Asiru Olatunde

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Asiru Olatunde

Asiru Olatunde (1918–1993) jẹ́ ayàwòrán, alágbẹ̀dẹ ni orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, tí ó jé ọkan lára àwọn gbajúgbajà ayàwòrán ní ìlú Òṣogbo.[1] Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ayàwòrán kékeré kan tí wọ́n darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ àwọn oníṣẹ́-ọnà kan, ìyẹn Oshogbo School of art.[2] Àwọn àwòrán rẹ̀ dá lórí àwọn ìtàn ìgbaani ti ilẹ̀ Yorùbá àti àwọn ìtàn inú Bíbélì.

Ìgbésíayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Asiru Olatunde sínú ìdílé àwọn alágbẹ̀de àmọ́ àìsàn[3] fi ipá gba iṣé yìí ní ọwọ́ rẹ̀ ní ọdún 1960. Ó ṣe àwọn ohun ọ̀ṣọ́ fún títà fún ìgbà díẹ̀ kí ó tó yí iṣẹ́rẹ̀ sí ìyàwòrán, gẹ́gẹ́ bí i àmọ̀ràn tí Uilli Beier àti Suzanne Wenger fun ní ọdún 1961. Ó máa ń fi bàbà, alumíníọ́ọ̀mù àti irin ṣe iṣé rẹ̀,[4] ó sì máa ń fi irin rọ àwọn ẹranko lóríṣiríṣi. Wọ́n ṣàfihàn iṣé rẹ̀ ní IMF headquarters, àti ní Smithsonian Institution bákan náà.[5]

Ikú rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ó kú ní ọdún 1993.

Àṣàyàn iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  • Tree of Life[6]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Ikpakronyi unveils Post COVID-19 vision for NGA, artists". Guardian. 
  2. "Asiru Olatunde". Archived from the original on 2007-06-10.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. "Asiru Olatunde | Indigo Arts". indigoarts.com. Retrieved 2020-10-01. 
  4. "ASIRU OLATUNDE". Retrieved 2020-09-09. 
  5. "Asiru Olatunde". Art Network. Retrieved 2020-09-09. 
  6. "Nairobi Gallery exhibition celebrates 50 years Nigerian art". 2018-04-23. Retrieved 2020-09-09.