Jump to content

Àyinla Omowura

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Alhaji
Ayinla Omowura
Fáìlì:Ayinla Omowura.jpg
Background information
Orúkọ àbísọWaidi Ayinla Yusuf Gbogbolowo
Wọ́n tún mọ̀ọ́ bíiAyinla Omowura
Hadji (Alhaji) Costly
Egunmogaji of Egbaland
Anigilaje
Ọjọ́ìbí1933
Itoko, Abeokuta
Aláìsí6 May 1980(1980-05-06) (ọmọ ọdún 46–47)
Bar ní Ago-Ika, Abeokuta
Irú orinApala
Occupation(s)Olórin
Years active1970–1980
LabelsEMI Records

Waidi Ayinla Yusuf Gbogbolowo tí gbogbo ayé mọ̀ sí Àyìnlá Ọmọwúrà (1933 – 6 May 1980) jẹ́ gbajúmọ̀ akọrin Apala ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Wọ́n bí i ní ìlú Ìtókò, ní Abẹ́òkuta ní ọdún 1933.[1]

Ọmọ bíbí Yusuff Gbogbolowo, tí í ṣe Alágbẹ̀dẹ, àti Wuramotu Morenike ni Àyìnlá.[2] Kò kàwé rẹpẹtẹ, iṣẹ́ alágbẹ̀dẹ lọ́dọ̀ bàbá rẹ̀ ni ó kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe. Lẹ́yìn náà, ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí awakọ̀, apanipẹran, gbẹ́nàgbẹ́nà, àti "bọọsi-pàákì". Bí ó ti rí bẹ́ẹ̀, Adewole Alao Oniluola ni ó ṣàwárí ẹ̀bùn rẹ̀, ẹni tí ó padà di olùlù rẹ̀; ibẹ̀ ni Àyìnlá ti bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ orin Apala títí tí ó fi dá tirẹ̀ sílẹ̀.[1]

Àyìnlá gbajúmọ̀ fún ìjàkádì láàárín òun àti àwọn akọrin yòókù, títí kan àwọn ọ̀gá rẹ̀ bíi Haruna Ishola, ẹni tí ó padà gba fún gẹ́gẹ́ bíi ọ̀gá rẹ̀ nípò. Ó tún ní awuyewuye pẹ̀lú Ayinde Barrister, Fatai Olowonyo, Yesufu Olatunji, àti Dauda Epo Akara.[3][4] 

Àwọn ìjà yìí farahàn kedere nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orin rẹ̀. Èèyàn inú-fùfù ni Àyìnlá, ó sì tún lókìkí fún lílo èrowò (marijuana) àti rògbòdìyàn.[1]

Láìjẹ́ pé ó kàwé, Àyìnlá jẹ́ akọrin tí ó mọ nǹkan tí ó ń lọ láwùjọ, ó sì jẹ́ ọ̀jáfáfá nínú lílo òwe, àpèjúwe, àti àmúlùmálà èdè. Ó máa ń lòrìn rẹ̀ láti ṣe àríwísí ìjọba àti láti kọ́ ará ìlú lẹ́kọ̀ọ́. Nínú àwo orin rẹ̀, Owo Udoji, ní ọdún 1976, ó kí ìjọba fún ìfikún owó oṣù, ṣùgbọ́n ó rọ ìjọba láti rántí àwọn òṣìṣẹ́ aládàáni pẹ̀lú. Nínú Orin Owo Ile Eko, ó ṣàlàyé òfin owó ilé ní Èkó fún àwọn olùgbọ́ rẹ̀, ó sì tún yin ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó lábẹ́ amúsìn Mobolaji Johnson fún àwọn ètò tó ṣàǹfààní fún ará ìlú. Ó ṣàlàyé ètò ìkànìyàn ọdún 1973 nínú àwo rẹ̀ National Census. Nínú àwo rẹ̀ Challenge Cup '73, ó ṣàlàyé ìyípadà bí a ṣe ń wa ọkọ̀ láti apá òsì sí apá ọ̀tún, àti ìyípadà owó Nàìjíríà láti Pound Sterling sí Naira àti Kobo nígbà ìjọba ologun tí General Yakubu Gowon dárí rẹ̀. Yàtọ̀ sí ìṣèlú, ó tún kọrin láti ṣàríwísí àwọn obìnrin tí ń pa awọ ara wọn rẹ́ (bleaching) àti àwọn tí kò ní ìwà rere.[4][2][5]

