasco Da Gama FC Enugu (1973–1977). Ekeji tún gbá bọ́ọ̀lù f´n ẹgbẹ́ East Central State, Àwọn Spartans, ẹni tí ó jáwé olúborí nínú àmì ẹ̀yẹ góòlù bọ́ọ̀lù níbi ayẹyẹ àjọ̀dún 1st National Sports, Lagos ní ọdún 1973.
Lẹ́yìn ìyànsipò rẹ̀ ní ọdún 1993 gẹ́gẹ́ bìi olùdarí eré ìdárayá ní ìpínlẹ̀ Imo, Ekeji ni wọ́n yàn gẹ́gẹ́ bíi olùdarí eré ti ìjọba àpapọ̀ tí a mọ̀ sí National Sports Commission ní oṣù Kejìlá ọdún 1994. Olùdarí Ìdàgbàsókè eré ìdárayá ní National Sports Commission, ọdún 2001, àti Olùdarí Gbogboogbò, National Sports Commission ni ọdún 2009, ó kọ ìwè ìfẹ̀yìntì ní ọdún 2013. Ekeji jẹ olùkọ́ni ní ṣókí fùn ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù orílẹ-èdè nàìjíríà ní ọdún 1986. O gbé Ngozi Immaculata Pat Ekeji ní ìyàwó, ọba òkè sì fi ọmọ mẹfa jíǹkì ìgbéyàwó wọn.