Jump to content

Adiele Afigbo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Adiele Eberechukwu Afigbo
Born(1937-11-22)Oṣù Kọkànlá 22, 1937
Ihube, Okigwe, Nigeria
DiedMarch 9, 2009(2009-03-09) (ọmọ ọdún 71)
Enugu, Enugu State, Nigeria
NationalityNigerian
EthnicityIgbo
FieldsAfrican History
InstitutionsUniversity of Ibadan, Ibadan
(1964 – 1966)
University of Nigeria Nsukka
(1966 – 1992)
Alvan Ikoku College of Education, Owerri,
(1993 – 1998)
Abia State University, Uturu,
(1998 – 2003)
Ebonyi State University, Abakaliki,
(2004 - 2009)
Alma materUniversity of Ibadan
Known forhistory and historiography of Africa

Adiele Eberechukwu Afigbo (born 22 November 1937 — 9 March 2009) je ojogbon onimo Itan omo ile Naijiria lati eya igbo.


Afigbo bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ amọ̀ràn-itan rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí akẹ́kọ̀ọ́ ìtàn ní ọdún mẹ́ẹ̀dógún-dín-lọ́gọ́rin (1950s) ni Ile-ẹ̀kọ́ Itan Ibadan (Ibadan School of History). Fún àárín ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n sí mẹ́ẹ̀dẹ́gbọ̀n, ile-ẹ̀kọ́ yìí ni ó jẹ́ olórí jùlọ nínú ẹ̀kọ́ ìtàn ní Áfíríkà. Afigbo di ọmọ ẹgbẹ́ pàtàkì nínú rẹ̀, ó sì kópa gidigidi nínú ìpinnu àfojúsùn rẹ̀—èyí tí ó dojukọ fífi hàn pé ìtàn Áfíríkà àti ìmúlò ìkọ̀wé-itan rẹ̀ jẹ́ apá pàtàkì àti aláyọkà nínú ìtàn ayé lapapọ̀.

Nípasẹ̀ ẹ̀kọ́ àti iṣẹ́ ìwádìí rẹ̀, Afigbo ṣàgbékalẹ̀ ọ̀pọ̀ iṣẹ́ tí ó mú kí ìtàn àtúnkọ́ (reconstructionist history) di mímọ̀, ó tún ṣe àfihàn ìlànà àti ọ̀nà ìmúlò ìtàn Áfíríkà, pẹ̀lú fífi ìbáṣepọ̀ hàn láàárín ìtàn àti ìṣàkóso ìjọba. Ó gba ọ̀nà àkójọpọ̀ (eclecticism) gẹ́gẹ́ bí ìlànà, níbi tí ó ti ń lo oríṣìíríṣìí orísun gẹ́gẹ́ bí àyípadà ìbéèrè ṣe jẹ́: àròsọ àti àlàyé àtọ́runwá (myth), àṣà-ọrọ̀ ẹnu (oral traditions), ìwádìí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ (archaeology), èdè àti ìtúpalẹ̀ rẹ̀ (linguistics), ohun èlò àṣà (material artefacts), àti orísun tí a kọ sílẹ̀.

Ní ìpinnu ikẹhin rẹ̀, Afigbo ṣàlàyé onítàn gẹ́gẹ́ bí akẹ́kọ̀ọ́ tó ń ṣàbẹ̀wò ìrírí ènìyàn lọ́nà ìmúlò àti ìtọ́nisọ́nà, ẹni tí ó ń tiraka láti sọ ìtàn bí ó ṣe rí gan-an, kí ó sì ṣàlàyé ìtumọ̀ àti ìdí rẹ̀.

