Jump to content

Ràshídì Adeéwọlú Ládọjà

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Adewolu Ladoja
Olubadan of Ibadan

Reign 26 September 2025 – present
Coronation 26 September 2025
Predecessor Owolabi Olakulehin
Lórí àga
7 December 2006  29 May 2007
DeputyAdebayo Alao-Akala
AsíwájúAdebayo Alao-Akala
Arọ́pòAdebayo Alao-Akala
Lórí àga
29 May 2003  12 January 2006
DeputyAdebayo Alao-Akala
AsíwájúLam Adesina
Arọ́pòAdebayo Alao-Akala
Lórí àga
5 December 1992  17 November 1993
Arọ́pòPeter Olawuyi Adeyemo (1999)
Spouse Olayinka Mutiat Ladoja
House Otun
Born 25 Oṣù Kẹ̀sán 1944 (1944-09-25) (ọmọ ọdún 81)
Gambari, Ibadan, Southern Region, British Nigeria (now in Oyo State, Nigeria)
Occupation
  • Politician
  • Businessman
Religion

Ọba Adéwọ̀lú Ládọjà tí a bí ni ọjọ́ karùndínlọ́gbọ̀n Oṣù Kẹsàn-án ọdún 1944) jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọba ilẹ̀ yorùbá ní orílẹ̀ édé Nàìjíríà. Ó jẹ́ Olúbádá kẹrinlélógójì ní ìlú Ibadan.

Ṣáájú kí ó tó gbadé, Ládọjà jẹ́ olóyè àti olóṣèlú tó ti fi ìgbà kan jẹ́ gómìnà ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ láti ọdún 2003 sí ọdún 2006; àti láti ọdún 2006 si 2007; àti gẹ́gẹ́bíi aṣòfin tó ṣojú ẹkùn gúsù ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ láti ọdún 1992 sí ọdún 1993. Ní Oṣù Kẹjọ ọdún 2025, ìjọba ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ kéde wípe òun ni yóo jẹ Olúbàdàn ti ilẹ̀ ìbàdàn kẹrìnlélógójì nípasẹ̀ Gómìnà ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, Seyi Makinde. Ayẹyẹ ìgbadé rẹ̀ wáyé ní ọjọ́ kẹrìndínlọgbọ̀n oṣù kẹsàn-àn ọdún 2025, ọjọ́ kejì ọjọ́ ìbí rẹ̀ tí ó pé ẹni ọdún mọ́kànlélọ́gọ́rin.

Ìgbà ìbí/èwe rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Ládọjà ní ọjọ́ ọjọ́ karùndínlọ́gbọ̀n oṣù kẹsan ọdún 1944 ní abúlé Gambari nítòsí Ibadan. Ó lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Girama àwọn Ọmọkùnrin Ibadan ní ọdún (1958 sí 1963) àti Ilé Ẹ̀kọ̀ Girama ti ìjọ onítẹ̀bọmi ti Olivet ní ọdún (1964 sí1965). Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ní Yunifásítì Liège, Belgium ní ọdún (1966 sí ọdún 1972) níbi tó ti kẹ́kọ̀ó gboyè nínú ìmọ̀ àwọn èròja tí a fi ń ṣẹ̀dá. Ó ríṣẹ́ kan ní ilé iṣẹ́ epo kan tó ń jẹ́ Total Nigeria, níbi tó ti ṣiṣẹ́ fún ọdún mẹ́tàlá ní onírúurú ipò kí ó bẹ̀rẹ̀ òwò ti ara rẹ̀ ní ọdún 1985. Awọn abala okòwò to fẹ́ràn ni ọkọ̀ ojú omi, ṣíṣẹ̀dá àwọn nǹkan, ilé ifowopamọsí, ọ̀gbìn àti ìgbòkègbodò ọkọ̀.[1] Nígbà tó di ọdún 2000, Ladoja ti di olùdarí ilé ìfowópamọ́sí Standard Trust Bank Limited.

