Jump to content

Ayọ̀ Bámgbóṣé

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Ayọ̀ Bangbóṣé)
Ayo Bamgbose
Ọjọ́ìbíAyọ̀rìndé Bámgbóṣé
(1932-01-27)27 Oṣù Kínní 1932 (age 86)
Odopotu, Ijebu Ode, Nigeria
Orílẹ̀-èdèNigerian
Iléẹ̀kọ́ gígaUniversity College London, University of Edinburgh
Iṣẹ́Linguist, Professor, Scholar
Ọmọ ìlúOdopotu

Ayọ̀ríndé Bámgbóṣé (ẹni tí a bí ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n, oṣù kìn-ín-ní, ọdún 1932) jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n onímọ̀ ẹ̀dá-èdè, tí ó sì tún jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tí ó gba oyè ọ̀jọ̀gbọ́n àkọ́kọ́ nínú ẹ̀kọ́ nípa ìmọ̀ ẹ̀dá-èdè ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó ti ṣiṣẹ́ ribiribi nínú ẹ̀kọ́ ìmọ̀ ẹ̀dá-èdè, tí ó sì ti di ìlú mọ̀ọ́ká àti gbajú-gbajà láàárín àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ lágbo ìmọ̀ ẹ̀dá-èdè.[1]

ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ àti ètò ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí ọ̀jọ̀gbọ́n Bámgbóṣé Odopotu, lẹ́bàá Ijebu Odeìpínlẹ̀ Ògùn ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọdún 1932. Bàbá rẹ̀, Rev. Sàngódípẹ̀ Bámgbóṣé, jẹ́ olórí agbègbè Odopotu, ẹni tí wọ́n bí sí ìdílé egúngún èyí tí ó gbajúmọ̀. Orúkọ bàbá rẹ̀ tí ó jẹ́ Bámgbóṣé, èyí tí ó túmọ̀ sí bá mi gbé oṣé Ṣàngó, àti orúkọ àkọ́kọ́ bàbá rẹ̀, Sàngó dí ìpẹ̀, náà ń tọ́ka pé ìdílé wọn jẹ́ ìdílé tó jẹ́ ẹlẹ́sìn Sàngó, ọba àrá.

Lẹ́yìn tí ó parí ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ rẹ̀, wọn gba Bámgbóṣé sí ilé-ẹ̀kọ́ St. Andrew's College. Ó peregedé gẹ́gẹ́ bíi olùkọ́ onípò kejì ní ọdún 1951. Lẹ́yìn náà ni ó wọlé sí ilé-ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì ìlú Ìbàdàn, èyí tí ó jẹ́ apá kan lára Yunifásítì ìlú Lọ́ńdọ́ọ̀nù. Ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa èdè Gẹ̀ẹ́sì, ó sì kẹ́kọ̀ọ́ jáde ní ọdún 1960.

Ó tẹ̀síwájú láti lọ kẹ́kọ̀ọ́ ní Yunifásítì ti Edinburgh, níbi tí ó ti gba dípúlómà nínú ìmọ̀ ẹ̀dá-èdè gbogboogbò ní ọdún 1961. Ní ọdún 1963 ni ó gba oyè ọ̀jọ̀gbọ́n, àkọlé iṣẹ́ ìwádìí rẹ̀ ni: “Ìwádìí nípa àwọn ètò àti àwọn ẹ̀ka nínú gírámà èdè Yorùbá òde-òní.”[2]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]