Aríyìíkẹ́ Akínbòbọ́lá
| Aríyìíkẹ́ Akínbóbólá | |
|---|---|
Akínbóbólá in 2014 | |
| Ọjọ́ìbí | Aríyìíkẹ́ Lawal 25 Oṣù Kẹrin 1982 Lagos, Nigeria |
| Ẹ̀kọ́ | London Academy of Media, Film and television |
| Iṣẹ́ | Agbejoro, Aláwòkọ́ṣe, Olóòtú, Òṣèrè, Olùdarí Ètò Amóhùnmáwòrán ati Oníròyìn-Àheso |
| Ìgbà iṣẹ́ | 2011 – present |
| Website | reflectionswithariyike.blogspot.com |
A bí Aríyìíkẹ́ Lawal-Akínbọ̀bọ́lá ní ọjọ́ kẹẹ̀édọ́gbòn oṣù kẹẹ̀rin ọdún 1982. Ó jẹ́ Olóòtú oríṣiríṣi ètò lórí i èrò tẹlifịṣàn, oníròyìn àheso, agbẹjọ́rò àti òṣèré sinimá àgbéléwò[1] láti 2011, ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olùdarí eré ìgbéléwòa àti Olóòtú Amóhùnmáwòrán ìkànnì DSTV . gẹ́gẹ́ bí olùgbàlejò Spice TV's flagship programme 'On the Couch'[2] and in addition she has produced and presented the fashion news and has as well presented other TV Shows including Sugar and Spice, Urban Spice, Instant Beauty Queen and Project Swan. She also currently presents the gadget show Spice Toys.[3]
Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbésí ayé
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wọ́n bí Akinbobola ni ile ìwòsàn St. Nicholas ní Ẹ̀kọ́, Nàìjíríà. Ó jẹ́ ọmọ Kàrún nínú ọmọ mẹ́fà tí Adéwálé ati Ladun Lawal (née Ojutalayo). Ó jẹ́ ọmọ Yorùbá ti bàbà rẹ, Mojeed Adewale sì kà ìwé nípa imo oro aje àwùjọ ni Yunifásítì Obafemi Awolowo, Ile-Ife. Ó jẹ́ òṣìṣẹ́ ìjọba ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tí ó sì kópa nínú àwọn iṣẹ́ ọ́kàn ó jọ kan kótó di wí pé ó fi àdàgbá rọ̀ sì ipò olùdarí eto ìṣúná ìjọba . Ara ẹ̀, Ládùn Lawal je ìjòyè Yeye-Ọba Iyanfoworogi ni ifẹ̀ Ó jẹ́ onímọ̀ nípa títa ogún ìlera tí tún dárí ilé iṣẹ́ kékeré kan tí òun pèlò Ògùn ni Ilé-Ifè, Ìpínlè òṣun pelu Ẹka kan ni Ipinle Èkó.
Ìfẹ́ Akinbobola sì ère idanilaraya bere láti ìgbà tí ọtí wá ní ọmọ kékeré. Òun àti àwọn àbúrò rè won má kopa ninu orin ni àkókò ìkorajo ebi àti ara. Ó lọ sí ilé ìwé alakobere federal home science primary school ìkòyí, ni ipinlẹ Èkó nibi ti o ti je omo egbe Aájò Brownies nígbà tí ó wọ ilé ẹ̀kọ́ àgbà ní Kọlẹji Queen ni Èkó. Ó jẹ́ ojú mimo ni ori pẹpẹ ìṣeré ilewe rẹ látàrí ìwà òyàya tó ní. Ti ó ṣì gba àmì Èyẹ ẹni tí ọní òyàya julọ fún yàrá ìkẹ́kọ̀ọ́ re ni ọdun 1998 ni àkókò ayẹyẹ ìparí ọdún. Leyin na ó tẹ̀síwájú nínú Ẹ̀kọ́ rẹ lọ sí Yunifásítì tí ìlú Èkó níbi tí ọtí kò ẹ̀kọ́ nípa imo òfin.
Ní Odún 2006, ó gba oyè Itesiwaju nínú Ẹ̀kọ́ imo òfin lèyí ti o fún ni ànfàní láti tẹ̀síwájú lọ sí ilé ìwé imo òfin tí Nàìjíríà ni ilu ẹ̀kọ́ níbi tí ó ti gba ẹ̀kọ́ òye sayensi nínú ìmọ̀ òfin.[4]
Akinbobola, ẹni tó sunmo baba rẹ Dada ni ìjákule púpò nígbà tí bàbá rè, ẹni tí ó tin na aarun ìgbàgbé Ọpọlọ àgbàlagbà finra fun bi Odún márùndínlọ́gun di olóògbé ni Oṣu kinni odun 2010.
