Jump to content

Solomon Olamilekan Adeola

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Solomon Adeola

Senator for Ogun West
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
13 June 2023
AsíwájúTolu Odebiyi
Senator for Lagos West
In office
9 June 2015  11 June 2023
Serving with Oluremi Tinubu and Tokunbo Abiru
AsíwájúGaniyu Solomon
Arọ́pòOluranti Adebule
Vice-Chairman of the
Senate Committee on Communications
In office
17 September 2015  9 June 2019
AsíwájúGilbert Nnaji
Member of the Nigerian House of Representatives
In office
6 June 2011  6 June 2015
AsíwájúEmmanuel Oyeyemi Adedeji
Arọ́pòOluwafemi Adebanjo
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí
Solomon Olamilekan Adeola

10 Oṣù Kẹjọ 1969 (1969-08-10) (ọmọ ọdún 56)
Lagos, Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúAll Progressives Congress
(Àwọn) olólùfẹ́Temitope Adeola
Alma materRufus Giwa Polytechnic
Occupation
  • Politician
  • accountant
Websiteyayiadeola.com.ng/

Solomon Olamilekan Adeola CON tí a tún mọ̀ sí Yáyì (tí a bí ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹjọ ọdún 1969), jẹ́ olóṣèlú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin fún Ìwọ̀ oòrùn Ògùn láti ọdún 2023. Ó fi ìgbàkan jẹ́ Aṣòfin tó lọ ṣojú Ìwọ̀ oòrùn ìlú Èko láti ọdún 2015 sí 2023. [1] Láti ọdún 2011 sí 2015, ó jẹ́ Alága Ìgbìmọ̀ Ilé Aṣojú Ṣòfin lórí ọ̀rọ̀ ará ìlú. Ó tún jẹ́ akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ oníṣírò owo àti ọmọ ẹgbẹ́ àjọ àwọn akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ oníṣírò owo (AAT). [2] [3]

Ìgbésí ayé rẹ̀ àti àwọn Ilé ẹ̀kọ́ tó lọ

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Adeola ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹjọ ọdún 1969, ní ilé ìwòsàn agbẹ̀bi ní erékúsù ìlú Èkó fún Àyìndé Adéolá Ògúnlẹ́yẹ àti Àbẹ̀ní Ọlásùńbọ̀ Ògúnlẹ́yẹ (tí a bí ní Akinọlá). Ó dàgbà ní Àlímọ̀shọ́ níbi tí ó ti bẹ̀rẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̌bẹ̀rẹ̀ ti Ìjọba ní Àlímọ̀ṣọ́, ní ìlú èkó. Ó tẹ̀síwájú sí Ilé-ẹ̀kọ́ girama ti agbègbè tó wà ní Akówọnjọ, ní ìlú èkó fún ẹ̀kọ́ girama rẹ̀. Lẹ́yìn náà ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìṣe ti ìpínlẹ̀ Ondo, èyí tí ó wà ní ìlú Ọ̀wọ̀ tí a ti yí padà sí ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìṣe Rufus Giwa, Ọ̀wọ̀, ìpínlẹ̀ Oǹdó níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí Díplómà àgbà (HND) nínú ìmọ̀ ìṣirò owó . [4]

Adeola jẹ́ akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ oníṣírò owo àti ọmọ ẹgbẹ́ àjọ àwọn akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ oníṣírò owo(ICAN) ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.[citation needed][<span title="This claim needs references to reliable sources. (February 2024)">citation needed</span>]

Àwọn ibi tí ó ti ṣiṣẹ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adéọlá ṣiṣẹ́ pẹ̀lu ìwé ìròyiìn pàtàkì kan ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, The Guardian Newspapers fún ọdún méjìlá, o sì ní ìgbéga sí ipò Akọ̀wé-owó.

Adéọlá tẹ̀síwájú lọ sí ilé iṣẹ́ Ọlátúnjí Ọmọ́yẹni & Co, ilé-iṣẹ́ ìṣirò owó tí wọ́n fún ní ìwé àṣẹ, níbi tí ó ti jẹ́ olórí àwọn aṣàyẹ̀wò níná owó fún ọ̀pọ̀ ọdún, lẹ́yìn náà ni wọ́n gbé e ga sí ipò Olùṣàyẹ̀wò Àgbà. Lẹ́yìn náà, ó dá ilé-iṣẹ́ tirẹ̀ sílẹ̀, èyí tí ó pè ní SOOTEM Nigeria Limited, níbi tí ó ti jẹ́ olùdarí àgbà àti olórí àgbà ní ilé-iṣẹ́ tí ó olùkànsí pàtàkì nípa ọ̀rọ̀ owó-orí.

Gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Lẹ́yìn ìpinnu rẹ̀ láti dara pọ̀ mọ́ òṣèlú, nígbà kan ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba kẹrin, wọ́n yan Adéọlá, ó sì borí nínú ìbò abẹ́le lábẹ́ àsìà ẹgbẹ́ òṣèlú ti Action Congress of Nigeria tí ó ń ṣàkóso ní Ìpínlẹ̀ Èkó nígbà náà, wọ́n sì yàn án gẹ́gẹ́ bí ọmọ ẹgbẹ́ láti ṣojú fún agbègbè Àlímọ̀ṣọ́ kejì, ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó láti ọdún 2003 sí 2007, àti láti ọdún 2007 sí 2011. Adèọlá jẹ́ olùrànlọ́wọ́ àti akópa pàtàkì nínú ṣíṣe òfin tí ó fún àjọ tó ń rísí pípawó wọlé lábẹ́lé ní ìpínlẹ̀ Èkó lágbára, òfin tí ó mú owó tí ìpínlẹ̀ náà ń pa gbéra láti bílíọ̀nù márùn-ùn Náírà lóṣooṣù sí èyí tí ó ju bílíọ̀nù lọ́nà ogún Náírà lọ. Ó tún jẹ́ ara àwọn ẹgbẹ́ tí wọ́n ṣe òfin Ìṣúná Owó àti Òfin ríra oun èlo fún ìjọba ti Ìpínlẹ̀ Èkó .

Wọ́n yan Adeola sí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àpapọ̀ láti ṣojú fún ẹkùn Àlímọ̀ṣọ́ ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣojú ṣòfin Nàìjíríà ní ọdún 2011.

Nígbà tí Olórí ilé, Rt. Hon. Aminu Tambuwal, ṣe ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ ní ilé, ó gba ipò alága ìgbìmọ̀ tó ń rísí ìwé òfin, Ìgbìmọ̀ tó ń rísí àkọsílẹ̀ oun tó bá ṣẹlẹ̀ ní Ilé. Ó gba ipò náà gẹ́gẹ́ bí aṣòfin àkọ́kọ́ ti yô wá fún ìgbà àkọ́kọ́ tí wọn yó fi ṣe alága ìgbìmọ̀ náà ní Ilé. Ó ti di Aṣòfin àgbà báyìí, ó sì jẹ́ Igbákejì Alága Ìgbìmọ̀ tó ń rísí ọ̀rọ̀ Ìbánisọ̀rọ̀, ó sì tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ tó ń rísí ètò Ìṣúná, ọ̀rọ̀ Omi, ọ̀rọ̀ abẹ́lé àti Ìmọ̀ Sáyẹ́ǹsì àti Ìmọ̀ Ẹ̀rọ ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin àgbà. Wọ́n padà tún yàn án gẹ́gẹ́ bí Aṣòfin tó ń ṣojú fún ìwọ̀ oòrùn Èkó ní ìdìbò gbogbogbòò tó wáye ọdún 2019. [5]

Wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí alága, ìgbìmọ̀ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin lórí ètò ìnáwó ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin kẹwàá ní ọjọ́ kẹjọ oṣù kẹjọ ọdún 2023. [6]

Àwọn Ẹgbẹ́ tí ó wà

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adèọlá jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ fún àwọn tó nílò ìrànwọ̀, ètò ẹ̀yáwó àti Ìṣàkóso Gbésè, Ìmúrasílẹ̀ fún Pàjáwìrì àti Àjálù, Ìrìnàjò Ilẹ̀ àti Àwọn ohun èlò Epo rọ̀bì ti orí ilẹ̀.

Àwọn àmì ẹ̀yẹ àti ọlá

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  • Ní ọjọ́ kọkànlá oṣù kẹwàá ọdún 2022, Ààrẹ Muhammadu Buhari fún un ní ọlá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti Commander Of The Order Of The Niger (CON). [7]
  • Ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kẹta ọdún 2022, wọ́n fún Adeola ní oyè ọmọ ẹgbẹ́ ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìṣe ti ìjọba àpapọ̀ tó wà ní ìlú Ìlarǒ. [8]

Àwọn ètò ìrònilágbára

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àtìlẹyìn fún àwọn oníṣòwò

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní oṣù Kejì ọdún 2023, Adeola ṣe ìfilọ́lẹ̀ ètò ìrónilágbára Ọlọ́jà Yáyì fún àwọn oníṣòwò jákèjádò ẹkùn ìdìbò ìwọ̀ oòrùn ìpínlẹ̀ Ògùn. Gẹ́gẹ́ bí ìwé ìròyìn This Day ṣe ṣe àgbékalẹ̀ rẹ̀, àwọn ọkùnrin àti obìnrin tó lé ní ẹgbẹ̀rún márùn-ún àti ààbọ̀ ló gba ẹgbẹ̀rún lọ́nà márùn-ún dínlọ́gbàn náírà nípasẹ̀ ìfiránṣẹ́ sí àpò àṣùwọ̀n ní ilé ìfowópamọsí wọn, tí àpapọ̀ rẹ̀ jẹ́ mílíọ̀nù mẹ́tàdínlógóje ólé ìgbọnjẹ̀ márùn-ùn (₦137.5 million). [9] Ètò náà, tí a ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àjọ tó ń rísí ọ̀rọ̀ ìwádìí àwọn Alagbalúgbú Omi ní ilẹ̀ Nàìjíríà (Nigerian Institute for Oceanography and Marine Research NIOMR), ni èrò láti dín àwọn ìpèníjà ọrọ̀ ajé tí àwọn oníṣòwò kékeré ń dojú kọ kù.

