Jump to content

Àṣà Nok

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Coordinates: 9°30′N 8°0′E / 9.500°N 8.000°E / 9.500; 8.000

Ìtàn ilẹ̀ Nàìjíríà

Àyọkà yìí jẹ́ ìkan nínú àwọn àyọkà ẹlẹ́sẹẹsẹ
Prehistory
Ayéijọ́un àti Àkókò Ojú Dúdú
(Síwájú 1500)
Kùtùkùtù ìgbà òdeòní
(1500–1800)
Nàìjíríà Alámùúsìn
(1800–1960)
Ìgba Òṣèlú Àkọ́kọ́
(1960–1979)
Ogun Abẹ́lé
(1967–1970)
Ìgba Òṣèlú Èkejì
(1979–1983)
Ìgba Òṣèlú Ẹ̀kẹta
(1993–1999)
Ìgba Òṣèlú Ẹ̀kẹrin
(1999–present)
Timeline
Topics
History of Nigeria (1979–1999)
History of the Igbo people
History of the Yoruba people
{Àdàkọ:Data99

Èbúté Nàìjíríà
Àṣà Nok (Nok culture)
Àwòrán ilẹ̀ tó ń ṣe àfihàn ìbú Àṣà Nok
AgbègbèÌwọ̀-oòrùn Áfíríkà
SànmánìNeolithic, Ìgbà Irin (Iron Age)
ÀkókòNǹkan bí 1500 BC — 1 BC
Ojúkò àkọ́kọ́Nok
Àwọn ojúkò pàtàkì
Ohun tó tẹ̀lé eKwararafa

Àṣà Nok jẹ́ ẹ̀yà ènìyàn tí a sọ àwọn ohun èlò ìtàn wọn lórúkọ ìlú àwọn ọmọ Ham tí ń jẹ́ Nok ní apá gúúsù Ìpínlẹ̀ KàdúnáNàìjíríà, níbi tí wọ́n ti kọ́kọ́ rí àwọn ère amọ̀ wọn ní ọdún 1928.[1][2] Ó ṣeé ṣe kí àwọn ènìyàn Nok àti àwọn ènìyàn Gajiganna ṣí wá láti Àárín Sàhárà, pẹ̀lú jéró àti ìkòkò, kí wọ́n tó yapa kí wọ́n tó dé apá àríwá Nàìjíríà òde-òní. Èyí ló ṣeé ṣe kí ó fa títẹ̀dó wọn sí àwọn agbègbè Gajiganna àti Nok.[3] Ó tún ṣeé ṣe kí àwọn ènìyàn Nok ṣí wá láti Sàhẹ̀lì Ìwọ̀-oòrùn Áfíríkà wá sí agbègbè Nok.[4] Ó ṣeé ṣe kí Àṣà Nok bẹ̀rẹ̀ ní ọdún 1500 ṣáájú Sànmánì Tiwa (BCE) kí ó sì wà títí di ọdún 1 BCE.[3]

Àwọn ènìyàn Nok ṣe é ṣe kí wọ́n ṣẹ̀dá àwọn ère amọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀rọ̀ ajé,[5] gẹ́gẹ́ bí apá kan àṣà ìsìnkú tó díjú[6] èyí tí ó lè ní àwọn ìṣe bíi ṣíṣe àsè nínú.[3] Àwọn ère amọ̀ Nok tó pẹ́ jùlọ ṣe é ṣe kí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ní ọdún 900 BCE.[3]

Yàtọ̀ sí iṣẹ́ ọnà Íjíbítì àtijọ́, àwọn ère Nok ni a kà sí àwọn àpẹẹrẹ àkọ́kọ́ ti iṣẹ́ ọnà gbígbẹ́ oní-ìwọ̀n-mẹ́ta (three-dimensional figurative art) ní kọ́ńtínẹ́ǹtì Áfíríkà.[7] Àwọn àṣà iṣẹ́ ọnà Ìwọ̀-oòrùn Áfíríkà tó tẹ̀lé e – Bura ní Niger (ọ̀rúndún 3rd CE – 10th CE), Koma ní Ghana (ọ̀rúndún 7th CE – 15th CE), Igbo-Ukwu ní Nàìjíríà (ọ̀rúndún 9th CE – 10th CE), Jenne-Jeno ní Mali (ọ̀rúndún 11th CE – 12th CE), àti Ilé Ifẹ̀ ní Nàìjíríà (ọ̀rúndún 11th CE – 15th CE) – ó ṣeé ṣe kí wọ́n gba ipa látara àṣà amọ̀ (clay terracotta) ti Àṣà Nok.[8] Iṣẹ́ irin ṣe é ṣe kí ó bẹ̀rẹ̀ fúnra rẹ̀ nínú àṣà Nok láàárín ọdún 750 BCE àti 550 BCE.[3][9][10][11]

