Augustine Ukattah

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Augustine ukattah)

Augustine Ukattah (tí wọ́n bí ní August 28,1918, tó sì ṣaláìsí ní January 27,1996) je oluko ile Naijiria ati oloselu.

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Augustine Echewodor Ukattah ní Ahaba-Oloko ní agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ Ikwuano ní Ìpínlẹ̀ Ábíá, ní August 28, 1918.[1] Ukattah jẹ́ ọmọkùnrin kẹrin tí Ukattah Nkor Abajuo àti Ejighiato Nwamgbede Ukattah, bí. Àwọn òbí rẹ̀ méjèèjì jẹ́ Ahaba-Oloko. Bàbá rè kú nígbà tó ṣì kéré, tí ó sì ń gbé lọ́dọ̀ àbúrò bàbá rè, ìyẹn Chief Mathew Ugoani. Ilé-ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Christ the King ní Aba ló lọ, àti ilé-ìwé St. Theresa ní Okigwe. Lẹ́yìn iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gé bí olùkọ́ àwọn akẹ́kọ̀ó, ó lọ sí St. Charles Teacher Training CollegeOnitsha,[2] ní ọdún 1941. Ó yege gẹ́gẹ́ bí i Higher Elementary Teacher ní ọdún 1944, ó sì ṣàṣeyege nínú ìdànwó ti àwọn olùkọ́ àgbà nínú ẹ̀kọ́ ìtà, ní ọdún1948.

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Who's who in Nigeria. Nigerian Printing and Publishing Company. 1958. p. 264. https://books.google.com/books?id=egUaAAAAIAAJ&q=Augustine+Ukattah. Retrieved 6 April 2015. "UKATTAH, Augustine Echewodor, M.H.R. teacher; b. 28 August 1921; ..." 
  2. Legislators of Eastern Nigeria. Eastern Nigeria Information Service. 1958. p. 51. https://books.google.com/books?id=zfY2AAAAIAAJ&q=A+E+Ukattah. Retrieved 6 April 2015. "A. E. UKATTAH, BENDE: Age 36; educated at St. Charles' College, Onitsha. ..."