Adéníkẹ̀ẹ́ Grange

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Àdàkọ:EngvarB

Adéníkẹ̀ẹ́ Grange
Ilé-iṣẹ́ ètò ìlera ìjọba àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (Federal Minister of Health)
In office
26 July 2007 – 26 March 2008
AsíwájúEyitayo Lambo
Arọ́pòBabatúndé Oṣótìmẹ́yìn

Adenike Grange jẹ́ Mínísítà àná fún ètó ìlera lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti ọdún 2007 sí 2008.

Ayé rẹ̀ ní ìbẹ̀rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adéníkẹ̀ẹ́ Grange kàwé ní ìlú Èkó kí ó tó kọjá sí St. Francis' College, LetchworthUnited Kingdom láti tẹ̀ síwájú. Ó kàwé gboyè nínú ìmọ̀ ìṣègùn òyìnbó lọ́dún 1958 sí 1964 ní University of St Andrews lórílẹ̀-èdè Scotland. Ó ṣiṣẹ́ ní ilé-ìwòsàn Dudley Road Hospital ní Birmingham kí ó tó padà sí Nàìjíríà lọ́dún 1965, tí ó sìn ṣiṣẹ́ ní àwọn ilé-ìwòsàn ní Ìpínlẹ̀ Èkó. Ó tún padà sí òkè-òkun, United Kingdom lọ́dún 1967, tí ó sìn ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí dókítà àwọn ọmọdé St Mary's Hospital for children. Ó kàwé gboyè dípólómà si nínú ìmọ̀ ìlera ọmọdé lọ́dún 1969. Lọ́dún 1971, ó dára pọ̀ mọ́ Lagos University Teaching Hospital, ó sìn di olùkọ́ ní Ẹ̀ka-ẹ̀kọ́ (College of Medicine) , Lọ́dún 1978 ní University of Lagos. Ó di olùkọ́ àgbà lọ́dún 1981,bẹ́ẹ̀ náà ó di Ọ̀jọ̀gbọ́n lọ́dún 1995.[1]

Adéníkẹ̀ẹ́ Grange ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí agbani-nímọ̀ràn sí ilé-iṣẹ́ ètò ìlera ìjọba àpapọ̀, Federal Ministry of Health, WHO, UNICEF, UNFPA àti USAID.[2] Òun ni olùdámọ̀ràn sí àjọ WHO ní Nàìjíríà lórí ètò ìlera ọmọ bíbí láti ọdún 1993 sí 1999. Ó ti kọ ju ìwé àádọ́ta lọ lórí ètò ìlera, pàápàá jù lọ lórí àìsàn diarrhoeal àti ètò oúnjẹ ẹ̀tọ́ fún ọmọdé. Ó jẹ́ Ààrẹ fún ẹgbẹ́ International Paediatric Association.[3] Lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀, wọ́n mọ̀ ọ́n gẹ́gẹ́ bí aṣègbè fún ìlera tó péye fún àwọn ọmọdé.[4]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Professor Adenike Grange" (PDF). World Health Organization. Retrieved 31 October 2009. 
  2. Pediatrics, American Academy of (2007-09-01). "Dr. Grange named Nigerian health minister" (in en). AAP News 28 (9): 40–40. ISSN 1073-0397. https://www.aappublications.org/content/28/9/40.1. 
  3. "Welcoming Adenike Grange and Gabriel Aduku". Nigeria Health Watch. 27 July 2007. Archived from the original on 29 April 2010. Retrieved 31 October 2009.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  4. "Article: Adenike Grange – Crusading for the African Child's Health". Women & Environments International Magazine Article. 1 October 2002. Retrieved 31 October 2009. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]