Jump to content

Abimbola Abolarinwa

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Abimbola Abolarinwa
Ọjọ́ìbíAbimbola Ayodeji Abolarinwa
c. 1979
England, United Kingdom
Orílẹ̀-èdèNigerian
Iṣẹ́
Ìgbà iṣẹ́2006  present
Àwọn ọmọ2

Abímbọ́lá Ayọ̀dèjì Abọ́lárìnwá (tí wọ́n bí ní 1979), jẹ́ oníṣègùn ọmọ Nàìjíríà. Ó jẹ́ Urọ́lọ́jístì obìnrin àkọ́kọ́ ní Nàìjíríà.[1]

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Abímbọ́lá ní ilẹ̀ gẹ̀ẹ́sì, ìlú Ọba (UK) fún ìyà rẹ̀ tí ó jẹ́ agbẹjọ́rò, bàbá rẹ̀ sí jẹ́ ọmọ ógun òfuurufú àti dókítà onísẹ́ abẹ. Abọ́lárìnwá jẹ́ ọmọ bíbí ìlú Ìlọfà, tí ó jẹ́ ọ̀kan lára agbègbè Ìjọba ìbílẹ̀ Òkè Ẹ̀rọ́ ní Ìpínlẹ̀ Kwara. Ó ka ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ni ilé ẹ̀kọ́ ọmọ ógun òfuurufú Nàìjíríà alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ní Kaduna, ó ṣi parí ilé ẹ̀kọ́ girama rẹ̀ ní ilé ẹ̀kọ́ ọmọ ógun òfuurufú obìnrin tó wà ní ìlú Jos kí ó tó tẹ̀síwájú láti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè nínú ìmò ìṣègun ní Yunifásítì Ibadan ni ọdún 2004.[2] Lẹ́yìn tí ó parí ẹ̀kọ́, ó ṣe ikẹ́kọ̀ọ́ ìṣe (internship) rẹ̀ ní Ilé-iwosan àwọn ọmọ ologun orí òfurufú orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (Nigerian Air Force), ní Ikeja, Ìpínlẹ̀ Èkó, lẹ́yìn náà ó tún parí àgùnbánirọ̀ (NYSC) rẹ̀ ní ilé-ìwòsàn àwọn ọmọ ologun orílè-èdè Nàìjíríà (Nigerian Army Reference Hospital), ní Kaduna, níbi tí ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọ́fíṣà ìṣègùn (medical officer). Ní ọdún 2009, wọn gba a síṣẹ́ ní ilé-ìwòsàn Fásitì ìpínlẹ̀ Èkó (Lagos State University Teaching Hospital), níbi tí ó ṣi ń ṣiṣẹ́ títí dòní, fún ẹ̀kọ́ ìmúṣẹ́ rẹ̀ (residency training) nínú abẹ́ (surgery). Ní Oṣù Kẹwàá ọdún 2013, ó di onímọ̀ urology tí a fọwọ́si (certified urologist) lẹ́yìn tí ó yege nínú ìdánwò Apá Kejì (Part 2) ti àwọn onímọ̀ iṣẹ abẹ ìwọ̀-oòrùn afríkà (West African College of Surgeons). Ó tún jẹ́ olùgbà àmì-ẹ̀yẹ àkọ́kọ́ (First Awards) tí a mọ̀ sí Zakilo Awards fún àwọn aṣáájú-ọ̀nà nínú iṣẹ́ wọn ní Oṣù Kínní ọdún 2019.[3] Ó jẹ́ olùkọ́ ní Fásitì kọlẹẹjì ògùn ní ìpínlẹ̀ Èkó (Lagos State University College of Medicine), ó sì tún jẹ́ Onímọ̀ ìtọ́jú ìbáṣepọ̀ (Honorary Consultant) sí ilé-ìwòsàn Fásitì ìpínlẹ̀ Èkó (Lagos State University Teaching Hospital), ní Ikeja.[4]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Orakpo, Ebele (24 May 2015). "My job is not family friendly —Abolarinwa, Nigeria’s first female urologist". Vanguard News. http://www.vanguardngr.com/2015/05/my-job-is-not-family-friendly-abolarinwa-nigerias-first-female-urologist/. Retrieved 18 July 2016.
  2. "LASU VC congratulates Abolarinwa, first Nigerian female Urologist". guardian.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2019-12-19. Retrieved 2019-12-19.
  3. https://guardian.ng/news/lasu-vc-congratulates-abolarinwa-first-nigerian-female-urologist/
  4. https://web.archive.org/web/20160808153101/http://nausonline.org/index.php?option=com_content&view=article&id=73:meet-dr-abimbola-abolarinwa-nigerias-first-female-urological-surgeon&catid=25:news-and-events&Itemid=55&limitstart=1