Aṣòfin tó ń ṣojú ìpínlẹ̀ Oyo

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní àkókò ìjọba olominira Kẹta Naijiria, a dìbò yàń gẹ́gẹ́ bí aṣòfin si ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ágbá ti orílẹ̀ èdè Naijiria ní ọdun 1992 gẹ́gẹ́bí ọmọ ẹgbẹ́ ti Social Democratic Party . [2]

Gẹ́gẹ́bíi Gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A dìbò yan Ládọjà gẹ́gẹ́bí gómìnà ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní Oṣù Kẹrin ọdún 2003 lábẹ́ àsìà ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, ó sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n Oṣù Karun, ọdun 2003. [1] Alhaji Lamidi Adedibu, èèkan gbóògì nínú ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní ìpínlẹ̀ náà ni ó ṣe àtìlẹyìn fún un. Nígbà tó fi máa di oṣù kẹjọ ọdún 2004, ìjàkadì tó lágbára ti bẹ́ sílẹ láàárin Ladoja àti Adedibu ti lórí pípín àwọn tí ìjọba yàn sípò. Àwọn ẹgbé kọ ẹ̀yìn sí Ladoja ọ̀rọ̀ yìí. Nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan tó wáyé ní òpin ọdún 2005, alága gbogboogbò fún ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní Nàìjírià, Ahmadu Ali, sọ pé Ládọjà yẹ kí ó gba ìtọ́nisọ́nà làti ọ̀dọ̀ Làmídì Adédibú.

Ní ọjọ́ kejìla oṣù kíńní ọdún 2006, àwọn aṣòfin ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ fi ẹ̀sùn kan Ladoja, wọ́n sì fipá yọọ́ kúrò nípò. Igbákejì rẹ̀, Christopher Adebayo Alao-Akala, ni wọ́n búra fún gẹ́gẹ́ bíi gómìnà tuntun. Ní ọjọ́ kìnńí oṣù kọkànlá ọdún 2006, Ilé Ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn ní ìlú Ìbàdàn, olú ìlú ìpínlẹ̀ náà, kéde pé ìyọninípò náà kò bófin mu, ṣùgbọ́n ó gbà wọ́n níyànjú pé kí wọ́n dúró de ìmúṣẹ ìpinnu yìí láti ọwọ́ Ilé Ẹjọ̣ tó Gíga jùlọ. Ilé Ẹjọ́ Gíga jùlọ fọwọ́ sí ìpinnu náà ní ọjọ́ kọkànla oṣù kọkànla ọdún 2006, Ladoja sì tún padà sípò ní ọjọ́ kejìlá oṣù kejìlá ọdùn 2006. Àwọn ọlọ́pàá kògbérěgbè ni wọ́n ti kó sí àwọn tó lọ sí ilé ìjọba latí dènà ìwà jàǹdùkú láti ọwọ́ àwọn olólùfẹ́ ti Adebayo Alao-Akala ati Lamidi Adedibu lákòkǒ tí ó ń padà sórí oyè.

Ládọjà kùnà láti gba àṣẹ nínú ẹgbẹ́ òṣèlú PDP gẹ́gẹ́ bí olùdíje fún ìgbà kejì. Ó pinnu láti ṣe àtìlẹyìn fún àwọn olùdíje láti inú ẹgbẹ́ òṣèlú ti Action Congress nínú èto ìdìbò sí àwọn ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n tí ó wà ní ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́. Ẹgbẹ́ PDP kọ̀ láti kópa nínú ètò ìdìbò náà. Lẹ́yìn èyí, àbájáde ètò ìdìbò náà fìdí rẹ̀ múlẹ̀ wípé ẹgbẹ́ òṣèlú ti Action Congress (AC) borí ní ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n, tí ẹgbẹ́ òṣèlú All Nigeria Peoples Party (ANPP) borí ní ìjọba ìbílẹ̀ méje. Sibẹsibẹ, ẹni tí ó gba ipò lọ́wọ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi gómìnà, tí ó tún jẹ́ igbákejì rẹ̀ àti gómìnà tẹ́lẹ̀ Christopher Adebayo Akala, yọ gbogbo àwọn alága ìjọba ìbílẹ̀ náà ní kété tí ó gba ọ̀pá àṣẹ tó sì rọ́pò wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú ti PDP.