Breunig àti Rupp (2016) sọ pé: "A kò mọ orísun wọn, ṣùgbọ́n níwọ̀n bí àwọn irúgbìn tí wọ́n lò (pàápàá jùlọ jéró) ti jẹ́ ohun ọ̀gbìn ìbílẹ̀ sí agbègbè Sàhẹ̀lì, ó ṣeé ṣe kí wọ́n wá láti ilẹ̀ àríwá ju ibikíbi mìíràn lọ."[12] Breunig (2017) ṣàlàyé síwájú sí i pé: "Àwọn ènìyàn àṣà Nok gbọ́dọ̀ ti wá láti ibòmíràn. Ṣùgbọ́n títí di báyìí, a kò tíì mọ agbègbè náà, bó tilẹ̀ jẹ́ pé a fura sí agbègbè Sàhẹ̀lì ní Ìwọ̀-oòrùn Áfíríkà."[4] Champion àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ (2022) dámọ̀ràn pé wọ́n lè ti wá láti Àárín Sàhárà.

Àwọn Ère Nok
Ère Nok, amọ̀, Louvre
Ère obìnrin; gíga rẹ̀ jẹ́ 48 cm; ọjọ́ orí rẹ̀: ọdún 900 sí 1,500
"Aláròjinlẹ̀" nǹkan bí ọdún 298 AD

A kò tíì mọ iṣẹ́ gangan tí àwọn ère amọ̀ Nok ń ṣe. Fún apá tó pọ̀ jùlọ, àwọn ère amọ̀ yìí wà káàkiri ní ẹ̀rúnrún. Ìdí nìyí tí iṣẹ́ ọnà Nok fi gbajúmọ̀ lónìí nìkan fún àwọn orí wọn, tọkùnrin tobìnrin, tí irun orí wọn kún fún àlàyé tó lẹ́wà gidigidi. Àwọn ère yìí wà ní ẹ̀rúnrún nítorí pé wọ́n sábà máa ń rí wọn nínú ẹrọ̀fọ̀ (alluvial mud), ní ibi tí omi ti gbé ilẹ̀ lọ. Wọ́n sábà máa ń fò mọ́lẹ̀, wọ́n ń dán, wọ́n sì ń fọ́. Ó ṣọ̀wọ́n kí a rí àwọn iṣẹ́ ńláńlá tí wọ́n wà ní odindi, èyí tó sọ wọ́n di ohun iyebíye jùlọ lórí ọjà iṣẹ́ ọnà káríayé.[13]

Àwọn ère amọ̀ yìí ṣófo nínú, wọ́n ṣe wọ́n ní ìṣọ̀wọ́ (coil built), wọ́n fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ìwọ̀n ènìyàn gangan fún orí àti ara èyí tí wọ́n fi àwọn ìrísí àrà-ọ̀tọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọ̀ṣọ́, àti onírúurú ìdúró hàn.

Diẹ̀ ni a mọ̀ nípa iṣẹ́ ìpilẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn ohun èlò yìí, ṣùgbọ́n àwọn àbá kan fi hàn pé wọ́n lè jẹ́ àwòrán àwọn baba ńlá, àmì ibojì (grave markers), tàbí oògùn láti dènà àìṣẹ-irúgbìn, àgàn, àti àìsàn. Pẹ̀lúpẹ̀lù, ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ìpìlẹ̀ ròbòtò tó wà lára ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ère yìí, wọ́n lè ti lò wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀ṣọ́ orí òrùlé fún àwọn ilé àtijọ́.

Látàrí ìkùnlẹ̀ àdánidá àti àwọn ohun tó kó jọ, àwọn ère amọ̀ Nok túká káàkiri sí onírúurú ìjìnlẹ̀ nínú koríko Sàhẹ̀lì, èyí tó mú u nira láti mọ ọjọ́ orí àti ìsọ̀rí àwọn ohun èlò àràmàǹdà wọ̀nyí. Ní oríire, wọ́n rí ibi ìwalẹ̀-pìtàn méjì, Samun Dukiya àti Taruga, tí ó ní iṣẹ́ ọnà Nok tí kò ṣí kúrò ní ipò rẹ̀. Àwọn àdánwò fi hàn pé àwọn ère yìí wà láàárín ọdún 2,900 sí 2,000 sẹ́yìn, èyí tó sọ wọ́n di ọ̀kan lára àwọn tó pẹ́ jùlọ ní Ìwọ̀-oòrùn Áfíríkà.

Níwọ̀n bí wọ́n ti jọra nínú àṣà àti iṣẹ́ ọnà pẹ̀lú àṣà Nok tí a rí ní Nok, Sokoto, àti Katsina, ó ṣeé ṣe kí àwọn ọmọ Yorùbá, Jukun, tàbí Dakakari[14] àti àwọn ọmọ Bassa jẹ́ àtìran àwọn ènìyàn Nok. Ní ìbámu pẹ̀lú ìjọra nínú ọ̀nà tí wọ́n fi ṣe àwọn ère amọ̀ Nok, àwọn ère idẹ ti Ilé Ifẹ̀ ti àwọn Yorùbá àti ti ìjọba Benin ti àwọn Ẹdó tún lè jẹ́ ìmúgbòòrò àwọn àṣà tí ó wá láti ọ̀dọ̀ àṣà Nok ìgbàanì.

