Clem Ohameze

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Clem Ohameze
Clem Ohameze at a party, August 2011
Ọjọ́ìbí27 Oṣù Kẹfà 1965 (1965-06-27) (ọmọ ọdún 58)
Port Harcourt, Nigeria
Orílẹ̀-èdèNigerian
Orúkọ mírànClem
Ọmọ orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Iléẹ̀kọ́ gígaUniversity of Port Harcourt
Iṣẹ́Actor
Ìgbà iṣẹ́1995-present
Ọmọ ìlúOguta, Imo State, Nigeria

Clem Ohameze jẹ́ gbajúmọ̀ òṣèré sinimá àgbéléwò ọmọ bíbí ìpínlẹ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ó ti ń ṣeré fún nǹkan bí ogún ọdún sẹ́yìn.[1] Clem Ohameze bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ sinimá àgbéléwò lọ́dún 1995. Ṣùgbọ́n ó bẹ̀rẹ̀ sí ní gbajúmọ̀ ní kété tí ó kópa nínú sinimá àgbéléwò kan tí àkọ́lé rẹ̀ End TIME.[2] Ó ti kópa nínú sinimá àgbéléwò tó ti to ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) fún ọdún ogún tí ó ti ń ṣeré láti ọdún 1995 títí di àkókò yìí.

Ìgbà èwe[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Clem Ohameze lọ́jọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣù kẹfà ọdún 1965 (27 June 1965) nílùú Port Harcourt, ní ìpínlẹ̀ Rivers, lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà.Ó kẹ́kọ̀ọ́ ní Holy Family College/Baptist High School fún ẹ̀kọ́ ilé-ìwé gírámà. Ó tẹ̀ síwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Institute of Management Technology, Enugu, lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà níbi tí ó ti kàwé gbàwé ẹ̀rí nínú Dípólómà nínú ìmọ̀ Ìbánisọ̀rọ̀[3]. Bákan náà ó lọ sí University of Port Harcourt níbi tí ó ti kàwé gbàwé ẹ̀rí nínú dìgírì nínú Ìmọ̀ Àyíká àti Ènìyàn (Ìṣeọ̀rọ̀àwùjọ àti Anthropology) lọ́dún 1989. Bákan náà, ó tún kàwé gboyè dìgírì kejì nínú ìmọ̀ ìṣègùn àbò àti àyíká ní òkè-òkun ní Buckingham University, ní London lọ́dún 2010.

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Clem Ohameze battles for The Kingdom". Vanguardngr.com. 2012-10-27. Retrieved 2013-09-21. 
  2. "Clem Ohameze Makes Nollywood Comeback With Eucharia Anunobi, Others In The Kingdom". nigeriafilms.com. 2012-11-03. Archived from the original on 2013-09-21. Retrieved 2013-09-21. 
  3. Suleiman, Taiye (2008-04-07). "Nollywood Photo Blog: Pictorial Glance at Clem Ohameze of Nollywood". Nollywood Photo Blog. Retrieved 2017-02-21.