Jump to content

Simi Drey

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Simi Drey

Simileoluwa Audrey Adejumo tí gbogbo ènìyàn mọ̀ sí Simi Drey (tí a bí ní ọjọ́ 5 oṣù kẹfà) jẹ́ òṣeré Bírítìṣì-Nàìjíríà, olóòtú ètò amóhùnmáwòrán àti olùgbàlejò. Ní ọdún 2019, ó gba àmì ẹ̀yẹ Future Awards Africa fún Best OAP. Ní ọdún 2016, ó kópa nínú eré ọlọ́sọ́ọ̀sẹ̀ orí amóhùnmáwòrán Nollywood TV series Tinsel, tí ó kó ipa ẹ̀dá ìtàn Amanda.

Ìtàn Ìgbésí ayé

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Simi Audrey Adejumo ní ọjọ́ 5 oṣù kẹfà ní London, United Kingdom ṣùgbọ́n tí ó wà láti Ìbàdàn, Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, ìran ti Ologun Kutere . Òun ni ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n pátápátá nínú àwọn ọmọ márùn-ún ti Professor David Olusoji Adejumo, Alága tẹ́lẹ̀ ti ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ Universal Basic Education àti Mrs. Emilomo Adejumo. Simi lo púpọ̀ nínú ìgbà èwe rẹ̀ ní United Kingdom Pẹ̀lú àwọn àbúrò rẹ̀. Ibẹ̀ náà ni ó ti ka ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti sẹ́kọ́ńdírí rẹ̀. Bàbá bàbá bàbá Simi, Ọ̀jọ̀gbọ́n Oladele Adebayo Ajose jẹ́ ọmọ ọba Èkó tí ó kọ́kọ́ ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Gíwá ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti Obafemi Awolowo University.

Ó súnmọ́ ìyá ìyá rẹ̀ gan-an, Audrey Olatokunbo Ajose, agbẹjọ́rò ilẹ̀ Nàìjíríà àti akọ̀ròyìn tí ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí aṣojú Nàìjíríà fún Scandinavia láti ọdún 1987 sí 1991, ó sì ṣe ìwúrí fún Adejumo láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí akọ̀ròyìn. Ní ọdún 2014, ó parí pẹ̀lú First Class Degree nínú Broadcasting, Journalism and Media Communications láti Ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti University of Wales, United Kingdom.

Adejumo ní ìfẹ́ sí kíka ìròyìn láti ìgbà tí ó ti wà ní kékeré. Nígbà tí ó wà ní ilé ẹ̀kọ́ gíga, ó ṣe ìdásílẹ̀ ó sì ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olóòtú fún ìwé ìròyìn akẹ́kọ̀ọ́, GMag. Ní ọdún 2011, nígbà tí ó sì wà ní ilé ẹ̀kọ́ gíga, iṣẹ́ rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ní pẹrẹu nígbà tí ó gba iṣẹ́ rẹ̀ àkọ́kọ́ ní while still in ilé iṣẹ́ rédíò kan ní Wales tí wọ́n ń pè ní Calon FM. Ní oṣù keje ọdún kan náà, ó ṣe ìrìn-àjò lọ sí Nàìjíríà ó sì ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ ẹ̀kọ́sẹ́ ní ilé iṣẹ́ amóhùnmáwòrán HiTV, Ìpínlẹ̀ Èkó. Lẹ́yìn tí ó parí ẹ̀kọ́sẹ́ rẹ̀ tán, ó pinnu láti padà wá sí Nàìjíríà After the kí ó sì tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ rẹ̀ níbẹ̀. Lẹ́yìn tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí rẹ̀ ti Ilé-ẹ̀kọ́ gíga ní ọdún 2013, ó padà sí Nàìjíríà pátápátá. Lẹ́yìn ìsìnrú rẹ̀ NYSC, ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú Cool TV fún ọdún méjì gẹ́gẹ́ bí olùgbàlejò ètò The Late Night Show, síwájú kí ó tó darapọ̀ mọ́ Spice TV tí ó sì ń tukọ̀ ètò wọn, Bargain Hunters ní ọdún 2016.

Ní ọdún yẹn bákan náà, ó kópa nínú fíìmù ọlọ́sọ́ọ̀sẹ̀ Nollywood series The Governor, tí ó kópa gẹ́gẹ́ bí Ify Ochello. Lẹ́yìn náà ni ó tẹ̀síwájú láti kópa nínú ètò ọlọ́sọ́ọ̀sẹ̀ orí amóhùnmáwòrán tó gùn jù lọ Nollywood's longest running TV series Tinsel. Nígbà tó wà níbi ìṣeré ti Tinsel, wọ́n lò ó fún ipa ẹ̀dá ìtàn Amanda nínú fíìmù Happy Father's Day (2016) àti àwọn èyí tí ó tẹ̀lé e Another Father's Day (2019).

Ní oṣù Kejìlá ọdún 2016, ó darapọ̀ mọ́The Beat 99.9 FM níbi tí ó ti tukọ̀ ètò Saturday and Sunday Morning fún ọdún mẹ́ta síwájú kí wọ́n tó gbé e lọ sí àárín ọ̀sẹ̀ ètò Morning Rush èyí tí ó máa ń tukọ̀ pẹ̀lú Osikhena Dirisu. Nígbà tí ó wà ní Beat FM, ní ìfọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú MTV Base, wọ́n yàn án fún àmì ẹ̀yẹ MTV EMAsSeville, Spain ní oṣù Kejìlá ọdún 2019.

Ní ọdún 2019, ó padà sí orí amóhùnmáwòrán ó sì di akàròyìn fún 53 Extra (tí a mọ̀ tẹ́lẹ̀ sí Studio 53) lórí Africa Magic títí di ìpele tó kẹ́yìn ní ọdún 2020, lẹ́yìn èyí ló di olùgbàlejò ètò Movie Talk lórí ìkànnì African Movie Channels.

  • The Governor (2016)[1]

|- |ELOY Awards |Award for TV personality |style="background: #FDD; color: black; vertical-align: middle; text-align: center; " class="no table-no2"|Wọ́n pèé |[2][3] |- |2023 |Icon Noble Awards |On Air personality of the year |Gbàá | |}

Ní oṣù kẹfà ọdún 2022, Simi Drey jọ́hẹn fún olùdásílẹ̀ BFree, Julian Flosbach. Àwọn lọ́kọláyà náà ṣe ìgbéyàwó ìbílẹ̀ wọn àti ìgbéyàwó ilẹ̀ òkèèrè ní oṣù karùn-ún ọdún 2023 ní Ibadan àti Lagos State, Nigeria ní sísẹ̀ntẹ̀lé.

  1. {{Citation |title="The Governor" The Offer (TV Episode 2016)
    • Happy Father's Day (2016)
    • Tinsel (2017)
    • Another Father's Day (2019)
    • A Lady and Her Lover (2021)

    Àwọn àmì ẹ̀yẹ

    Year Title Category Result Ref
    2015 Trek African Women Awards TV presenter of the year Gbàá 2019 The Future Awards Africa Prize for OAP Gbàá <ref>"At 21, OAP and Media Personality— Simi Drey is the Youngest African to Win The Future Awards – Leading Ladies Africa" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2024-02-22. Retrieved 2024-02-22. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  2. "ELOY Awards 2019 Winners Emerge - THISDAYLIVE". www.thisdaylive.com. Archived from the original on 2024-02-23. Retrieved 2024-02-23. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. "ELOY Awards 2019 Nominees List – Glitz Africa Magazine" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2024-02-23. Retrieved 2024-02-23. Unknown parameter |url-status= ignored (help)