Jump to content

Abiola Dosunmu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Abiola dosunmu)
Abiola Dosunmu
Erelu Kuti of Lagos

Spouse Major Adekunle Elegbede (widowed)
Chief Antonio Deinde Fernandez (divorced)
Issue
  • Kunle Elegbede
  • Adewunmi Elegbede
  • Antoinette Oyinkansola Fernandez
House
  • Dosunmu (by birth)
  • Olumegbon (by marriage)
Father Omoba Adewunmi Dosunmu
Mother Olori Adejoke Dosunmu
Born 29 Oṣù Agẹmọ 1947
Kano, Nigeria

Olóyè Abiola Dosunmu (tí ó fìgbà kan jẹ́ Dosunmu-Elegbede-Fernandez, tí wọ́n bí ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù Kejẹ ọdún 1947), jẹ́ oníṣòwò, gbajúmọ̀ àti Olóyè ìbílẹ̀ ní ilẹ̀ Nàìjíríà. Ní àfikún sí àwọn oyè oríṣiríṣị tó jẹ, òun ni Erelu Kuti IV ti Èkó.

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Abiola Dosunmu sí ìlú Kano, ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù Kejẹ ọdún 1947, sínú ìdílé ọlọ́ba ti Omoba Adewunmi àti Olori Adejoke Dosunmu ti Lagos Island. Ó jẹ́ ọmọ ìran Oba Dosunmu ti Èkó, èyí tó sì mu tan mọ́ ìdílé ọba ti ilẹ̀ Yorùbá àti Bini.[1][2] Ìyá-ìyá rẹ̀ jẹ́ Iyalode ní Owu Egba.[3]

Ayé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Erelu Kuti IV tí Èkó

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọ̀kan lára àwọn mọ̀lẹ́bí rẹ̀, ìyẹn Oba Adeyinka Oyekan tí Èkó ló fi Abiola Dosunmu jẹ Erelu Kuti IV tí Èkó, ní ọdún 1980.[4] Èyí sì sọ ọ́ di Ìyáàfin tó jẹ Adelé ní Èkó lẹ́yìn ti Baálè kan wàjà, ó wà ní ipò yìí títí àwọn afọbajẹ fi yan ẹlòmíì sípò náà. Láti ìgbà náà ló sì ti di Erelu Kuti, tí ó sì tún di ipò tí àwọn ọmọbìnrin ní ìdihlé ọba máa ń jẹ.[5]

Àwọn ojúṣe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Olóyè

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọ ojúṣe Erelu Kuti ti Èkó ni:

  • jíjẹ́ olùdámọ̀ràn àwọn olórí ìbílè ti Èkó.
  • jíjẹ́ agbaninímọ̀ràn lórí àwọn ọ̀rọ̀ tó jẹ mọ́ ayẹyẹ bíi ayẹyẹ ìfọbajẹ àti ìwúyè.
  • jíjẹ́ adarí ìbílè fún àwọn ẹgbẹ́ obìnrin lóríṣiríṣi.
  • jíjẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ-ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ afọbajẹ.

Àwọn tó ba dupò

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Arábìnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Dosunmu fi lélẹ̀ pé òun ni Erelu Kuti, tí ó sì ba dupò yìí, àmọ́ ó kú ní ọdún 2019.[6]

Iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí oníṣòwò

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Dosunmu kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmọ̀ business administration ní ìlú London.[7] Ìtàn fi yé wa pé òun ló sọ òwò Aso Oke di ohun tó dà lónìí,[8] tí ó sì ṣe ìgbélárugẹ aṣà ilẹ̀ Yorùbá pẹ̀lú Aso Oke. Ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olùṣẹ̀ṣọ́ ilé ti Nigerian High Commission ní ìlú London.[8] Bákan náà ni ó ṣí ṣọ́ọ̀bù kan sí Bond Street ní ìlú London.[8]

The Erelu, tó jẹ́ aṣọ imúra ajẹmọ́-oge jẹ́ síkẹ́ẹ̀tì àti agbada kékeré tí àwọn obìnrin máa ń wọ̀ ní ọdún 1980 wọ ọdún 1990, náà jẹ́ aṣọ tí Abiola Dosunmu bẹ̀rẹ̀.[9] Olórin ilè Nàìjíríà ìyẹn King Sunny Adé kọ orin kan láti fi gbóríyìn fún Dosunmu èyí tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ "Biibire Kose Fowora".[10]

Àwọn àmì-ẹ̀yẹ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  • National honour of the Royal Kingdom of Belgium.[11]
  • Life achievement award by Vanguard newspaper[11]
  • Honorary Doctorate Degree, D.Cul-Doctor of Culture at the 4th convocation ceremony of Igbinedion University, Okada.[12]
  • Pan African Exemplary Leadership 2016 Honour /Icon of True Silent Mega Philanthropist in Africa - In recognition and appreciation of her immense contribution to Nation building, massive job creation, consistent assistance to the less privileged, excellent mentorship towards youths, youth employment, public service delivery with integrity in her discharge of duty, Promotion and Preservation of African culture and values including her selfless service to God, Humanity, Nigeria and Africa.
  • The Commonwealth Journalists Association Award.
  • Nigerian Institute of International Affairs Award.
  • West African Students Union Parliament Award for Exemplary Leadership.

