Jump to content

Taiwo Alimi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Àdàkọ:Cleanup-rewrite

Taiwo Olubowale Allimi LL-Q34311 (yor)-Tunmise123-Taiwo Olubowale Allimi.wav Listen(born December 17, 1944, in Sagamu, Nigeria) is a Nigerian journalist and media executive.[1]

Early life and education=

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí ní ọjọ́ kẹtàdínlógún, oṣù Kejìlá ọdún 1944,ni Sagamu, Nàìjíríà.


Ó jẹ́ Olùdarí Gbogbogbo ti Voice of Nigeria láti ọdún 1999 sí ọdún 2004; tí ó sì jẹ́ alága àríyànjiyàn ìdìbò Ààrẹ Nàìjíríà ọdún 2003, 2007 àti 2007 lórí redio, tẹlifíṣọ̀n àti sátẹ́làítì ní Abuja . Ó tún jẹ́ alága tẹ́lẹ̀ rí ti Broadcasting Organizations of Nigeria (BON),ìyẹn tí umbrella association àjọ àgbéléwọ̀lé fún gbogbo ilé iṣẹ́ redio àti tẹlifíṣọ̀n ní Nàìjíríà, ti ìjọba àti ti aládani, láti 1999 sí 2004. Ó jẹ́ Kọmíṣọ́nà Ìpínlẹ̀ tó pé jù lọ ní Nàìjíríà fún Ìmọ̀ Alágbèéká (Information), Ìtọju Àwùjọ, Ọ̀dọ́, Eré-ìdárayá àti Àṣà ní Ogun State láti 1986 sí 1991. Ó jẹ́ Igbakeji Ààrẹ Commonwealth Broadcasting Association (CBA) ní London ní ọdún 2004. Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ olùdásílẹ̀ ìmúlò àgbáyé Global Media AIDS Initiative pẹ̀lú Kofi Annan gẹ́gẹ́ bí alága ní UN, New York, Oṣù Kini, odun 2004. Ó jẹ́ onkọ̀wé àti olùdásílẹ̀ ìlànà “ìpàdé ojú ọjà abúlé” (village-square-meeting concept) fún ìṣàkóso tó bẹ̀rẹ̀ láti ìpele ìsàlẹ̀ sí òkè àti ìkópa aráàlú fún ìdàgbàsókè alágbára ní Nàìjíríà, ní 1986. Ó jẹ́ olùdásílẹ̀ àti onkọ̀wé àkọ́kọ́ fún àwọ̀n nẹ́tíwọ́ọ̀kì tẹlifíṣọ̀n àpẹẹrẹ Nàìjíríà — Lagos Television / Lagos Weekend Television, láti 1980 sí 1985. Ó jẹ́ aṣojú ìpínlẹ̀ ní Àpéjọ Ìtúnṣe Òṣèlú Orílẹ̀-Èdè Nàìjíríà ní 2005, tó dojú kọ ìmúlò òfin tuntun fún orílẹ̀-èdè náà. Ó jẹ́ alákóso (coordinator) ti Ogun State Elders’ Consultative Forum, ẹgbẹ́ aláìṣèlú tó ń fúnni ní ìmọ̀, ìmọ̀ràn àti ìtọ́sọ́nà lórí ọ̀ràn ìṣàkóso ní Ogun State, gúúsù-ìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà, láti 2005 títí di òní. Àwọn ìpínlẹ̀ mìíràn ní Nàìjíríà àti orílẹ̀-èdè Áfíríkà kan (pẹ̀lú Dókítà Nelson Mandela ti gba àpẹẹrẹ Ogun State yìí. Ó jẹ́ agbátẹrù pàtàkì fún ìdásílẹ̀ eto redio ìbílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ipele kẹta nínú ètò ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ní Nàìjíríà láti ọdún 1992. Ó jẹ́ olùdásílẹ̀, agbalejo àti aṣelọpọ eto tẹlifíṣọ̀n “Vote ’83”, ìkànnì ìròyìn ìdìbò tó gbajúgbajà jù lọ ní Nàìjíríà, ní 1983. Ó tún jẹ́ olùdásílẹ̀, agbalejo àti aṣelọpọ “Elections ’79”, ìkànnì tẹlifíṣọ̀n àkọ́kọ́ nípa ìdìbò ní Nigerian Television Authority (NTA Channel 10, Lagos) ní 1979. Ó jẹ́ alága ìpàdé gbòógì (plenary session) ní àpéjọ United Nations Economic Commission for Africa ní Addis Ababa, Oṣù Kẹrin 2003, lórí kókó-ọrọ̀ “Fífi ìdàgbàsókè sí ọkàn ètò ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́”. Ó tún jẹ́ agbọrọ̀sọ lórí “Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ àti HIV/AIDS” ní World Electronic Media Forum ní Geneva, Switzerland láti ọjọ́ kẹjọ sí ọjọ́ Kejìlá, Oṣù Kejìlá,ọdún 2003. Ó jẹ́ oníròyìn tẹlifíṣọ̀n Nàìjíríà àkọ́kọ́ tó dá àtúpalẹ̀ olootu “Issues of Our Time” sílẹ̀ lórí tẹlifíṣọ̀n ní ọdún 1982. Ó tún jẹ́ olùdásílẹ̀, agbalejo àti aṣelọpọ “Lagos Report”, eto ìwádìí alẹ́-ọ̀sẹ̀ tó gba àmì ẹ̀yẹ ní Nàìjíríà, ní ọdún 1977. Ó jẹ́ onkọ̀wé ìwé Without Time: Memoirs of a Journalist in Public Service, tí wọn tẹ̀ jáde ní Oṣù Kẹrin 1999. Aremo Taiwo Allimi ni olùdásílẹ̀ àti alákóso àgbà (principal consultant) ti Talim Associates Nigeria Limited, ilé-iṣẹ́ ìmọ̀ràn nípa média, ìwádìí, ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ àti ìdàgbàsókè ìbánisọ̀rọ̀, tí wọn dá sílẹ̀ ní ọdún 1986.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Osso, Nyaknno (1990). Who's who in Nigeria. Newswatch. p. 146. ISBN 978-978-2704-12-2.