  1. "Nok". Archived from the original on 28 April 2014. Retrieved 25 February 2022. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  2. Obikili, Nonso (2018). "State Formation in Precolonial Nigeria". The Oxford Handbook of Nigerian Politics. Oxford University Press. p. 35. doi:10.1093/oxfordhb/9780198804307.013.1. ISBN 9780198804307. OCLC 1076346474. https://api.pageplace.de/preview/DT0400.9780192526311_A35506288/preview-9780192526311_A35506288.pdf#page=58.
  3. 1 2 3 4 5 Champion, Louis (15 December 2022). "A question of rite—pearl millet consumption at Nok culture sites, Nigeria (second/first millennium BC)". Vegetation History and Archaeobotany 32 (3): 263–283. doi:10.1007/s00334-022-00902-0.
  4. 1 2 Breunig, Peter (January 2017). Exploring the Nok Culture. Goethe University. p. 24. http://araf.studiumdigitale.uni-frankfurt.de/attachments/110_Nok%20Brosch%C3%BCre%20Exploring%20the%20Nok%20Culture%20online.pdf.
  5. Sun, Z. J. (2017). "Instrumental neutron activation analysis (INAA) of Nok sculptures in I. P. Stanback Museum". Journal of Radioanalytical and Nuclear Chemistry 313: 85–92. doi:10.1007/s10967-017-5297-8. ISSN 0236-5731. OCLC 7062772522. https://link.springer.com/article/10.1007/s10967-017-5297-8.
  6. Breunig, Peter (2022). "Prehistoric Developments In Nigeria". The Oxford Handbook of Nigerian History. Oxford University Press. pp. 123–124. doi:10.1093/oxfordhb/9780190050092.013.5. ISBN 978-0-19-005009-2. OCLC 1267402325. https://books.google.com/books?id=gQ5YEAAAQBAJ&dq=%22nok+culture%22&pg=PA136.
  7. Dunne, J. B. (2022). "Making the invisible visible: tracing the origins of plants in West African cuisine through archaeobotanical and organic residue analysis". Archaeological and Anthropological Sciences 14 (1). Bibcode 2022ArAnS..14...30D. doi:10.1007/s12520-021-01476-0. ISSN 1866-9557. OCLC 9384103618. https://research-information.bris.ac.uk/ws/portalfiles/portal/313538950/NOK_plant_paper_final_version_re_reviewer_comments.pdf.
  8. Ramsamy, Edward; Elliott, Carolyn M.; Seybolt, Peter J. (January 5, 2012). "Part I: Prehistory To 1400". Cultural Sociology of the Middle East, Asia, and Africa: An Encyclopedia. SAGE Publications. p. 8. doi:10.4135/9781452218458. ISBN 978-1-4129-8176-7. OCLC 809773339. https://books.google.com/books?id=GtCL2OYsH6wC&q=Koma%20Ghana.
  9. Miller, Duncan E.; Van Der Merwe, N.J. (1994). "Early Metal Working in Sub Saharan Africa". Journal of African History 35: 1–36. doi:10.1017/s0021853700025949.
  10. Stuiver, Minze; van der Merwe, N. J. (1968). "Radiocarbon Chronology of the Iron Age in Sub-Saharan Africa". Current Anthropology 9 (1): 54–58. doi:10.1086/200878. JSTOR 2740446.
  11. Ehret, Christopher (2023). "African Firsts in the History of Technology". Ancient Africa: A Global History, to 300 CE. Princeton University Press. p. 19. doi:10.2307/j.ctv34kc6ng.5. ISBN 9780691244105. JSTOR j.ctv34kc6ng.5. OCLC 1330712064. https://books.google.com/books?id=Q5KjEAAAQBAJ.
  12. Breunig, Peter; Rupp, Nicole (2016). "An Outline of Recent Studies on the Nigerian Nok Culture". Journal of African Archaeology 14 (3): 242, 247. doi:10.3213/2191-5784-10298. ISSN 1612-1651. JSTOR 44295241. OCLC 8512542846. https://brill.com/view/journals/jaa/14/3/article-p237_1.pdf.
  13. "The Ancient Nok Culture Kaduna State". Nigeria Information & Guide. Retrieved 2022-02-04.
  14. Lamp, Frederick John (2011). "Ancient Terracotta Figures from Northern Nigeria". Yale University Art Gallery Bulletin: 55. ISSN 0084-3539. JSTOR 41421509. OCLC 9972665249. https://docslib.org/doc/5614066/ancient-terracotta-figures-from-northern-nigeria.