Jump to content

Adekunle Akinlade

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Adekunle Akinlade
Ọjọ́ìbí9 Oṣù Kẹ̀wá 1969 (1969-10-09) (ọmọ ọdún 56)[1]
Ipokia, Ìpínlẹ̀ Ògùn, Nàìjíríà
Iṣẹ́Olóṣèlú

Adekunle Abdulkabir Akinlade Yo-Adekunle Abdulkabir Akinlad.ogg Listen Triple A (a bí i ní ọjọ́ kẹsàn-án oṣù Ọ̀wàrà ọdún 1969) jẹ́ olóṣèlú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó ṣojú Egbado South àti Ipokia federal constituency nínú Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àpapọ̀.[2] Ó kúrò nínú All Progressive Congress ó sì dara pọ̀ mọ́ Allied Peoples Movement láti díje fún ipò Gomina Ìpínlẹ̀ Ògùn nínú ìdìbò ọdún 2019.[3]

Ìbèrè ìgbésí ayé

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Akinlade ní Ipadilpopo Compound ní Agosasa, Ipokia Local Government Area ti Ìpínlẹ̀ Ògùn. Ó lo àwọn ọdún ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé rẹ̀ ní rírìn-àjò kárí orílẹ̀-èdè pẹ̀lú bàbá rẹ̀.[4][5]

Akinlade lọ sí Children House School àti St. Anne's Primary School ní Ibara, Abeokuta, kí ó tó parí ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ ní Army Children Primary School ní Akure, Ìpínlẹ̀ Òndó. Ó lọ sí Emmanuel Comprehensive High School, Ilaro, àti lẹ́yìn náà Yewa High School, Ajilete, níbi tí ó ti gba West African School Certificate (WASC) ní ọdún 1988. Lẹ́yìn náà, ó kẹ́kọ̀ọ́ ní College of Preliminary Studies, Yola, kí ó tó gba oyè bachelor’s nínú ìmọ̀ òṣèlú láti Lagos State University ní ọdún 1995. Lẹ́yìn ìparí ẹ̀kọ́, ó parí National Youth Service Corps (NYSC).[6][7]

Iṣẹ́ Gégébí olóṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A yàn án gẹ́gẹ́ bí olùrànlọ́wọ́ pàtàkì lórí ọ̀rọ̀ ọ̀wọ̀ orí àti ipawo wọlé ní ábéléní ni oṣù Agẹmọ ọdún 2011. Ní ipò yìí, ó ṣàkóso Directorate of other Taxes ti Board of Internal Revenue Services (IRS) ìpínlẹ̀. Ó dara pọ̀ mọ́ All Progressive Congress nínú ìdìbò gbogbogbò ọdún 2015 láti ṣojú Egbado South àti Ipokia ní Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àpapọ̀.[8] Ó yí padà sí Allied Peoples Movement láti díje nínú ìdìbò gomina ọdún 2019, lẹ́yìn tí kò rí yíyàn APC, èyí tí ó pàdánù fún Dapo Abiodun.[9]

Ìgbésí ayé ara ẹni

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Akinlade ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú Chinenye Ochuba, ẹni tó jẹ́ Most Beautiful Girl in Nigeria àti Miss World Africa tẹ́lẹ̀rí, ní ọdún 2008.[10][11]

  1. "-The story of Hon. Adekunle Abdulkabir Akinlade". 8 September 2018.
  2. "Adekunle Akinlade". Nigeria National Assembly. Retrieved 2 August 2026.
  3. "Amosun's Candidate, Adekunle Akinlade, Dumps APC For APM". Sahara Reporters (New York City, United States). http://saharareporters.com/2018/11/30/amosun’s-candidate-adekunle-akinlade-dumps-apc-apm.
  4. "WHO IS OGUN APC CONSENSUS CANDIDATE? [THE STORY OF HON. ADEKUNLE ABDULKABIR AKINLADE". 8 September 2018.
  5. "Hon. Adekunle Abdulkabir Akinlade". Archived from the original on 2019-03-06. https://web.archive.org/web/20190306045809/https://www.yewaland.com/portfolio/hon-adekunle-abdulkabir-akinlade/.
  6. "How Gov. Amosun Plans To Make Akinlade Governor". City People Magazine. 2018. Retrieved 2 August 2026.
  7. "Hon. Adekunle Abdulkabir Akinlade: A Yewa Man Like No Other". Independent Newspaper Nigeria. 9 October 2019. Retrieved 2 August 2026.
  8. "Biography of Adekunle Akinlade". 6 June 2018.
  9. "God'll not forgive me if I stop Akinlade, others from moving to APM — Amosun". Vanguard (Lagos, Nigeria). 4 December 2018. https://www.vanguardngr.com/2018/12/godll-not-forgive-me-if-i-stop-akinlade-others-from-moving-to-apm-amosun/.
  10. "Kunle Akinlade, wife step out in style". The Punch. 8 October 2017. https://punchng.com/kunle-akinlade-wife-step-out-in-style/amp/.
  11. "That Amosun/Akinlade deal". Vanguard (Lagos, Nigeria). 26 January 2019. https://www.vanguardngr.com/2019/01/that-amosun-akinlade-deal/amp/.