Abdullahi Burja

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Abdullahi Burja
Sarkin Kano

Abdullahi Dan Kanajeji, tí a mọ̀ sí Abdullahi Burja, jẹ́ ọba ìlú Kano kẹrìndínlógú. Látàri dídá ìbáṣepọ̀ àti ọ̀nọ̀n okòwò tí ó péye sílẹ̀, Butja ni ó yí ìlú Kano kúrò sí ìlú ìṣòwò tí a mọ Kano àti àwọn ará Kano sí lóde òní [1] Ó jẹ́ ọba Hausa àkọ́kọ́ tí ó tẹríba fún ìlu Bornu tí èyi sì jẹ́ kí àjọṣepọ̀ tí ó dánmọ́ran wà láàrin wọn tí èyí sì jẹ́ kí okòwò wọn gbòòrò láti Gwanja sí Bornu. Ó sì tún jẹ́ ọba àkọ́kọ́ tí ó máa kọ́kọ́ ní ràkúnmí ní gbogbo ilẹ̀ Hausa. [2] Èyí sì fa kí ìṣòwò ẹrú gbòòrò lati Kano sí gúùsù sí Bornu.

Abdullahi Burja nípasẹ̀ Galadima rẹ̀ ṣẹ̀dá àwọn ìleto ẹrú tuntun mọ́kànlélógun, tí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó bí ẹgbẹ̀rún àwọn ẹrú tí ó ipín dọ́gba láàrín àwọn ẹrú ọkùnrin àti obìnrin. Díẹ̀ díẹ̀, ìṣòwò ní Ìlú Kano yípadà sí àwọn òwò mííràn. [3]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Movements, Borders, and Identities in Africa. Boydell & Brewer. 
  2. The Kano Chronicle. https://zenodo.org/record/2415833. 
  3. David Henige, Oral Historiography. London: Longman, 1982, 150 pp., £3.95 paperback..