Grace Ebun Delano
| Grace Ebun Delano | |
|---|---|
| Ọjọ́ìbí | 13 November 1935 Kaduna |
| Orílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Iṣẹ́ | Nurse |
| Gbajúmọ̀ fún | Work in Reproductive Health in Nigeria |
Grace Ebun Delano (abi ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kọkànlá ọdún 1935, ní ìlú Kàdúná) jẹ́ oníṣègùn àti agbẹ̀bí ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tó ti kó ipa pàtàkì nínú ìfètòsọ́mọbíbì àti àwọn iṣẹ́ ìlera nípa ìbímọ ní Nàìjííà. O jẹ olùjùmọ̀dásílẹ̀ ti Association for Reproductive and Family Health ibi tí ó ti jẹ́ olùdarí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́bí olùdarí sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àjọ oríṣìríṣǐ káàkiri ilẹ̀ Áfíríkà, àti pé ó ti kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé fún ra ẹ̀ àti àwọn ìwé àjùmọ̀kọ lórí ìlera obìnrin àti àwọn àkọ́lé tí ó jọmọ. Ní ọdún 1993, ó gba àmì ẹ̀yẹ ti Sasakawa láti ọwọ́ àjọ tí ó ń rí sí ètò ìlera ní àgbáyé.
Ìgbà Èwe àti ilé ẹ̀kọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ìyá rẹ̀, tí ó ní ẹ̀kọ́ kékeré fúnrarẹ̀, ṣe àtìlẹyìn fún ìfẹ̀ tí ọmọbìnrin rẹ̀ ní fún ẹ̀kọ́ ìdí èyí ni ó fi gbǎ láàyè láti lọ kàwé ní ìlú èkó nígbà tí ó pé ọdún mẹ́tàlá.[1] Àmọ́ọ̀, kí Grace tó wá sí ìlú Èko, ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ ìpilẹ̀ṣẹ̀ àkọ́kọ́ ní ilé ẹ̀kọ́ kan tí wọ́n ń pè ní United Native African School, ní Kaduna, ní àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti ọdún 1940 sí 1944. Ní ọdún 1945, ó lọ sí ilé-ìwé tí ó jẹ́ wípé àwọn ọmọkùnrin nìkan ni ó wà níbẹ̀ tí a ńpè ní Ilé-ìwé Ìjọba ní Kàdúná èyítí olùdarí tí ò gba gbẹ̀rẹ́ tí a ń pè ní Ọ̀gbẹ́ni Sàlàkọ́ tí ó fi tipátipá gba àwọn ọmọbìrin méjì àkọ́kọ́ ní ilé-iwè náà. Delano gba àmì ẹ̀yẹ láti lọ kẹ́kọ̀ọ́ ọ̀fẹ́ èyí tí ó fun ní ààfàní láti lọ sí àwọn ilé ẹ̀kọ́ tó gbé pẹ́ẹ́lí, ní èyí tí ó mu parí ní ilé ẹ̀kọ́ girama ti ìlú Abéòkúta. Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ ìyá rẹ̀ àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin, Delano lọ sí Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì lọ́dún 1956 láti lọ gba ìdánilẹ́kọ̀ọ́ nípa iṣẹ́ nọ́ọ̀sì fún ọdún mẹ́ta. Lẹ́yìn náà, ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìgbẹ̀bí àti nọ́ọ̀sì agbègbè. Lẹ́yìn náà ni ó ṣalábǎpàdé àwọn obìrin ti wọn ìrànlọ́wọ́ nípa ìfètòsọ́mọbíbí tí ó sì lo àǹfàní yìí láti máa ṣe ìdánilẹ́kọ̀ọ́ àti bí a ti ń lo ìsénà láti dènà oyún níní. [1] Delano padà sí Nàìjíríà lọ́dún 1961 ó sì gba iṣẹ́ lọ́dún tó tẹ̀ lé e ní Ilé Ìwòsàn ti Yunifásítì ilẹ̀ Ìbàdàn eléyìí tí ó wà ní orítamẹ́fà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ ní ẹka tí ó ń rí sí ọ̀rọ̀ àwọn aláboyún. Nígbà yẹn, ó ti fẹ́ Adájọ́-lọ́la Tunde Delano gẹ́gẹ́ bí ọkọ rẹ̀.[1]
