Abiku

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Àbíkú Àbíkú jẹ́ orúkọ Yorùbá tí ó lè túmọ̀ sí 'ẹni tí wọ́n ń bí tí ó ń kú lọ́pọ̀ ìgbà'.

Ìtumọ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àbíkú ń tọ́ka sí ẹ̀mí ẹni tókú yálà ọmọdé tàbí ẹni tí ó kú kí ó tó dàgbà. Ọmọ tí ó kú kí ó tó di pé ó pé ọmọ ọdún méjìlá ni a lè pè ní àbíkú ọmọdé, bẹ́ẹ̀ kẹ̀,ẹni tí ó kú nígbà tí ó dàgbà tí àwọn òbí rẹ̀ kò ní agbára láti bí òmíràn mọọ́ ni wọ́n ń pè ní àbíkú àgbà.Kò kí ń ṣe wí pé àbíkú nìkan ni ẹ̀mí ọmọ tí ó kú ní kékeré,gẹ́gẹ́ bí ìgbàgbọ́ Yorùbá ni pé ẹ̀mí náà á padà sí ara Ìyá rẹ̀ kan náà ní àìmọye ìgbà láti tún n bí ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà .Ìgbàgbọ́ yìí ni pé ẹ̀mí náà ni ó pinnu láti dúró "ṣe ayé" síbẹ̀ ó jẹ́ sí ipò (ti ìyá )àti ìpọ́njú ìyá rẹ̀. Ẹ̀mí fúnra wọn gbàgbọ́ láti gbé nínú igi ẹ̀yà òwú sílíìkì.[1]

Lítírésọ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìwé à-kà-kọ́gbọ́n ti Ben Okri tí ó pè ní"The famished road"ọ̀nà tókú fún ebi" dá lé lórí àbíkú.ìwé À-kà-kọ́gbọ́n Dèbó kọ̀tun Àbíkú"Àròfọ̀ òṣèlú Nàìjíríà olówó ológun"dá lé lórí àbíkú.ìwé À-kà-kọ́gbọ́n aṣàpèjúwe Gerald Brom ṣe àpèjúwe ohun èlò ìṣeré tó ń jà tako àbíkú,gẹ́gẹ́ Pulse ṣe sàpèjúwe rẹ̀.Ìpadà,Àbíkú ọmọ náà wáyé nínú ìwé kíkọ òǹkọ̀wé ará sìlìfẹ́níáànì Gabriela Babnik,nínú ìwé rẹ̀" Koža is bombaža. A ton rí ewì Wọlé Sóyínká"Àbíkú"tẹpẹlẹ gidi lórí i ìṣèlẹ̀ yìí .[2]

Ìwádìí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àtúnyẹ̀wò àwọn ìtàn àtẹnudẹ́nu káàkiri pàkíyèsí sí i wí pé: Irú àkọlé bẹ́ẹ̀ (nígbà mììràn ìsọ̀tumọ̀ tó dára jù ni wọ́n máa ń jẹ́)nígbà gbogbo ó máa ń papọ̀ mọ́ òtítọ́ nípa àbíkú pẹ̀lú òtítọ́ nípa ọ̀gbáǹje.sojú ìsọ̀kan kọjá àkókò àti ààyè ìkùnà láti sọ ìyàtọ̀ tó wà láàrin gbajúmọ̀ àti a-kọ́ṣẹ́-mọsẹ́,òṣìṣẹ́ ìjọba àti aládàámọ̀,onílé àti àlejò àwon ọfọ̀ àbíkú,ká sọ pé ìgbàgbọ́ nínú àbíkú ní ajẹmọ́ṣẹ́ ọkàn ju ìpìlẹ̀ṣẹ̀ ontọ́lọ́jì àti Kíkánjú wo ìbójúmu àbíkú láti dúró gẹ́gẹ́ bì i àmì fún ọjọ́ òní,èròǹgbà àti àkíyèsí olú ìlú.

Àwọn ìtọ́ka sí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Joseph-Vilain, Melanie. "Commonwealth Essays and Studies - 'The famished road': Ben Okri's family romance? (Literature & Culture Collection)". Commonwealth Essays and Studies 35 (2). https://search.informit.com.au/documentSummary;dn=626759810226949;res=IELLCC. Retrieved 2018-12-11. 
  2. Okri, Ben. "Reading Guide". PenguinRandomhouse.com. Retrieved 2018-12-11.