Samuel Ademulegun
Brigadier Samuel Adesujo Ademulegun (ti a bí ni Ogúnjọ́ oṣù kẹwa ọdún 1924 – Ogúnjọ́ oṣù kínní ọdún 1966) jẹ ọgagun Naijiria ti o jẹ ọgagun apàṣẹ [1] ti 1st Brigade nígbà ìgbimọ ológun oṣù kínní ọdún 1966 .
Ìbẹrẹ Ìgbésí ayé ati ebi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bi i ni Ogúnjọ́ Oṣu Kẹwa Ọdún 1924 ni Ilu Ondo, Ìwọ̀-oòrùn Nàìjíríà, àti pé wọn jẹ ọkàn nínú àwọn oṣiṣẹ to dára jùlọ ni orílẹ-èdè ni àkókò yẹn. [2] Ọmọ Ọgbẹni ati Iyaafin Michael Ademulegun, o ti kọ ẹkọ rẹ ni ipinlẹ Ondo ṣáájú ki o to darapọ mọn àwọn ọmọ ológun Nàìjíríà (Nigerian Army) ni ẹni to daduro ní ọdún 1942. [3] Ademulegun fẹ Latifat Feyisitan Abike Ademulegun (nee Noble) ti a tun mo si Sisi Nọ́ọ̀si.
Iṣẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ọdún 1949 ní wọn yán Ademulegun sípò ológun, o si jẹ ọkàn lara ọgá ọgá ológun pẹlu Aguiyi Ironsi, Zakariya Maimalari ati Babafemi Ogundipe . O wa láàrin àwọn ti a gbèrò lati fun ni ipo ọmọ ogún giga ti GOC ni ọdún 1965 lori ifẹhinti lẹnu iṣẹ ti Alakoso Gbogboògbò ti ilu òkèèrè (GOC). Wọ́n kà á sí ọ̀rẹ́ pẹ̀lú Ahmadu Bello, èyí sì kó ìbànújẹ́ bá àwọn ọ̀gá àgbà kan tí wọ́n dojú kọ ọ̀gá wọn tí wọ́n ń bá àwọn olóṣèlú ṣe.
Iku
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ademulegun ati iyawo rẹ ni wọn pa nígbà ti wọn wa lóri ibùsùn lásìkò ti ologun gbajoba ni ọdún 1966 nígbà ti awọn ọlọtẹ ti Timothy Onwuatuegwu darí yin ìbon pa wọn, olukọni ni ilè ìwé ẹkọ ológun ti Nàìjíríà. [4] [5] Ninu iroyin ẹlẹri ti ipaniyan ti ọmọbìnrin rẹ, Solape Ademulegun-Agbi, o sọ bi àwọn ọmọ ológun ṣe pa baba rẹ. Akọọlẹ rẹ pese awọn alaye nipa ikọlu ati ipaniyan ti o burújú ti Alákóso iṣáájú (GOC), ẹka kinni ni ipinlẹ Kaduna . Ti wọn pa ninu ìgbà jọba ológun akọkọ ni Nàìjíríà, àwọn aṣebi náà ti wa ni akọsilẹ pe wọn n gba orilẹ-ede náà kuro lọwọ awọn olóṣèlú onibajẹ ati awọn ti wọn sunmọ wọn. [6]
Àwọn ọmọ ti o gbẹyin rẹ̀ ní Ọmọbinrin rẹ Iyaafin Solape Ademulegun-Agbi, Bankole, Kunle, Gbenga, Goke, ati akọbi rẹ Frank Bamidele ti o wa ni ile-iṣẹ ologun ofurufu Naijiria ti o ti de ipo Captain Group ṣaaju ki o to ku ni ọdun 2002. [7]
Awọn itọkasi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Federal Government of Nigeria (1965). Federal Republic of Nigeria Official Gazette. 52. Lagos, Nigeria: The Federal Ministry of Information, Printing Division. https://gazettes.africa/archive/ng/1965/ng-government-gazette-dated-1965-10-01-no-75.pdf.
- ↑ http://www.citypeopleonline.com/brigadier-samuel-ademulegun-with-his-pregnant-wife-and-children/
- ↑ https://topcelebrities.com.ng/murder-brigadier-samuel-ademulegun-pregnant-wife/
- ↑ Let truth be told. Zaria, Nigeria. 1982.https://en.wikipedia.org/wiki/Samuel_Ademulegun#cite_ref-4
- ↑ Military regimes and nation building in Nigeria, 1966-1999. 2013.https://en.wikipedia.org/wiki/Samuel_Ademulegun#cite_ref-5
- ↑ https://punchng.com/first-1966-coup-though-painful-im-happy-witnessed-killing-parents/
- ↑ https://www.vanguardngr.com/2019/06/death-didnt-stop-ojukwu-ademulegun/
Akasiwsju
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Obi-Ani, Ngozika A.; Obi-Ani, Paul (2016). "January 15 1966 Coup d' Etat Reconsidered". Nsukka Journal of the Humanities 24 (2): 16–26. https://oer.unn.edu.ng/read/nsukka-journal-of-the-humanities-vol-24-no2-january-15-1966-coup-d-etat-reconsidered.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]