Jump to content

Ọdún Ọlọ́jọ́

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Àdàkọ:More footnotes

Olojo Festival
StatusActive
GenreFestivals
BeginsOctober
FrequencyAnnually in September|October
Location(s)Ile Ife Osun State
CountryNigeria
PeopleYoruba people
ọdún ọlọ́jọ̀
àwọn èrò ní ọdún ọlọ́jọ̀

Ọdún Ọlọ́jọ́ jẹ́ ọdún ìbílẹ̀ kan pàtàkì tí wọ́n máa ń ṣe ní Ilé-Ifẹ̀ ní ìpínlè Ọ̀ṣun lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà.[1]

Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ayẹyẹ tí ó gbajúmọ̀ jùlọ ní ilẹ̀ Yorùbá, Ọba Adéyẹ́yè Ẹnitan Ògúnwùsì ṣe àpèjúwe ọdún yìí gẹ́gẹ́ bí ayẹyẹ kan tí ó ń ṣe ayẹyẹ ìran àwọn adúláwọ̀ kárí gbogbo àgbáńlá ayé.[2]

Ọ̀rọ̀ Yorùbá 'Ọlọ́jọ́' túmọ̀ sí 'Ọjọ́ Ojúmọ́ Àkọ́kọ́' tí ó ń ṣàpèjúwe bí ọkàn àwọn ènìyàn ṣe kún fún ọpẹ́ tó sí àwọn ìṣẹ̀dá Ọlọ́run àti wíwà láàyè àwọn ọmọ ènìyàn.[3][4] Ó jẹ́ ọdún tí wọ́n máa ń ṣe ní Ilé-Ifẹ̀ láti ṣe ìrántí ọjọ́ akọ́dá ayé, èyí ni ọjọ́ tí Olódùmarè kọ́kọ́ dá ilé-ayé. Ìgbàgbọ́ àwọn tí wọ́n ń ṣodún Ọlọ́jọ́ ni pé, o jẹ́ ọdún tí wọ́n fi ń bọ Olódùmarè.[5].

Ọdún Ọlọ́jọ́ jẹ́ ayẹyẹ ìbílẹ̀ èyí tí a mọ̀ mọ́ àwọn ará Ílé-Ifẹ̀, ní ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun, èyí tí ó wà ní apá gúúsù ìwọ̀-oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. [6][7]

Ó jẹ́ ọdún tí wọ́n máa ń ṣe ní ìrántí Ògún, ọba irin, ẹni tí a gbàgbọ́ pé ó jẹ́ ọmọkùnrin àkọ́bí Odùduwà, bàbà ńlá àwọn Yorùbá. [8][9] Ayẹyẹ ọdún yìí máa ń wáyé lọ́dọọdún nínú oṣù kẹsàn-án/oṣù kẹwàá. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ní ọdún 2019, wọ́n ṣe ọdún yìí nínú oṣù kejì.[10] Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọdún tí ó tóbi jùlọ nínú àwọn ọdún tí wọ́n máa ń ṣe ní Ilé-Ifẹ̀.[11]

Àwọn tó ń ṣe ọdún Ọlọ́jọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ilé-Ifẹ̀ tí ó jẹ́ orísun Yorùbá ni ọdún yìí tí gbajúmọ̀ jùlọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé káàkiri àgbáyé níbi tí àwọn ọmọ Yorùbá bá wà ní wọ́n tí máa ń ṣe Ọdún Ọlọ́jọ́. [12]

Àkókò tí wọ́n máa ń ṣe ọdún Ọlọ́jọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Oṣù kẹwàá nínú ọdún ni wọ́n máa ń ṣe Ọdún Ọlọ́jọ́.

Ní ọjọ́ yìí, Ọọ̀ni ( ọba Ilé-Ifẹ̀ ) yóò farahàn lẹ́yìn ọjọ́ méje tí ó ti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ tí ó sì sẹ́, níbi tí á ti máa bá àwọn baba ńlá rẹ̀ sọ̀rọ̀, tí yóò sì máa gbàdúrà fún àwọn ènìyàn rẹ̀. Èyí ni láti sọ ọ́ di mímọ́ kí ó sì rí i dájú pé àdúrà rẹ̀ gbà dáadáa. Kí Ọọ̀ni ó tó jáde, àwọn obìnrin láti ìdílé ìyá àti baba rẹ̀ á gbá Ààfin, èyí ni láti gbá àwọn ohun tí ó dàbí ibi kúrò nínú Ààfin.[2][3]

Lẹ́yìn náà, Ọọ̀ni yóò farahàn ní gbangba pẹ̀lú adé Arè (Adé Ọba), èyí tí a gbàgbọ́ pé ó jẹ́ adé àkọ́kọ́ tí Odùduwà dé láti darí ètò àwọn Olórí ìletò kọ̀ọ̀kan àti àwọn Olú-awo láti ṣe ètùtù ní ojúbọ Ògún.

Ìpele tí ó tẹ̀lé ti ayẹyẹ yìí ni láti darí àwọn ènìyàn lọ sí ibi ojúbọ Òkèmògún. Níbí yìí ni wọn yóò ti ṣe àwọn iṣẹ́ bíi ìbúra, dídá Ifá fún Ọọ̀ni ní ìsàlẹ̀ òkè Òkétàgé láti ọwọ́ Àràbà (Olórí àwọn Aláwo), àti ṣíṣe àbẹ̀wò sí àwọn ibi pàtàkì nínú ìtàn.[13]

Ní ibi ojúbọ yìí, àwọn olóyè pẹ̀lú idà oyè wọn tí a fi ẹfun pa tí a sì fi igi ṣe àmì sí, wọ́n yóò fara hàn nínú aṣọ ayẹyẹ ọdún ìbílẹ̀, wọ́n yóò sì máa jó sí ìlú Bẹ̀m̀bẹ́, ìlú tí ó jẹ́ ìlú ìbílẹ̀. IÌlú tí a máa ń lù àti orin tí a máa ń kọ fún olóyè kọ̀ọ̀kan yàtọ̀ sí ar a wọn. Ọọ̀ni nìkan ni ó lè jó sí ìlú tí à ń pè ní Osirigi.

