Jump to content

Timothy Onwuatuegwu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

 

Timothy Onwuatuegwu (? – ọjọ kẹẹdogun oṣù kínní ọdún 1970) jẹ oga ologun Nàìjíríà to si jẹ oga agba nínú àwọn ọmọ ológun Biafra . Ó jẹ́ olórí ogún nínú Ogun abẹ́lé Nàìjíríà àti olùkópa nínú ìdìjọba ilẹ̀ Nàìjíríà lọ́dún 1966 .

Onwuategwu gba ìyànda láti dara pọ̀ mọ́ àwọn ọmọ ogun orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lẹ́yìn tí ó parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Royal Military Academy, Sandhurst, United Kingdom ní ọdún 1961, [1] nibi ti o ti jẹ ẹlẹgbẹ pẹlu awọn olórí míìràn gẹgẹbi Murtala Muhammed, Muhammed Shuwa, ati Illiya Bisalla .

Ìgbà jọba Ọdun 1966

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Timothy Onwuatuegwu kópa nínú ìdìtẹ̀ ológun lọ́dún 1966 tí ó fi gba ìjọba Nàìjíríà , Abubakar Tafawa Balewa, nígbà tí ó sì tún pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀gá ológun ní Àríwá. Onwuatuegwu ni won fi jẹ olórí àwọn ọmọ ogun kékeré kan ti ise pataki wọn ni lati pa oṣiṣẹ tàbi olóṣèlú Nàìjíríà ti won ro pe o lewu ni Kaduna . Maj. Onwuatuegwu, fúnra rẹ ni o dari awọn ọmọ ogún kan si ilè Brig. Ile Samuel Ademulegun. Onwuatuegwu tẹsiwaju lọ sí yàrá Brigadier níbi tí ó ti o sùn sí lẹ́gbẹ̀ẹ́ ìyàwó rẹ̀. Nigbati o ri Onwuatuegwu tí o wọ inú yàrá náà, Ademulegun pariwo mọn "Timothy, kini Bìlísì tí o lérò pe o n ṣe?". Onwuatuegwu sọ fún Ademulegun pe wọn ti mún. Ademulegun nán ọwọ́ sí ẹgbẹ́ ibùsùn rẹ, bo se náà ọwọ́ náà, Onwuatuegwu yìnbọn páa lori ibùsùn rẹ, pẹlú ìyàwó rẹ ti o sun lẹgbẹ rẹ̀. Bi o tile jẹwipe Johnson Aguiyi Ironsi padà dá ifipagbàjọba náà dúró àti òun àti ọgá rẹ Major Chukwuma Kaduna Nzeogwu sìn darí apá àríwá orílè èdè Nàìjíríà fun ose melo kan . Awọn ọlọpaa Naijiria ti mu Onwuatuegwu ati Nzeogwu ni ibẹrẹ oṣu Kínní ṣugbọn wọn ko pa wọn eyi ti o sì bi ọpọlọpọ awọn ara ilu Àríwá nínú. Fun odidi odun kan ni Onwuatuegwu wa nínú tubu Enugu titi di ọjọ karùn-ún oṣù karùn-ún, ọdún 1967 nigba ti olori Biafra, Odumegwu Ojukwu gba a sile.

Nigba ti wọn kéde Biafra lominira ni ọgbọ̀njọ́ oṣù kàrún ọdún 1967 Ojukwu sọ Onwuatuegwu di ọgá nínú àwọn ọmọ ogun re. [2] Onwuatuegwu ko ri ìgbésẹ to po titi di oṣù kẹta ọdún 1969 nigba ti wọn fi si olórí ẹgbẹ́ Biafra S Division, lati tun gba Owerri lọwọ àwọn ọmọ ologun Naijiria. Ni ọjọ kẹẹdogun oṣù kẹta ọdún 1969 Onwuatuegwu dari ikọlu si Ẹgbẹ kẹrindínlógún Naijiria, ti wọn ti n gba ilu Owerri lati Oṣu Kẹwa ọdun 1968, ṣugbọn o fi agbara mu lati da duro lẹhin ti awọn ipalara pupọ. Onwuatuegwu gbe idaji awọn ọmọkunrin rẹ labẹ aṣẹ Maj. Joseph Achuzie, ti o ṣakoso lati gba laarin kilomita kàn ti ilu náà. Achuzie bèèrè fun ìṣàkóso lapapọ ti S Division ṣugbọn Onwuatuegwu kọ, ti awọn ọkùnrin méjèèjì si fẹ́rẹ̀ yinbọn fun ara wọn lẹyin ti wọn yọ ibọn wọn. Ààrẹ Ojukwu wọlé o si fun Achuzie ní ase ti S Division fun ọ̀se kan. Ikolu iwaju Achuzie ja si pabo, o si fi agbára mu lati padasehin, Ojukwu si da Onwuatuegwu pada sípò gẹgẹ bi olori S Division. Ni ọjọ kẹsan osu kini ọdún 1970 Onwuatuegwu sín Ààrẹ Biafra, Odumegwu Ojukwu, lo si Papa ofurufu Uli. [3]