Toyin Olakunri
| Olutoyin Olakunri | |
|---|---|
| Ọjọ́ìbí | Oṣù Kọkànlá 4, 1937 Lagos, Nigeria |
| Aláìsí | June 3, 2018 (ọmọ ọdún 80) |
| Orílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Orúkọ míràn | Olusola |
| Iṣẹ́ | Accountant, Stock broker and business woman |
| Gbajúmọ̀ fún | Africa’s first female Chartered Accountant |
Oloye (Iyaafin) Olutoyin Olakunri (OFR) (ọjọ kẹrin oṣu kọkanla, ọdun 1937 - ọjọ kẹta oṣu Kẹfa, ọdun 2018) jẹ onísírò owó, onínúure ati oníṣòwò obìnrin ti orilẹ-ede Naijiria ti o jẹ akọ́ṣirò obìnrin akọkọ ni ile Afirika. Ni ọdún 2000, Ààrẹ Obasanjo yán an gẹgẹ bi olórí ètò ẹ̀kọ́ Trust Fund. O jẹ ààrẹ Institute of Chartered Accountants of Nigeria láàrin ọdún 1994 ati 1995.
Olakunri kó ipa ìpìlẹ níbi ìdásílẹ̀ Society of Woman Accountants of Nigeria. [1]
Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbésí ayé àti ẹ̀kọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Olakunri ni wọn bi ni ilu Eko fún Ọgbẹni Akinola ati Iyaafin Esther Adesigbin, bàbá rẹ jẹ agbẹjọ́rọ̀ láti ìdílè Layeni-Adesigbin, ẹni tí o ni Tika Tore Press nígbà ti màmá rẹ jẹ ọmọ olọ́jà Eko, JH Doherty, nígbà ti o dàgbà, o jẹ ọmọ kàn soso fún ìgbà pípẹ́.
O lọ si ilé-ìwé alakọbẹrẹ ni Aba, o si tẹsiwaju ẹkọ alakọbẹrẹ ni CMS Girls School ni Èkó. Ni ọdún 1950, o lọ papọ̀ pẹlú ilé-ìwé náà nígbàtí wọn kò ilé-ìwé náà lọ si Ibadan wọn sí dáa pọ mọn Kudeti Girls School ti wọn si sọ́ lorukọ St Anne's School Ibadan, ni ọmọ ọdun mẹtala, o lọ si United Kingdom lati tẹ̀síwájú ẹkọ ile-iwe giga rẹ ni Hawthorns School ni Frinton-on-Sea, Essex. [1] Lakókò ti o wa ni England o fẹ ọkọ rẹ akọkọ, Arthur Ladipo Vigo, ni ọdún 1957. Lori ìmọràn ti baba rẹ ati ipa ti iya oníṣòwò kan, Olakunri yan iṣiro gẹgẹbi iṣẹ, nireti pe yóò fun u ni ànfàní lati ṣiṣẹ gẹgẹbi iya ati tun ṣíṣe bákannáà. [2] [3]
Olakunri parí ile-iwe giga Yunifasiti ti Birmingham, o si ṣe ọkọ-ọrọ pẹlu Ilu Lọndọnu ati Dorset & Co ṣáájú ki o to yege bi oniṣiro ni ọdún 1963. O fẹ ọkọ rẹ keji, Simeon Moronfolu Olakunri ni àyíká ọdún 1965. O bi ọmọ meje.
Iṣẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Lẹhinna o pada si Nàìjíríà o si darapọ mọ ọfiisi Peat Marwick Cassleton Elliot and Co. [1] Ni ọdun 1965, Olakunri darapọ mọ oṣiṣẹ ti Nigerian Industrial Development Bank (NIDB) tin jẹ Bank of Industry ni báyìí ni ọdún kan lẹhin ti wọn daalẹ̀. O ṣiṣẹ ni NIDB fun ọdun méje o si fi silẹ gẹgẹbi olùdarí ti ICON Stockbrokers ti alapemọn ti NIDB. Lẹhin ijade rẹ lati banki, Olakunri ṣakoso ile-iṣẹ iṣowo ọja kan, CTB Stockbrokers ti o fẹ kọkọ ra. Bí ó tilẹ̀ jẹwipe, ní ọdún 1972, ó padà ra ilé-iṣẹ́ ike kan ní Apapa èyí ti ọmọ ilẹ̀ Ítálì kan dá sílẹ̀. O tun yà lọ sínú agbewọle ti awọn ile ti a ti kọ kalẹ tẹlẹ ṣugbọn ìṣòwò náà ko rii aṣeyọri dáadáa. [4]
Ni ọdún 1977, Olakunri ni a yan gẹgẹbi ọmọ ẹgbẹ ti 1977 Constituent Assembly, àpéjọ àwọn ọmọ Nàìjíríà lati ṣe ìpinnu lori ofin ijọba tiwantiwa tuntun. Lẹ́yìn ọdún kàn, òun àti àwọn ọmọ ẹgbẹ́ obìnrin ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ti ICAN, fọwọ́sowọ́pọ̀ dá Society of Women Accountants of Nigeria sílẹ̀, àjọ kan láti dáàbò bo ire àwọn akọ̀ròyìn obìnrin ní Nàìjíríà. [2]
Olakunri je oludari ìdásílẹ̀ ile ìfowópamọ́ International Eko ati Banki Gateway, leyi to jẹwipe ijoba ipinle Eko ló nìí tẹlẹ tosí padà bọ́ sí ọwọ́ ijoba ipinle Ogun .
Awọn itọkasi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 3 . Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; name "guard" defined multiple times with different content - 1 2 https://guardian.ng/saturday-magazine/life-and-times-of-first-lady-of-accounting-olutoyin-olakunri/ Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; name "gbonegun" defined multiple times with different content - ↑ Anibaba, Musliu O. (1990). A short history of the accountancy profession in Nigeria. Lagos, Nigeria: West African Book Publishers. ISBN 9781531045. OCLC 25526285. https://en.wikipedia.org/wiki/Toyin_Olakunri#cite_ref-3
- ↑ Forrest, Tom G. (1994). The advance of African capital : the growth of Nigerian private enterprise. Charlottesville: University Press of Virginia. pp. 117. ISBN 0813915627. OCLC 30355123. https://en.wikipedia.org/wiki/Toyin_Olakunri#cite_ref-4