Ọdún Ifá jẹ́ àjọyọ̀ ọlọ́jọ́ méje tí ó máa ń wáyé lọ́dọọdún ní ọjọ́ àbámẹ́ta àkọ́kọ́ nínú oṣù Kẹfà. Ifá (tí a tún mọ̀ sí Ọ̀rúnmìlà ) jẹ́ Ẹlẹ́rìí-ìpín àti ọ̀kan lára àwọn òrìṣà tí ó pàtàkì jùlọ ní ilẹ̀ Yorùbá. Ọjọ́ àkọ́kọ́ àjọyọ̀ yìí ní a ti máa ń rí àwọn àṣà bíi Ìjáwé Ifá Ọọ̀ni (gbígbé ewé gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún Ifá Ọọ̀ni) àti àìsùn ìdánà l'áàfin (ìtọ́jú oúnjẹ qní ààfin), nígbàtí ọjọ́ kejì ni a yà sọ́tọ̀ fún bíbọ Ifá Ọọ̀ni (ìrúbọ fún Ifá Ọọ̀ni). Ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ kẹrin ni a yà sọ́tọ̀ fún Awo Olójú mẹ́rìndínlógún (ẹgbẹ́ awo kan tí ó ní ojú mẹ́rìndínlógún).

Ìdánilẹ́kọ̀ọ́ gbogbogboò àti ìjíròrò lórí 'àwọn obìnrin nínú Ifá,' àti ìṣe àwọn àṣà láti ọwọ́ olú-awo tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Àràbà àgbáyé, èyí tí ó wáyé ní ọjọ́ karùn-ún. Àṣeyọrí ńlá yìí, tí ó bẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ Àbámẹ́ta tí wọ́n ti wọ́n sì ṣe títí di kùtùkùtù ọjọ́ kejì, pẹ̀lú ìwúre (ìbùkún/àdúrà) láti ọwọ́ Àràbà àgbáyé àti àwọn Àràbà mìíràn, àti bíbọ́ Ifá àti dídá Ifá fún ọdún tuntun.[14]

Àwọn Yorùbá gbà pé Ilé-Ife ni ibi tí àwọn ọmọ Yorùbá ti ṣẹ̀ wá, èyí tí í ṣe ibi tí ojúmọ́ ti ń mọ́ wá sílé ayé. Ó jẹ́ ìlú àwọn akíkanjú ológun, ibùjókòó orírun àwọn ọmọ Yorùbá, àti ilẹ̀ àwọn ọba aládé.

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Ooni, Aregbesola, Alabi promote culture at Olojo festival". Punch Newspapers (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2022-09-25. Retrieved 2022-12-26.
  2. 1 2 "Olojo Festival … Grand celebration of rich Yoruba cultural heritage". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2018-11-17. Retrieved 2021-08-07.
  3. 1 2 "Ife begins Olojo Festival as Ooni enters 7-day seclusion" (in en-GB). Premium Times. 2020-09-21. https://www.premiumtimesng.com/regional/ssouth-west/416252-ife-begins-olojo-festival-as-ooni-enters-7-day-seclusion.html.
  4. "Olojo Festival … Grand celebration of rich Yoruba cultural heritage". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2018-11-17. Retrieved 2021-08-07.
  5. "Olojo Festival … Grand celebration of rich Yoruba cultural heritage - The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. 2018-11-17. Archived from the original on 2019-11-12. Retrieved 2019-11-12.
  6. Akintonde, Oluwasola (2022-12-15). "Former Osun State Governor Denies Loan Allegations By Incumbent Governor". Voice of Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2022-12-26. Retrieved 2022-12-26.
  7. "Olojo festival: Celebrating the dawn of creation in Ile-Ife" (in en). Daily Trust. https://dailytrust.com/olojo-festival-celebrating-the-dawn-of-creation-in-ile-ife.
  8. "Olojo festival: Celebrating the dawn of creation in Ile-Ife" (in en). Daily Trust. https://dailytrust.com/olojo-festival-celebrating-the-dawn-of-creation-in-ile-ife.
  9. Ayanwuyi, Israel (2024). "Olojo: The First Dawn" (MP4). AIF YORUBA CULTURAL CENTRE. Retrieved September 29, 2024 via YouTube.
  10. "Osun to build Yoruba museum in Ife, as Ooni emerges from seclusion". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2020-09-26. Retrieved 2021-08-31.
  11. "Olojo Festival Osun State :: Nigeria Information & Guide". www.nigeriagalleria.com. Retrieved 2022-12-31.
  12. "Olojo festival begins in Ife - The Nation Newspaper". The Nation Newspaper. 2019-09-22. Retrieved 2019-11-12.
  13. Ihejirika, Uzoma (2021-07-09). "Olojo Festival". Folio (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2021-08-31.
  14. "Ifa Festival, Ile-Ife Osun State of Nigeria :: Nigeria Information & Guide". www.nigeriagalleria.com. Retrieved 2021-07-31.