Yemi Elebuibon
Ifáyẹmí Ọ̀ṣúndàgbonù Elébuìbọn (a bíi ni ọdún 1947)ó jẹ́ òǹkọ̀wé Yorùbá ọmọ Nàìjíríà, akéwì, òǹkọ̀wé, onímọ̀ èdè, àti àlùfáà Ifá to gbajúgbajà lágbàáyé. [1] Awọn eré àti fíìmù rè ti gba iyìn káàkiri àgbáyé fún ilepa ati itoju asa ati ogún yoruba . Ó tún ṣiṣẹ́ gẹgẹbi olùkóni orí ìrìn ní òpòlopò awọn ile-iṣẹ pẹlu ni ẹka ti ede Afirika ati litireso ni Ile-ẹkọ giga Obafemi Awolowo ati Black Studies ni Ile-ẹkọ giga ti Ipinle San Francisco ati ni Ile-ẹkọ Aṣa Wajumbe ni California.
Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbésí ayé
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wón bí Elébuìbọn ni 1947 nilu Ọ̀ṣogbo [2] fún Akínrìndé Àkàndé Ẹlẹ́búìbọn (c. 1885 – 1957) ti Ó jẹ́ Àlùfáà Ifá àti ọdẹ, àti Ṣíjuwọya Abeje Ẹlẹ́búìbọn (née Awóníyì). Elebuibon wá láti ìran àwọn ọdẹ, àwọn onífá, awọn oníṣègùn egbògi, ati awọn jagunjagun. Bàbá rẹ̀ ni wọ́n sọ pé àtọmọdọ́mọ gbajúgbajà jagunjagun Olutimehin, ọ̀kan lára àwọn tó dá ìlú Ọ̀ṣogbo sílẹ̀ ni. Wọn bí ìyá re sinu ìdílé awon aláwo ti wón ń sìn Ọya ati Ifá. Oyè “Araba” ni a fún olórí Olúwo Ifá ní Òṣogbó, oyè yìí sì jẹ́ ti Bàbá ìyá rẹ̀, Kẹ̀hìndé Adéyẹmi Awóníyì, ẹni tópe jùlọ lórí òye Araba ní Osogbo. Oyawenu Awoniyi ni iya agba re. Awọn orúkọ ti Elebuibon ati awọn obi rẹ jẹ ṣe apejuwe kedere ni apejuwe awọn ipilẹṣẹ ati awọn aṣa ti ìdílé won. Oruko iya Elebuibon, Sijuwoya tumo si "La oju re lati ri/sin Oya," ṣe fihàn pé awon obi rè ń sin Ọya . "Elebuibon" wa lati orukọ apeso ti baba rẹ ti o tumọ si "Ẹni tí òní ọpọlọpọ ibon," tí o fihan pé ó jẹ́ ọdẹ. Oruko wundia ti iya Elebuibon ni Awoniyi tó túmọ̀ sí “Ifa ni iyì,” Awọ na tọka si Ifa.
Bàbá Elebuibon jé aláya púpò ti o si ni iyawo mẹ́fà, iya Elebuibon si ni ìyàwó tí o kéré jùlọ. Bàbá rẹ̀ ní ọmọ púpọ̀, ṣùgbọ́n ní àkókò yẹn ọ̀pọ̀ nínú wọn ló kú ní kékeré. Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ni a mọ̀ ní nú àṣà Yorùbá sí abíkú . Baba Elebuibon àti bàbá ìyá Elebuibon (Awoniyi) jé òré tímọ́tímọ́ nínú Ifa ti won si fi han pe lati yanjú ìṣòro yii, bàbá Elebuibon ni láti fé ọmọ obìnrin lati ìdílé olóyè Àràbà . Ọmọbìnrin yii ni ìyá Elebuibon. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó fe Sijuwoya, tún ní ìṣòro Àbíkú, o bi ọmọ méjì ti o ku ni ìkókó. Lati wa ojútùú si iṣoro yii, ó kàn sí Ifá, wọn si pinnu pe yoo lo ọmi fi rúbọ fún òrìṣà Ọsun (ni odo Ọsun). Láìpẹ́ laijìna, ó bí Elebuibon, ọmọ kan ṣoṣo tí kò kú . Awọn àyídáyidà ìbímọ rẹ ni a le rii ninu awọn orúkọ ti a fún Elebuibon. Orúkọ rè Kínní, Ifáyemí túmọ̀ sí Ifá ni ó yẹ mí àti orúkọ rẹ̀ míràn Osundagbonu tókasí Òrìsà Osun, tí wọ́n gbàgbó pé òní ó fún wọn ní Elebuibon.