Ní Odún 2011,leyin igba ti ọtí bere si n se ise amòfin, ó gba oyè dípílómà nípa ìgboun sì afẹ́fẹ́ ni ile ìkẹ́kọ̀ọ́ nípa oro orí afẹ́fẹ́, (London Academy Of Media And Transmission).[5]
Iṣẹ́ Ìṣe
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní Odún 2010, Akinbobola bere si mi ṣe àkásílè àwọn àwo fọ́nrán fún èrè orí telefison rẹ pẹlu àkọlé, "Reflections with Ariyike" èyí tí ó ṣe wọ lórí ìkànnì YouTube rẹ, "Ariyike Weekly". Ni Odún 2011, ó ṣe ètò ìgbéyàwó fún ipò olùṣètọ́ lórí ìkànnì Tẹlifíṣọ̀n Spice ni ọdun 2011, wọn gba Akinbobola gẹgẹbi osise ni Tẹlifíṣọ̀n Spice gẹgẹbi olùṣètọ́.[6]
Gẹ́gẹ́bi olusoro ọri afẹ́fẹ́, Akinbobola tí ṣe ìjomitoro òrọ̀ pelu awon ilumoka ènìyàn ara Nàìjíríà àti àwọn tí ìlú Ọ̀kèrè títí to fi dé orí àwọn asoju sì ilé Ọ̀kèrè. Ó ti fọ̀rọ̀ jomitoro pẹ̀lú Dr. Andrew Pocock, aṣoju Ile britiko sì ilé Nàìjíríà, Mr. Mike Purves, Olùdarí fun òrọ̀ Karakata, Pauline Long, olùdásílẹ̀ ami eye BEFFTA, Mrs. Bunmi Òkè, Aare ẹgbé ìpolongo ọjà ni Nàìjíríà (AAAN) Carl Thomas, olorin Ile Amerika, Otunba Nìyí Baba de tí CNN àti opó àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tí wọ́n jẹ́ oníṣòwò. No 2013, ó ṣe alagbateru ayẹyẹ iṣafihan ẹwà ni Nigerian - British Chamber of commerce presidential ball.[7]
Ni 2013, Akinbobola ṣe afihan ere àkókò rẹ nínú ère àgbéléwò alábala "Lekki Wives[8]" Pẹ̀lú Kiki Omeili àti Katherine Obiang, o tun ṣe afihan miran nínú eré alábala "Aunty Caro's Bar"[9]. Òun àti Ikponmwosa Osakioduwa jọ fowosowopo se Lagos Countdown Crossover ni 2012 áti "Quest" Pẹ̀lú Gbenga Adeyinka àti I'll-Rhyme ni ọdun 2013. Ayẹyẹ òun ni Ijọba ìpínlẹ̀ ẹ̀kọ́ gbekalẹ̀ tí wọ́n sì ṣe àfihàn rẹ káàkiri gbọgbọ ilé Afirika. Ó fi ara pé ayẹyẹ olódọọdún tí wọ́n má ńṣe ni Times Square, New Year Countdown[10].
Akinbobola tún jẹ́ olùkọ̀wé àlejò fún ọ̀kan lára àwọn ojú-ìwé bulọ́ọ̀gù tí ó ga jù lọ ní Nàìjíríà “Bella Naija”, níbi tí ó ti ń kọ ìtàn ìṣìrọ̀ àti ìbáṣepọ̀ nípa àwọn ọ̀ràn tó ń kan àwọn ọmọ Áfríkà. Ó ní abala tirẹ̀ tí a pè ní “Ariyike writes”. Ó tún ń ṣe bulọ́ọ̀gù tirẹ̀ www.reflectionswithariyike.blogspot.com.
Ní ọdún 2022, Akinbobola bẹ̀rẹ̀ sí í ìgbalejò ìgbáfé kíkà ìwé ebí ní Ontario Canada tí a pè ní ‘Beautifully Coloured’. Tí ìrìnàjò igbafe náà si ń gbé kíkà ìwé lárugẹ, kíkà àwọn ìfọwọ́sí rere, àti láti pàkíyèsí sí àwọn ọ̀ràn to ni ṣe pẹ̀lú ìfipá kó ọmọdé àti àwọn ibi mìíràn Ìwé àwòrán tirẹ̀ lórí ìwà rere, tí a tún pè ní Beautifully Coloured, jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìwé tí ó tà jù lọ lórí Amazon[11][12].