Ìrónilágbára iṣẹ́ àgbẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọjọ́ kẹjọ oṣù kẹrin ọdún 2025, Adéọlá ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn àgbẹ̀ tó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé méjìlélọ́gọ́rin (3,082) ní Ìlarǒ, ìpínlẹ̀ Ògun. [10] Àwọn tó jàǹfààní rẹ̀ gba àwọn ohun èlò oko àti àwọn ohun èlò bíi katakata, àwọn ẹ̀rọ ìtulẹ̀, àwọn ẹ̀rọ tí a fi ń fa omi, àwọn ẹ̀rọ tí a fi ǹ fìn oko, àwọn irúgbìn tó dára, àwọn ajile, àti àwọn oògùn apakòkòrò, pẹ̀lú owó ìrànlọ́wọ́ owó tó jẹ́ ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rùn-ún Náírà. [11]

Ní oṣù kẹfà ọdún 2025, ìwé ìròyìn This Day ròyìn pé ètò ìrónilágbára iṣẹ́ àgbẹ̀ tí Adéọlá ṣe ní “ọ̀nà mẹ́ta” láti pèsè àwọn ohun èlò oko, pínpín àwọn ohun èlò iṣẹ́ àgbẹ̀, àti ṣíṣe ìrànwọ́ owó tààrà sí àwọn tó jẹ àǹfàní yǐ. [12] Ìgbésẹ̀ náà dé ọ̀dọ̀ àwọn àgbẹ̀ tó lé ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta níye, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún márùn-ún láti agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ ogún tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn gba owó tó jẹ́ ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rùn-ún Náírà, àti àwọn katakata, ẹ̀rọ ìtulẹ̀, kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́ta, fínko-fínko, ẹ̀rọ tí a fi ń fa omi, àwọn irúgbìn tó dára, àwọn ajile, àti àwọn oògùn apakòkòrò. [13]


Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Raji, Zainab (2019-10-10). "Senate revisits bill to upgrade Yabatech to university". The Guardian. https://guardian.ng/news/senate-revisits-bill-to-upgrade-yabatech-to-university/.
  2. "Lagos West: Adeola Aka Yayi Make History Winning Senate Seat". The Nigerian Voice. 2015-03-31. https://www.thenigerianvoice.com/news/174644/1/lagos-west-adeola-aka-yayi-make-history-winning-se.html.
  3. "Yayi wins Lagos West senate seat". The Nation. 2015-03-31. https://thenationonlineng.net/yayi-wins-lagos-west-senate-seat/.
  4. Raji, Zainab (2019-10-10). "Senate revisits bill to upgrade Yabatech to university". The Guardian. https://guardian.ng/news/senate-revisits-bill-to-upgrade-yabatech-to-university/.
  5. "Lagos West: Adeola Aka Yayi Make History Winning Senate Seat". The Nigerian Voice. 2015-03-31. https://www.thenigerianvoice.com/news/174644/1/lagos-west-adeola-aka-yayi-make-history-winning-se.html.
  6. Raji, Zainab (2019-10-10). "Senate revisits bill to upgrade Yabatech to university". The Guardian. https://guardian.ng/news/senate-revisits-bill-to-upgrade-yabatech-to-university/.
  7. Raji, Zainab (2019-10-10). "Senate revisits bill to upgrade Yabatech to university". The Guardian. https://guardian.ng/news/senate-revisits-bill-to-upgrade-yabatech-to-university/.
  8. "Lagos West: Adeola Aka Yayi Make History Winning Senate Seat". The Nigerian Voice. 2015-03-31. https://www.thenigerianvoice.com/news/174644/1/lagos-west-adeola-aka-yayi-make-history-winning-se.html.
  9. Raji, Zainab (2019-10-10). "Senate revisits bill to upgrade Yabatech to university". The Guardian. https://guardian.ng/news/senate-revisits-bill-to-upgrade-yabatech-to-university/.
  10. Raji, Zainab (2019-10-10). "Senate revisits bill to upgrade Yabatech to university". The Guardian. https://guardian.ng/news/senate-revisits-bill-to-upgrade-yabatech-to-university/.
  11. "Lagos West: Adeola Aka Yayi Make History Winning Senate Seat". The Nigerian Voice. 2015-03-31. https://www.thenigerianvoice.com/news/174644/1/lagos-west-adeola-aka-yayi-make-history-winning-se.html.
  12. Raji, Zainab (2019-10-10). "Senate revisits bill to upgrade Yabatech to university". The Guardian. https://guardian.ng/news/senate-revisits-bill-to-upgrade-yabatech-to-university/.
  13. "Lagos West: Adeola Aka Yayi Make History Winning Senate Seat". The Nigerian Voice. 2015-03-31. https://www.thenigerianvoice.com/news/174644/1/lagos-west-adeola-aka-yayi-make-history-winning-se.html.