Iṣẹ-ṣiṣe
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Elebuibon bẹrẹ ìkẹ́kọ̀ọ́ gẹ́gẹ́bi bi àlùfáà Ifa lati ọdọ bàbá rẹ ní ọdún 1951 nígbàtí ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rin . Ó tẹ̀síwájú ìkẹ́kọ̀ọ́ lile yii ni iṣẹ ọna ìbílẹ̀ títí bàbá rẹ̀ fi kú nígbàtí ó jẹ́ ọmọ ọdún mewa ni ọdun 1957. Wọ́n sì fi í sábẹ́ ìdarí Olóyè Faniyi Ajani (Agbongbon-Awo ti Osogbo), àlùfáà Ifá mìíràn tí ó yaranti nipa ẹ́kọ̀ọ́ ifa dáradára tí ó sì ṣeé ṣe kí ó jẹ́ alákòóso bàbá àti baba ńlá Elebuibon. Lẹ́yìn ìdánilẹ́kọ̀ọ́ fún ọdún mẹ́wàá mìíràn, ó di Babaláwo aláṣẹ ní ọdún 1967. Ko lọ si ile-iwe kankan ṣùgbọ́n ó dà ara re lẹkọ fúnrararè. Lẹhinna ó di òṣèré fún àwọn ere olókìkí ti Duro Ladipo pẹlu Ọba kò bẹ . Lẹhinna ó ní nkan ṣe pẹ̀lú National Black Theatre, nínú èyítí o ṣe lọwọlọwọ bi olùdámòràn àsà. Ó bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé àti ìwé jáde ní èdè Yorùbá àti Gẹ̀ẹ́sì. Ó tún kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ eré ìbílẹ̀ Yorùbá tí ó dá lórí àwòkẹ́kọ̀ọ́ Yorùbá (tí a mọ̀ sí ewi ní Yorùbá). Eré re nípa ìjẹ ọmọlúwàbí àtàtà “IFA OLOKUN ASORODAYO” (àṣàyàn òrọ̀ láti inú esè Ifa àti Orunmila tiwọn yọ nínú Odu-Ifa je àgbéjáde gẹ́gẹ́bi ere ori ìtàgé óni pẹ̀lẹ́ Lori ìmún maworan tí apapọ̀ Nàìjíríà. [3] Nínú ìlàkàkà rẹ láti dabo bo aṣa ati ise ilé Yorùbá ti òní igbagbo pé ó tin di òun ìgbàgbé látàrí itowobo àwọn ènìyàn láti ìwọ ọrùn, ó ṣe idasilẹ àwọn ilé-iṣẹ́ àṣà àti ìṣe púpò ni Nàìjíríà, nínú wọn ni atirí "Ancient Philosophy International in Ọ̀ṣogbo and African" ti wọn se agbekale rẹ fún dídá ni leko nípa ìṣe, àṣà àti èsìn àwọn ènìyàn Áfíríkà. Wọn yàn ni Igbakeji Alaga ti Board of Traditional Medicine, Osun State, Lówólówó awọn ni Aare ti International Congress of Orisa Tradition and Culture, Nigeria Chapter látàrí ìgbìyànjú rẹ Osun-Osogbo Grove di àgbègbè amuye lagbaye tí "UNESCO World Heritage site" ni Ọdún 2005, UNESCO kede nínú ìkéde kẹta rẹ̀ lórí Àwọn Ẹ̀dá Àgbègbè àlùmọní àgbáyé Ifa Divination System èyí tin bẹ ní ìlú Nàìjíríà jẹ́ okan lára àwọn agbègbè lati lọ ṣe awọn irin-ajo ikẹkọ ni afikun ṣiṣe ẹsin ibile rẹ.[citation needed]
- ↑ Afro-Latin American Studies: An Introduction. https://books.google.com/books?id=QEFPDwAAQBAJ&pg=PA641.
- ↑ "Dad doesn't believe in corporal punishment — Yemi Elebuibon's daughter". https://punchng.com/dad-doesnt-believe-corporal-punishment-yemi-elebuibons-daughter/.
- ↑ Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; no text was provided for refs namedauto1