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí nọ́ọ̀sì ilé ìgbẹ̀bí ló mú kó darapọ̀ mọ́ iṣẹ́ kan tí ọ̀jọ̀gbọ́n kan ní Yunifásítì Ìbàdàn bẹ̀rẹ̀, ó sì di nọ́ọ̀sì tó ń bójú tó àwọn ìlànà ètò nípa ìfètòsọ́mọbíbí ń ní ilé ìwòsàn olùkọ́ni àkọ́kọ́ ní Nàìjíríà. Nígbà tí ó yá, <span title="This claim needs references to reliable sources. (May 2020)">awọn</span> [ ] ètò nǎ táǹ káàkiri láti ìlú sí àwọn agbègbè ìgbèríko, [1] tí ó sì jẹ́ wípé láti ilé-ìwòsàn a gbé ètò yǐ lọ sí àwọn ìgbèríko àti agbègbè, pẹ̀lu pínpín àwọn ohun èlò nípasẹ̀ àwọn ọjà ìbílẹ̀. [1] [2] Iṣẹ́ yìí wá fẹjú débi wípe ó nílò láti rin ìrìn àjò lọ sí òkè òkun: ní ìrìn àjò àkọ́kọ́ sí ìlú AMẸ́RÍKÀ fún ìkẹ́kọ̀ọ́, lẹ́yìn èyí Delano lọ gẹ́gẹ́bí olùdámọ̀ràn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ Adúláwọ̀ mìíràn. Púpọ̀ nínú iṣẹ́ rẹ̀ jẹ́ agbátẹrù tàbi apákan-òwò nípasẹ̀ àwọn ilé-iṣẹ́ àgbáyé bíi USAID, Pathfinder International àti Ford Foundation . [1] Lẹ́hìn tí ó kọ ìwé tí ó ṣe àlàyé kíkún lórí ètò ìfètòsọ́mọbíbí ni Ajo Agbaye fun Olugbe (UNFPA) san owó fún títẹ̀ àti pínpín ìwé nâ ní orísìí èdè márùn-ún. [1] Ó tẹ̀síwájú láti kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìwé mìíràn àti pé ó ti jẹ́ olùjùmọ̀kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn nǹkan tí ó jọmọ́ ìdànilẹ́kộ lórì ètò ìlera. UNFPA tún ṣe àtìlẹyìn ìwé atọ́nisọ́nà rẹ̀ lórí ètò ìfètòsọ́mọbíbí ti IUCD .
Ní ọdún 1980 ó sopọ̀ pẹ̀lú Ilé-iṣẹ́ tí ó ń rísí ìdàdàsókè àti ọ̀rọ̀ ará ìlú (CEDPA) tí ó máa ń ṣètò ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdàgbàsókè àti ipò adarí fún àwọn obìnrin, pàápàá ṣíṣe àtìlẹyìn fún ọ̀rọ̀ ìlera àti ẹ̀kọ́. [3] O ti di apákan ti èto ilẹ̀ Amẹ́ríkà. Delano bẹ̀rẹ̀ síí ní ìgboyà láti sọ̀rọ̀ ní gbangba, ó sì ń lọ sí àwọn àpèjọ lóríṣǐríṣǐ, pàdé pẹ̀lú àwọn adarí obìnrin mìíràn, àti àwọn ètò ìlànà láti ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn obìnrin, pàápàá àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ní ṣe pẹlu ìlóyún. [1]
Nígbà tí Delano ṣì ń ṣiṣẹ́ ní Yunifásítì Ibadan (ó kúrò ní ọdún 1992) ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn àjọ tó ń gbé ìgbòkègbodò láti dá àjọ olómìnira kan sílẹ̀ tí ó padà di àjọ olómìnira tí ó ń rísí ọ̀rọ̀ ìbímọ́ àti ìlera ìdílé (ARFH). Ó gbòòrò, ó fi ìtaniji lórí ọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀ fún àwọn mọ̀jèsín kun àti àwọn abala mìíràn si àwọn ìfiyèsí rẹ̀ ó tùn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìjọba lórí àwọn àkànṣe iṣẹ́ lórí àìsàn kògbóògùn HIV / AIDS. A lo àwọn ohun èlò ẹ̀kọ́ àti ìmọ̀ran ARFH ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè ní ilẹ̀ Áfíríkà. [1] Ẹni tí ó jẹ́ amúgbálẹ́gbẹ̌ rẹ̀ pàtàkì tí wọ́n jọ ń ṣeṣẹ́ yìí ni Ọ̀jọ̀gbọ́n O.A. Ladipo, ẹni tó jẹ́ ààrẹ àti alákòóso ARFH. Delano jẹ́ igbákejì Alákoǒso àti Olùdarí fún diẹ ọdún márùndínlọ́gbọ̀n ó lé. [4] Ní Oṣù kọkànlá ọdún 2015, lákòkǒ ígbà tí ó ń ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbí ọgọ́rin ọdún, a ṣe ayẹyẹ ìfẹ̀hìntì àti ìdánilẹ́kọ̌ láti bu ọlá fun. [5] Grace ni òǹkọ̀wé àwọn ìwé tó tí ó wà káàkiri àgbáyé. Ó ṣe àtẹ̀jáde àwọn iṣẹ́ ìwadìí mẹ́sàn-án pẹ̀lú àwọn ìwé ìtọ́kasí tì ó tó àádóje àti àwọn olùkà tí ó tó ẹgbẹ̀rún-kan ó jé ní àádóje dín mẹ́rin lóri ayélujára.