Ìgbésí ayé ara-ẹni

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Dosunmu fẹ́ Major Adekunle Elegbede, tí wọ́n sì jọ bí ọmọ méjì, ìyẹn Kunle Elegbede àti Adewunmi Elegbede. Ìgbéyàwó náà parí lẹ́yìn tí Major Elegbede kú ní ọdún 1970.[13] Dosunmu pàdé Olóyè Antonio Deinde Fernandez, tó jẹ́ ọmọ-ẹgbẹ́ Amaro láti ìdílé Olumegbon ti Èkó, ní ọdún 1972. Ní ìgbà náà, Fernandez fẹ́ arábìnrin ilẹ̀ America kan.[14] Dosunmu àti Fernandez ṣe ìgbéyàwó wọn ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ní ààfin Ọba Èkó ní oṣù Kẹrin ọdún 1973. Ọ̀pọ̀ gbajúmọ̀ àti àwọn ọlọ́lá ènìyàn bih Adekunle Lawal ló wá síbi ìgbéyàwó náà.[15] Wọ́n ní ọmọbìnrin kan, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Antoinette Fernandez, tó jẹ́ aṣefíìmù àgbéléwò ní ìlú London.[16][17] Ní ọdún 2007, Fernandez sọ fún Dosunmu ní gbangba pé kó má lọ orúkọ òun mọ́.[18]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Published (2017-12-10). "Lagos is an extension of Benin – Erelu Dosunmu – Punch Newspapers". Punchng.com. Retrieved 2020-04-04.
  2. "Erelu Dosunmu : A voice for the recognition of indigenous Lagosians". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2019-01-18. Retrieved 2020-02-01.
  3. "At over 70, I'm as young, enterprising as I used to be - Erelu Dosunmu". Punchng.com. 13 September 2020. Retrieved November 1, 2020.
  4. "Dosunmu 70th Birthday Lecture Holds Friday". July 25, 2017. https://m.guardian.ng/news/dosunmu-70th-birthday-lecture-holds-friday/. Retrieved April 28, 2020.
  5. "Erelu Abiola Dosunmu: The Woman King". mediaroomhub.com. Retrieved December 16, 2023.
  6. "Erelu Abiola Dosunmu To Be Buried In Lagos On Valentine's Day". urbanlifeng.com (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-02-01.
  7. Metrofile: Personality Profile Features Erelu Of Lagos HRH Abiola Dosumu (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì), retrieved 2020-02-01
  8. 1 2 3 "Erelu Dosunmu : A voice for the recognition of indigenous Lagosians". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2019-01-18. Retrieved 2020-02-01.
  9. "ERELU DOSUNMU: A voice for the recognition of indigenous Lagosians – Livelyinfo". Archived from the original on 2019-02-02. Retrieved 2020-04-02. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  10. "[THROWBACK]: King Sunny Ade- 'Bibiire Kose Fowora'". oshakmusicblog.com (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2018-02-27. Archived from the original on 2018-10-06. Retrieved 2018-12-13.
  11. 1 2 "Erelu Dosunmu : A voice for the recognition of indigenous Lagosians". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2019-01-18. Retrieved 2020-02-01.
  12. "Contact Support". Thenigerianexpression.com. Retrieved 2020-04-04.
  13. Elites, The (2015-09-23). "EXCLUSIVE: How Erelu Abiola Dosunmu Lost The Three Men She Cherished Most Within Six Months - The Elites Nigeria". Theelitesng.com. Retrieved 2020-04-04.
  14. Barbara Fernandez V. Antonio Deinde Fernandez. "FERNANDEZ v. FERNANDEZ | 208 Conn. 329 (1988) | conn3291514". Leagle.com. Retrieved 2022-08-12.
  15. "Fernandez: At last 'the veil is lifted' - Vanguard News". Vanguardngr.com. 2015-09-16. Retrieved 2020-04-04.
  16. "Tackling the Green Party's diversity issues starts with electing a Black female representative". Bright Green (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2023-01-27.
  17. "Antoinette Fernandez". IMDb. Retrieved 2018-12-13.
  18. "Erelu Dosumu refuses to talk about late husband, Fernandez | Encomium Magazine". Encomium.ng. Retrieved 2020-04-04.