Ìgbésí-ayé ìbẹ̀rẹ̀ àti Ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Afigbo ní Ihubẹ̀, Okigwe, ní ìpínlẹ̀ Imo tí a mọ̀ lónìí. Ẹ̀kọ́ ilé-ẹ̀kọ́ gidi rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ní ọdún 1944 ní Methodist Central School, Ihube, níbi tí ó ti wá sí abẹ́ ìtọ́́sọ́nà àwọn olùkọ́ tí wọ́n jẹ́ ẹni ìyàsọ́tọ̀ gan-an ní ìfaradà àti ìfaramọ́ sí iṣẹ́. Lára wọn, ẹni tí ó dára jùlọ ni Ọgbẹ́ni Oji Iheukumere, olórí ilé-ẹ̀kọ́ (head teacher), ọmọ ìlú Uzuakoli ti a mo si ìpínlẹ̀ Abia tí a mọ̀ lónìí. A mọ̀ ọ́ gẹ́gẹ́ bí akọrin ṣọ́ọ̀ṣì tó gbajúgbajà àti ẹni tó lágbára nínú ìtójú ìwa àti ìlànà.

Ní Ihube Central School, ọgbọ́n àti ìmúlò ọpọlọ Afigbo fara hàn láti ìbẹ̀rẹ̀. Ìfarahàn yìí ló mú kí àwọn olùkọ́ rẹ̀ gbà á níyànjú láti tẹ̀síwájú sí ilé-ẹ̀kọ́ girama (secondary school), láìka ìtakò àwọn òbí rẹ̀ tí wọ́n bẹ̀rù ìnáwó tó wà nínú ẹ̀kọ́ lẹ́yìn ìpele alakọbẹrẹ (post-primary education).

Ní ìparí, ó ṣàṣeyọrí nínú ìsapá rẹ̀, ó sì lọ sí St. Augustine’s (CMS) Grammar School, Nkwerre, Orlu ní Ìpínlẹ̀ Imo, pẹ̀lú sikolashipu Okigwe Native Administration tí ó gba lẹ́yìn ìdánwò ìdíje kan. Ní ilé-ẹ̀kọ́ yìí pẹ̀lú, ó tún pàdé ẹgbẹ́ àwọn olùkọ́ tí ipa wọn fi ààmì kedere sí ìdàgbàsókè ọpọlọ àti ìmọ̀ rẹ̀.

Lára àwọn olùkọ́ wọ̀nyí, ẹni pàtàkì jùlọ ni Mazi F. C. Ogbalu, olùkọ́ èdè àti àṣà Igbo, tí ó tún jẹ́ olùdásílẹ̀ Society for Promoting Igbo Language and Culture; C. G. I. Eneli, akẹ́kọ̀ọ́ ìtàn tí ó parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní University College, Ibadan; àti E. C. Ezekwesili, olùdarí ilé-ẹ̀kọ́ (principal) náà, tí ó jẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ ìtàn láti University of Southampton, ní Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì (UK). Àwọn olùkọ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ló kó ipa tó lágbára jùlọ nínú ìtọ́sọ́nà àti ìpinnu ipa-ọ̀nà iṣẹ́ ẹ̀kọ́ gíga tí Afigbo gbà ní ọjọ́ iwájú.

Látinú St. Augustine’s Grammar School, Afigbo rí ìwọlé láti kẹ́kọ̀ọ́ ìtàn ní University College, Ibadan (nígbà yẹn tí ó jẹ́ alájọṣepọ̀ pẹ̀lú University of London), pẹ̀lú sikolashipu láti ọ̀dọ̀ ìjọba Ìlà-Oòrùn Nàìjíríà (Eastern Nigeria). Níbi yìí pẹ̀lú, ó tún pàdé àwọn amòye-ẹ̀kọ́ tí a mọ̀ fún ọgbọ́n gíga àti ipa rere tí wọ́n ní lórí akẹ́kọ̀ọ́—J. D. Omer-Cooper, J. C. Anene, J. F. Ade Ajayi, àti Kenneth Onwuka Dike.