A sábà máa ń ṣàpèjúwe rẹ̀ pẹ̀lú àwọn gbólóhùn bíi " aṣáájú lórí ọ̀rọ̀ ìfètòsọ́mọbíbí ní Nàìjíríà", àti " oníṣègùn àgbà tí ó lààmì laaka nípa ìlera ìbínọ́mọ àti ètò ìfètòsọ́mọbíbí pẹ̀lú ìrírí tó lé ní àádọ́ta ọdún".
Àwọn ipò àti Àmì Ẹ̀yẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 3 4 5 6 7 8 9 Grace Ebun Delano - Population and Reproductive Health Oral History Project, Sophia Smith Collection, Smith College. Smith College. October 7, 2013. Archived from the original on January 17, 2017. https://web.archive.org/web/20170117021148/https://www.smith.edu/library/libs/ssc/prh/transcripts/delano-trans.pdf. Retrieved May 14, 2016.
- ↑ Family planning in traditional markets in Nigeria.
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- ↑ Empty citation (help)
- Oludari Alase ati Igbakeji Aare ti Nigeria Association for Reproductive and Family Health (ARFH)
- Aami Eye Sasakawa Ajo Agbaye fun Ilera 1993
- Ẹ̀bùn ìtayọ fún àwọn àfikún pàtàkì sí àṣeyọrí ti Initiative Health Reproductive Health Initiative (NURHI). (Ti a ṣe inawo nipasẹ Bill ati Melinda Gates Foundation lati mu lilo awọn ọna eto ìfètòsọ́mọbíbí igbalode (FP) laarin àwọn mẹ̀kùnùn ti ilu mẹfa.) [1]
- Oludamoran lori ilera ibisi si ọpọlọpọ àwọn àjọ ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ati ni awọn orilẹ-ede Afirika miiran.
- Alakoso Orilẹ-ede fun Ile-iwe Johns Hopkins ti Ilera Awujọ - Awọn eto Ibaraẹnisọrọ
- Ẹlẹgbẹ ti Ile-ẹkọ Nọọsi ti Iwọ-oorun Afirika
- Ẹlẹgbẹ ti Institute for Humanitarian Studies ati Social Development [2]
- Akowe Agba fun Ẹgbẹ Ọjọgbọn ti Awọn Agbẹbi ti Nigeria
- Oludamoran si International Planned Parenthood Federation[citation needed]
- Àmì ẹ̀yẹ láti ọwọ́ àwọn Dọ̀kítà tí ó rísí ọ̀rọ̀ oyùn àti ìbímọ
Àwọn ìwé àtẹ̀jáde
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Ìṣírí Ìdáàbò Boji Lórí Àwọn Ilé Ìwòsàn Ìpínlẹ̀ Ìdílé ní Ibadan Nigeria
- Atọ́ka fún Ìpèsè Ìdílé
- Àwọn Ìdáhùn sí Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè Nípa Ìbálòpọ̀ Rere[3]
- Igbese idiwọ oyun ni ile-iṣẹ ilera akọkọ ti NGO ṣakoso ni Ibadan, Nigeria
- Ṣiṣiro ipele ti igbaradi ti awọn olutọju ilera aladani fun iṣakoso iwosan ti Ikolu HIV / AIDS ni Ipinle Nassarawa, Nigeria. Ìwé ìròyìn African Journal of Reproductive Health (AJRH) [4]
- Ipa ti awọn ipolongo idena HIV / AIDS lori awọn ayipada ihuwasi ti o ni ibatan si HIV ni Ibadan, Nigeria [4]
- "àwọn aṣojú pínpín tó dá lórí àwùjọ" ń ṣe àfikún ìsọfúnni àti iṣẹ́ ìsálú ìdílé ní ìpínlẹ̀ márùn-ún ní Nàìjíríà: Ìwà ìyanu àbí ohun tó ń ṣẹlẹ̀?[4]