Ìgbé ayé rẹ̀ lẹ́yìn Gómìnà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹjọ ọdun 2008, àjo EFCC gbé Ládọjà látàrí ẹ̀sùn wípé kò kó owó tó dín díẹ̀ ní bilionu méjì Náírà èyí tí wọ́n rí níbi títa ìpín ìdókòwò ìjọba sílẹ̀ nígbà ìṣàkóso rẹ̀. [3] Ilé-ẹjọ́ gìga tí ìjọba àpapọ̀ tí ó ń jókòó ní ilu Eko pàṣẹ kí wọ́n fi sí àtìmọ́lé fún ìgbá díẹ̀ ni ọgbọ̀n ọjọ́ Oṣù Kẹjọ ọdún 2008. [4] A gba onídǔró rẹ̀ ní ọjọ́ ọjọ́ karùn-ún Oṣù Kẹsàn-án, ní iye owó tí ó jẹ́ mílíọ̀nù lọ́nà ọgọ́rùn-ún naira pẹlu onídùró méjì ní iye owó kanńà. [5] Ní Oṣù Kẹta ọdún 2009, ọ̀kan lára àwọn amúgbálẹ̀lẹ́ tẹ́lẹ̀ fún Ládọjà jẹ́rìí lórí ọ̀nà tí wọ́n gbà pín owó ìpín ìdókòwò láàrín ìdílé Ládojà, ẹ̀ṣọ́, àwọn àgbà olósèlú àti àwọn agbẹjọ́rò.

Ládọjà jẹ́ olùdíje fún ipò gomina lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú Accord ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní àkókò ìdìbò tí ó wáyé ní Oṣù Kẹrin ọdún 2011 ati 2015, ó pàdánù sí ọwọ́ Aṣòfin Abiola Ajimobi. Ní ọdún 2017 ó da ẹgbẹ́ rẹ̀ tíí ṣe Accord Party papọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú PDP. Ìjà tó wáyé nínú ẹgbẹ́ òṣèlú PDP mú kí òun àtàwọn alátìlẹ̀lẹyìn rẹ̀ (láti ẹgbẹ́ òṣèlù Labour, All Progressives Congress APC, àti bẹ́ẹ̀ lọ) kó lọ dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú African Democratic Congress (ADC) lọ́dún 2018. Lẹ́hìn ìgbà díẹ̀ nínú ẹẹ́ òṣèlú ADC èyítí ó fihàn pé ó jẹ́ ìbáṣepọ̀ láàárín àwọn àjèjì, Ládọjà pẹ̀lù àwọn alátìlẹyìn rẹ̀ yalọ sí inú ẹgbẹ́ òṣèlú Zenith Labour Party (ZLP) ní Oṣù kejìlá ọdún 2018.

Gẹ́gẹ́ bíi Olúbàdàn

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ládọjà di Ọba lẹ́hìn tó gba adé ẹ̀yẹ àti ìlẹ̀kẹ̀ iyùn Olúbàdàn láti ọwọ́ ìjọba ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní ọjọ́ kejìlá Oṣù Kẹjọ ọdún 2024.

Lẹ́hìn ikú Ọba Owólabí Olákùlẹ́hìn, Olúbàdàn kẹtàlélógójì, Làdọjá ni a kéde gẹ́gẹ́ bíi Olúbàdàn tuntun ni ọjọ́ keje Oṣu Keje, ọdun 2025.

Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹjọ ọdún 2025, Gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo, Seyi Makinde, fọwọ́ sí Ladoja gẹ́gẹ́ bí ẹni tí yóò jẹ Olúbàdàn kẹrinlélógójì, ó sì ṣètò ayẹyẹ ìgbadé rẹ̀ ní ọjọ́ ẹtì, ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n oṣù kẹsàn-àn ọdún 2025 ní gbọ̀ngàn ńlá ti Màpó.

Nínú ìwé ìtàn, ọba Ládọjà ni ẹni àkọ́kọ́ tí yó jẹ Gómìnà alágbádá tí ó tún padà wá di ọba ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. 1 2 Empty citation (help)
  2. Empty citation (help)
  3. Empty citation (help)
  4. Empty citation (help)
  5. Empty citation (help)