Ó tún ní àwọn ẹlẹ́gbẹ́ ẹ̀kọ́ bíi Obaro Ikime àti Philip Igbafe, tí kì í ṣe pé wọ́n kẹ́kọ̀ọ́ ìtàn pọ̀ mọ́ọ̀, ṣùgbọ́n tí wọ́n tún jẹ́ alákóso ìbẹ̀rẹ̀ ohun tí a pè ní “PhD tí a ṣe ní Nàìjíríà” (made in Nigeria PhD) ní University of Ibadan tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ dá sílẹ̀, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ sikolashipu ẹ̀kọ́ gíga (postgraduate scholarships) tí yunifásítì náà fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó dára jùlọ ní ìpẹ̀yà ìparí ẹ̀kọ́ wọn.

Afigbo kì í ṣe pé ó parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹni tó ga jùlọ nínú kíláàsì rẹ̀ nìkan, ó tún jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ láàárín àwọn ẹlẹ́gbẹ́ rẹ̀ tí ó parí ìwé-ẹ̀rí PhD rẹ̀. Nípa èyí, ó di ẹni àkọ́kọ́ tí ó gba ìwé-ẹ̀rí dókítà (doctoral degree) láti inú yunifásítì kan ní Nàìjíríà[1].

Iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Onítàn

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Afigbo jẹ́ òn-kò itán Áfíríkà, onítàn Nàìjíríà, onítàn Gúúsù-Ìlà-Oòrùn Nàìjíríà, àti ní parí parí e, onítàn àwọn èyà Igbo. Ó jẹ́ onítàn òṣèlú, onítàn ètò-ọrọ̀ ajé àti àwùjọ, pẹ̀lú amòye nínú ìmúlò àti ìkọ̀wé-itan (historiography). Ọ̀kan lára àwọn ìwé àkójọpọ̀ àròkọ rẹ̀ mẹ́ta tí Toyin Falola ṣàtúnṣe, "Myth, History and Society[2]", dá lórí ìtúpalẹ̀ ìmọ̀-ọrọ̀ nípa àwọn ọ̀nà tí a fi ń ṣe ìtàn ní Áfíríkà, àwọn orísun ìtàn Áfíríkà, ipa àti ìwúlò ìtàn ní àgbègbè Áfíríkà, àti àwọn ọ̀ràn míì tó jọmọ́ wọn.

Nínú ọ̀pọ̀ ìtẹ̀jáde rẹ̀, Afigbo ń gbìmọ̀ràn láti lo ohun kékeré kan láti ṣàlàyé ohun tó jẹ́ òun àgbáyé, àti láti lo ìrírí àgbáyé láti túmọ̀ ohun kékeré . Fún àpẹẹrẹ, ó lo ìwádìí jinlẹ̀ lórí ìlànà aṣọ àti ìdáṣe aṣọ ní Gúúsù Nàìjíríà láti tan ìmole sí ìbáṣepọ̀ àwùjọ àti àṣà àwọn àwùjọ agbègbè yẹn. Bákan náà, ó lo ìdàgbàsókè àti ìtàn ìtẹ̀síwájú àwọn ìjọba ńlá ṣáájú ìjọba òkèèrè—gẹ́gẹ́ bí Benin—láti fi hàn pé ohun tí a ń pè ní “àwùjọ apakan-apakan” (segmentary societies) àti “àwọn ìpínlẹ̀ kékeré” (mini-states) ní Áfíríkà ṣáájú ìjọba òkèèrè, jẹ́ lára ohun míì, àfihàn tí ó ti di dídì (fossilized) ti àwọn àyípadà àwùjọ àti òṣèlú tí àwọn ìjọba ńlá wọ̀nyí ti dá sílẹ̀ láti inú wọn.

Alàgbà Afigbo jáde láye ní ilú Enugu, Nigeria ní ọjọ́ ajé, ojọ́ kẹsàn án oṣù kẹta ọdún 2009 lẹ́yìn àìsàn ránpẹ́.[3]