Margaret Adebisi Sowunmi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Margaret Adebisi Sowunmi
BornOṣù Kẹ̀sán 24, 1939 (1939-09-24) (ọmọ ọdún 84)
Kano, Nigeria
NationalityNigerian She attended St Anne's School Ibadan for her secondary school education
InstitutionsUppsala University
University College Ibadan
UCL Institute of Archaeology
Alma materUniversity College Ibadan

Margaret Adebisi Sowunmi tí wọ́n ń pè ní Jádesimi) tí ọjọ́ ìbí rẹ̀ jẹ́ ọjọ́ Kẹ́rìnlélógún oṣù kẹsán, ọdún 1993 jẹ́ oníṣe botany ní orílé èdè Nàìjíríà àti Onímọ̀ Nípa Archaeology. O jẹ́ Ọ̀jọ̀gbọ́n, àti Pùròfẹ́sọ̀ nínú iṣẹ Palynology àti Onímọ̀ àti oníṣe ìwàádìí lórí àwọn ohun tí o jẹ́ mọ Environmental Archaeology ní Fásitì tí ó wà ní ìbàdàn, Fásitì Ìlú Ìbàdàn. A lè pé Margaret Sowunmi ní ẹni àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ kọ́ ẹ̀kọ́ Environmental Archaeology àti Paleoethnobotany ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1][2] ó sì jẹ́ olùdásílẹ̀ àti olùdarí ẹgbẹ́ Palynological tí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1]

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ Ayé Rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Sowunmi sí ìpínlẹ̀ Kano, àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọjọ́ Kẹ́rìnlélógún oṣù kẹsán, ọdún 1993. Bàbá rẹ̀ jẹ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run alààyè ní ìjọ Nàìjíríà náà. Ó lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ gíga tí ilé-ẹ̀kọ́ St Anne ti ìlú Ibadan fún ẹ̀kọ́ ilé mẹ́wàá rẹ̀. Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè Pàtàkì BSc nínú Botany ní ẹ̀ka-ẹ̀kọ́ ìmọ̀ ti Botany, ní Fáṣítì kọ́lẹ́jì ti Ibadan, ó sì kẹ́kọ̀ọ́ jáde ní ọdún 1962. Ó gba ẹ̀bùn ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ ti ẹ̀kọ́ PhD ní ọdún 1963 láti ṣiṣẹ́ ìwádìí nínú ẹ̀kọ́ Palynology. Láti ṣiṣẹ́ ìwádìí Palynology yìí, Sowunmi rìnrìn àjò lọ sí Sweden láti lọ kẹ́kọ̀ọ́ pẹ̀lú Gunnar Erdtman, ẹni tí ó ṣe alábòójútó rẹ̀ fún ẹ̀kọ́ PhD rẹ̀. Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè PhD rẹ̀ nínú botany láti Fáṣítì ti Ibadan ní ọdún 1967.[3]

  1. 1.0 1.1 Orijemie, Emuobosa Akpo (2014), "Sowunmi, Margaret Adebisi", in Smith, Claire, Encyclopedia of Global Archaeology (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì), Springer New York, pp. 6941–6943, ISBN 9781441904652, doi:10.1007/978-1-4419-0465-2_2354 
  2. Babah, Chinedu (2017-03-23). "SOWUNMI, Prof. M. Adebisi (nee Jadesimi)". Biographical Legacy and Research Foundation (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-07-02. 
  3. Orijemie, Emuobosa Akpo (2014), "Sowunmi, Margaret Adebisi", in Smith, Claire, Encyclopedia of Global Archaeology (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì), Springer New York, pp. 6941–6943, ISBN 9781441904652, doi:10.1007/978-1-4419-0465-2_2354