Ó ní orúkọ ìnagijẹ púpọ̀, ọ̀kan lára wọn ni "Hadji Costly" nítorí bí ó ṣe máa ń wọ aṣọ olówó-iyebíye bíi lace láti ìlú Switzerland àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ wúrà. Àwọn ìnagijẹ rẹ̀ míràn ni Egunmogaji, Anigilaje àti Alujannu Elere.[1][4]

Mùsùlùmí ni Àyìnlá láti ìgbà tí wọ́n ti bí i, ó sì lọ sí ilẹ̀ mímọ́ Mẹ́kà (Hajj) ní ọdún 1975. Síbẹ̀síbẹ̀, ó tún máa ń ṣe àwọn ètò ìṣẹ̀ṣe àbáláyé.[4]

Àwọn Àwo Orin Rẹ̀ (Discography)

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ó ṣe àwo orin LP méjìlélógún (22) lábẹ́ ilé-iṣẹ́ EMI Records. Méjì nínú wọn ni ó jáde lẹ́yìn ikú rẹ̀.[4]

1972 – National Population Census

1972 – Challenge Cup ’72

1973 – Orin Owo Ile Eko (Lagos Rent Edict)

1973 – Challenge Cup '73

1974 – Challenge Cup ’74

1976 – Owo Udoji

Owo Tuntun

Bayewu, ẹni tí ó jẹ́ alákòóso (manager) rẹ̀ ni ó pa Àyìnlá Ọmọwúrà nínú ìjà kan ní bar ní 6 May 1980 nígbà tí ó wà ní ọmọ ọdún 47. Ìyẹn ṣẹlẹ̀ nígbà tí Bayewu fi ago ọtí (beer mug) lù ú ní orí.[1] Wọ́n mú Bayewu lọ sí ilé-ẹjọ́, wọ́n sì dá a lẹ́bi ikú ní ọdún díẹ̀ lẹ́yìn náà.[2] Ní ọjọ́ tí Àyìnlá kú, ilé-iṣẹ́ EMI Records ta ó kéré tán ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta (50,000) àwo orin rẹ̀.[5]

Ogún Rẹ̀ (Legacy)

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Lẹ́yìn ikú Àyìnlá Ọmọwúrà ní ọdún 1980 àti Haruna Ishola ní ọdún 1983, òkìkí orin Apala dínkù, orin Fuji sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gbilẹ̀. Àwọn akọrin òde-òní bíi Terry Apala, Mayolee àti Q-dot Alagbe máa ń kọrin ní ọ̀nà tí Àyìnlá Ọmọwúrà gbà ń kọrin.[1]

Ní ọdún 2020, tí ó jẹ́ ogójì ọdún (40 years) lẹ́yìn ikú rẹ̀, wọ́n gbé àwo orin kan jáde tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ Anigilaje láti rántí rẹ̀. Olùdarí sinimá, Tunde Kelani, tún gbé fiimu kan jáde ní 18 June 2021 tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ Ayinla láti sọ ìtàn ayé rẹ̀.[1]

Àwọn Ìtọ́kasí (References)

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. 1 2 3 4 5 6 7 Ajayi, Dami (2021-03-01). "Nigeria's Ayinla Omowura: The original gangster and patron saint of Abeokuta's working class". The Africa Report (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2021-03-01. Retrieved 2021-05-12. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  2. 1 2 3 "Ayinla Ọmọwura, orin èébú àti oríyìn lo fi di ọ̀rẹ́ àwọ̀n obìnrin". BBC News Yorùbá. 2019-06-19. Retrieved 2021-05-15.
  3. "Sikiru Ayinde Barrister, the unforgettable pioneer of Fuji". TheCable Lifestyle (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2016-12-16. Retrieved 2021-05-15.
  4. 1 2 3 4 5 Adegbite, Adewuyi. "Enduring Legacies Of Ayinla Omowura". Nigerian Voice. Archived from the original on 2021-05-15. Retrieved 2021-05-15. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  5. 1 2 Adedayo, Festus (2017-09-27). "Ayinla Omowura: 37 years after the sybarite". TheCable (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2017-09-28. Retrieved 2021-05-15. Unknown parameter |url-status= ignored (help)