Ìgbésíayé Ara Eni
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wọn tí gbé Ariyike ni ìyàwó[13] ó sì ti bí ọmọ ọkùnrin mẹ́ta.
Àwọn Iṣẹ́ Àánú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní ọjọ́ kẹjọ oṣù Kejìlá ọdún 2013,Akinbobola ṣe apeje Kérésìmesì àkókò tó jẹ́ titi ìtọrẹ níbi tí ìtọrẹ Anu láti ọwọ́ rẹ àti àwọn ẹbí, ọrẹ, àti ojulumo rẹ tí losi àwọn ilé àjò tiwọn ṣe agbáterù ìtọrẹ àánú mẹsan.[14]
Àwọn aṣojú láti àwọn ẹgbẹ́ NGO, àwọn olókìkí olórukọ àti àwọn olórukọ nínú ilé ìròyìn wà níbi ìṣẹ̀lẹ̀ náà pẹ̀lú. Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́sàn-án tí ó jẹ̀rè ni Earths Haven foundation, Slumdwellers Liberation forum, Lots charity, Green pastures kiddies, Haven for the Nigerian child, Vocal Slender's Ghetto Love project, Arrows of God orphanage, Society for love and social justice, Campaign against Ignorance and illiteracy. Ariyike tún ṣẹ̀dá ojú-ìwé wẹ́bù kan tí ó ń ṣètìlẹ́yìn àti ṣẹ̀dá ìpolongo fún àwọn ẹgbẹ́ àjọ, ojú-ìwé náà ni www.234give.com.
Ní oṣù Kejìlá ọdún 2012, gẹ́gẹ́ bí ipá kan nínú ìrìn àjò Edutainment ti ilé-ẹ̀kọ́ síkọ́ndẹ̀rì tí Van Cliff àti iCirculate ṣètò, Akinbobola àti ẹgbẹ́ kan àwọn òṣèré ṣàbẹ̀wò sí oríṣiríṣi ilé-ẹ̀kọ́ síkọ́ndẹ̀rì láti se kóríyá fun àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àti láti gbìn erongba dada sínú wọn nípa Nàìjíríà. Wọ́n tún kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn anfàní àti àwọn aburu ti nbẹ nínú lilo ìkànnì ibanidore, ti won sì tún gba àwọn akẹ́kọ̀ọ́ níyànjú nípa ìjẹ́pàtàkì ẹ̀kọ́ nígbà tí a bá ń ṣiṣẹ́ nínú ilé-iṣẹ́ eré-ìdárayá. Ní ọdún 2013, wọn ṣètò apá kejì ìrìn àjò náà.
Ní oṣù kọkànlá ọdún 2013,Akinbobola fowósowópò pelu "Vocal Slender's Back to School Ghetto Love Project" láti fi àwọn àpò ìkọ̀wé ọmọ ilé ìwé kale fún ogoro àwọn akeko ni agbègbè Ajegunle tí wọ́n ó rí owó rori, àti fún àwọn ọmọ tí wọ́n padà lọ sí ilé ìwé. Akinbobola tún darapò mó Pink ààjo Heritage Company, Ààjo kan tí òun ṣe ìpolongo itaniji àti ìgbani-níyànjú lori ibalopo àìtọ́ Pẹ̀lú àwọn ọmọ ilé ìwé.
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "I Make my husband chase me: Spice TV Presenter, Ariyike Akinbobola". The Nation Newspaper (Lagos, Nigeria). 17 May 2014. http://thenationonlineng.net/new/make-husband-chase-always-spice-tv-presenter-ariyike-akinbobola/. Retrieved 19 June 2014.
- ↑ "Spice TV’s "On The Couch" is Back for Season 3 with Host & New Mum Ariyike Akinbobola". BellaNaija (Lagos, Nigeria). 25 May 2016. https://www.bellanaija.com/2016/05/spice-tvs-on-the-couch-is-back-for-season-3-with-host-new-mum-ariyike-akinbobola/. Retrieved 14 September 2017.
- ↑ "TV Personality Ariyike Akinbobola releases Pretty New Photos, spills on Her Big Plans". BellaNaija (Lagos, Nigeria). 26 August 2014. https://www.bellanaija.com/2014/08/tv-personality-ariyike-akinbobola-releases-pretty-new-photos-spills-on-her-big-plans/. Retrieved 14 September 2017.
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-school-6
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-Husband-2
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-Husband-2
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-host-7
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Lekki_Wives
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-Caro-8
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-countdown-9
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-bestseller-10
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-bestseller-10
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-Husband-2
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Ariyike_Akinbobola#cite_note-11