Tomi Adeyemi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Tomi Adeyemi
Adeyemi in 2022
Ọjọ́ ìbíOṣù Kẹjọ 1, 1993 (1993-08-01) (ọmọ ọdún 30)
Iṣẹ́Writer, Creative Director
Alma materHarvard University
Genre
Notable works
Notable awards
Website
tomiadeyemi.com

Tomi Adeyemi (tí wọ́n bí ní August 1, 1993) jẹ́ ònkọ̀wé àti olùkọ́ àkọsílẹ̀ àtinúdá ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó tan mọ́ ilẹ̀ America. Ó gbajúmọ̀ fún ìwé ìtàn-àròsọ rẹ̀ Children of Blood and Bone, èyí tó jẹ́ àkọ́kọ́ nínú ìtàn Legacy of Orïsha trilogy, tí Henry Holt Books for Young Readers ṣá̀tẹ̀jáde rẹ̀.[1] Ìwé yìí gba àmì-ẹ̀yẹ ti Andre Norton ní ọdún 2018 fún Young Adult Science Fiction and Fantasy,[2] bákan náà ni ó gba àmì-ẹ̀yẹ ti Waterstones Book Prize ọdún 2019, àti àmì-ẹ̀yẹ ti Hugo Lodestar Award for Best Young Adult Book, ní ọdún 2019.[3] Ní ọdún 2019, ìwé-ìròyìn Forbes kọ orúkọ rẹ̀ sínú àkójọ 30 Under 30. Ní ọdún 2020, ìwé-ìròyìn TIME náà to orúkọ rẹ̀ pọ̀ mọ́ 100 Most Influential People of 2020.[4]

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Tomi Adeyemi ní August 1, 1993[5][6] ní United States sí àwọn òbí tó kó kúrò ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Bàmí rẹ̀ jẹ́ dọ́kítà ní Nàìjíríà, ó sì ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí i awakọ̀ kí ó tó ríṣẹ́ lókè òkun. Ìyá rẹ̀ sì jẹ́ afọlẹ̀. Ìlú Chicago ni Tomi dàgbà sí, wọn ò sí mu mọ àṣà Yorùbá; àwọn òbí rè sì pinnu láti má kọ́ òun àti àwọn àbúrò rẹ̀ ní èdè abínibí wọn. Àmọ́ ìgbà tó ṣẹ̀ dàgbà ló kọ́ èdè Yorùbá. Ó sì ṣàpèjúwe ọ̀kan lára àwọn ìwé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i lẹ́tà sí èdè rẹ̀[6]

Àwọn iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Legacy of Orïsha trilogy[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  • Children of Blood and Bone (March 6, 2018)
  • Children of Virtue and Vengeance (December 3, 2019)
  • Children of Anguish and Anarchy (June 25, 2024)

Companion books

  • Awaken the Magic (journal) (April 7, 2020)

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]